< Jesajas 18 >

1 Ak vai, zeme, kur spārni žvingst, viņpus Kūsa upēm;
Ègbé ni fún ilẹ̀ tí ó kún fún ariwo ìyẹ́ eṣú, ní àwọn ipadò Kuṣi,
2 Tā sūta vēstnešus pār jūru un niedru laivās pār ūdeņiem. Ejat, jūs čaklie vēstneši, pie tautas, kas bijājama tālu tālu, pie tautas, kas pavēlētāja un saminēja, kam upes zemi dala.
tí ó rán àwọn ikọ̀ lórí Òkun lórí omi nínú ọkọ̀-ọpọ́n tí a fi eèsún papirusi ṣe. Ẹ lọ, ẹ̀yin ikọ̀ tí ó yára, sí àwọn ènìyàn gíga tí àwọ̀ ara wọn jọ̀lọ̀, sí àwọn ènìyàn tí a ń bẹ̀rù káàkiri, orílẹ̀-èdè aláfojúdi alájèjì èdè, tí odò pín ilẹ̀ rẹ̀ yẹ́lẹyẹ̀lẹ.
3 Visi jūs pasaules iedzīvotāji un jūs ļaudis virs zemes, kad karogs taps izcelts kalnos, tad redziet, un kad trumete skanēs, tad dzirdiet!
Gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ayé, tí ó ń gbé orílẹ̀ ayé, nígbà tí a bá gbé àsíá kan sókè lórí òkè, ẹ ó rí i, nígbà tí a bá fun fèrè kan ẹ ó gbọ́ ọ.
4 Jo tā Tas Kungs uz mani sacījis: “Es turēšos klusu un skatīšos no Sava mājokļa, kā karstums spiež saulei spīdot un padebesis raso pļaujama laika karstumā.”
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Èmi yóò dákẹ́ jẹ́ẹ́, èmi yóò sì máa wo òréré láti ibùgbé e mi wá, gẹ́gẹ́ bí ooru gbígbóná nínú ìtànṣán oòrùn, gẹ́gẹ́ bí òjò-dídì ní àárín gbùngbùn ìkórè.”
5 Jo priekš pašas pļaujas, kad ziedi noziedējuši un kad no ziediem ķekari jau ietekās, tad Viņš stīgas nogriezīs ar dārza nazi un zarus atņems un nokapās.
Nítorí, kí ìkórè tó bẹ̀rẹ̀, nígbà tí ìrudí bá kún, nígbà tí ìtànná bá di èso àjàrà pípọ́n. Òun yóò sì fi dòjé rẹ́ ẹ̀ka tuntun, yóò sì mu kúrò, yóò sì gé ẹ̀ka lulẹ̀.
6 Tie visi taps atstāti kalnu ērgļiem un zemes zvēriem, un tie ērgļi tur paliek pa vasaru un visi zemes zvēri tur mīt pa ziemu.
A ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ẹyẹ òkè ńlá àti fún àwọn ẹranko búburú; àwọn ẹyẹ yóò fi wọ́n ṣe oúnjẹ nínú ẹ̀ẹ̀rùn àti àwọn ẹranko búburú nígbà òjò.
7 Tanī laikā Tam Kungam Cebaot nesīs dāvanas no tās tautas, kas lielu slaiku augumu, un no tās tautas, kas bijājama tālu tālu, no tās tautas, kas pavēlētāja un saminēja, kam upes zemi dala, uz to vietu, kur Tā Kunga Cebaot vārds, uz Ciānas kalnu.
Ní àkókò náà ni a ó mú ẹ̀bùn wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn gíga tí ẹran-ara wọn jọ̀lọ̀, láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí a bẹ̀rù níbi gbogbo, orílẹ̀-èdè aláfojúdi àti alájèjì èdè, ilẹ̀ ẹni tí omi pín sí yẹ́lẹyẹ̀lẹ— a ó mú àwọn ẹ̀bùn náà wá sí òkè Sioni, ibi tí orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbé wà.

< Jesajas 18 >