< Jesajas 30 >

1 Ak vai, tiem stūrgalvīgiem bērniem, saka Tas Kungs, kas padomu ņemas, bet ne no Manis, un derību der, bet bez Mana Gara, un krāj grēku uz grēku!
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 Kas ceļas iet uz Ēģipti, nevaicādami Manu muti, un stiprinājās ar Faraona spēku un meklē patvērumu apakš Ēģiptes ēnas.
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 Faraona spēks jums būs par kaunu, un tas patvērums apakš Ēģiptes ēnas par apsmieklu.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 Jo viņa (t.i. Jūda) virsnieki gan bijuši Coanā, un viņa vēstneši nākuši līdz Hanesai,
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Bet visi paliks kaunā pie tās tautas, kas viņiem nederēs nedz par palīgu, nedz par citu labumu, bet būs par kaunu vien un par apsmieklu.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Spriedums par dienvidu Beēmotu(zvēru). Pa bēdu un izbaiļu zemi, kur lauvu mātes un lauvas, odzes un skrejoši pūķi, tie savu mantu vedīs kumeļu mugurā, un savu bagātību uz kamieļu kupriem, pie tautas, kas nekā nepalīdz.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 Jo Ēģiptes zeme nav nekas un it nekā nepalīdzēs; tādēļ Es to nosaucu par lielmuti, kas paliek sēžot uz vietas.
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Nu tad ej, raksti to viņu priekšā uz galdu un ieraksti to grāmata, ka tas paliek uz nākamām dienām mūžīgi mūžam.
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 Jo tā ir stūrgalvīga tauta, tie ir melkuļu bērni, bērni, kas Tā Kunga bauslību negrib klausīt,
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 Kas uz redzētājiem saka: neredziet! Un uz sludinātājiem: nesludinājiet mums patiesīgu mācību! Runājiet uz mums ar mīkstu mēli! Sludinājiet viltu!
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Atkāpjaties no ceļa, atstājaties no tekas, lai paliek nost no mums Israēla Svētais!
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Tādēļ Israēla Svētais tā saka: Tāpēc ka jūs šo vārdu atmetat un ceriet uz varas darbu un blēdību un uz to paļaujaties,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 Tāpēc jums šis noziegums būs tā kā plaisums ielīkušā krītošā augstā mūrī, kas piepeši vienā acu mirklī sagrūs.
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 Un tas tos sadauzīs tāpat kā podnieks sadauza trauku, ko dauzot netaupa, un kad tas satriekts, neviena gabaliņa neatliek, ar ko uguni varētu ņemt no ugunskura vai ūdeni smelt no akas.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
15 Jo tā saka Tas Kungs Dievs, tas Svētais iekš Israēla: caur atgriešanos un norimšanu jūs taptu izglābti, caur klusu sirdi un cerību jūs varētu stipri būt, bet jūs neesat gribējuši.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 Un jūs sakāt: nē, bet uz zirgiem mēs gribam skriet: tāpēc jums būs skriet; un uz čakliem zirgiem mēs gribam jāt: tāpēc arī tie jās čakli, kas jums dzenās pakaļ.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Viens tūkstotis (bēgs) no viena vienīga (vīra) draudiem, no piecu draudiem jūs bēgsiet, līdz kamēr no jums atliksies tik kā masta koks kalna galā un kā karogs pakalna virsū.
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 Un tādēļ Tas Kungs gaidīs, pirms jums būs žēlīgs, un augsti pacelsies, pirms pār jums apžēlosies; jo Tas Kungs ir Dievs, kas tiesās: svētīgi visi, kas uz Viņu cerē.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 Jo tu, Ciānas tauta, kas dzīvo Jeruzālemē, raudot tu vienmēr neraudāsi, apžēlodamies Viņš par tevi apžēlosies uz tavas saukšanas balsi; kad Viņš tevi dzirdēs, tad tev atbildēs.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 Tas Kungs jums dos bēdās maizi un izbailēs ūdeni. Un tavi mācītāji vairs neapslēpsies, bet tavas acis redzēs tavus mācītājus.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 Un tavas ausis dzirdēs aiz tevis šo vārdu: šis ir tas ceļš, staigājiet pa to! Kad jūs nogriezušies vai pa labo vai pa kreiso roku.
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 Un jūs sagānīsiet savu izgriezto sudraba bilžu uzvalkus un savu izlieto zelta bilžu drēbes; tās tu nometīsi tā kā sārņus un sacīsi uz tām: nost!
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 Tad Viņš dos lietu tavai sēklai, ar ko tu savu zemi esi apsējis, un maizi no zemes augļiem, un tā būs trekna un tauka. Un tavi lopi tai dienā taps ganīti plašās ganībās.
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 Un tie vērši un ēzeļi, ar ko zemi strādās, ēdīs sālītu mistru, kas vētīts ar liekšķeri un vētekli.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 Un pa visiem augstiem kalniem un pa visiem lieliem pakalniem būs upītes un ūdens strauti, tās lielās kaušanas dienā, kad torņi sagrūs.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 Un mēness gaišums būs kā saules gaišums, un saules gaišums septiņkārt gaišāks nekā septiņu dienu gaišums, tai dienā, kad Tas Kungs Savu ļaužu vainu sasies un to vāti dziedinās, ar ko tie ievainoti.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Redzi, Tā Kunga vārds nāk no tālienes, Viņa dusmība deg un ir grūti nesama, Viņa lūpas ir bardzības pilnas, un Viņa mēle tā kā rijoša uguns.
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Un Viņa dvaša ir kā ūdens plūdi, kas sniedzās līdz kaklam, ka Viņš pagānus sijā ar posta sietu un tautām žokļos liek iemauktus, kas maldina.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Tad pie jums dziedās kā svētku naktī, un jūsu sirds priecāsies it(kā tiem), kas ar stabulēm nāk uz Tā Kunga kalnu, uz Israēla akmens kalnu.
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 Un Tas Kungs liks dzirdēt Savas balss godību un liks redzēt Savu izstiepto elkoni ar bargām dusmām un ar rijošu uguns liesmu, ar zibeni un ar plūdiem un ar krusu.
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Jo Asurs iztrūcināsies no Tā Kunga balss, kad Viņš ar rīksti sitīs.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 Un pie katra cirtiena ar to nospriesto rīksti, ko Tas Kungs laidīs Asuram virsū, skanēs bungas un kokles, un ar karstu karošanu Viņš pret to karos.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 Jo bedre jau sen ir gatava, arī priekš ķēniņa tā ir gatava, dziļa un plata; viņas uguns- un malkas- kopa ir varen liela; Tā Kunga dvaša to iededzinās kā sēra strautu.
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

< Jesajas 30 >