< Hozejas 1 >

1 Šis ir Tā Kunga vārds, kas notika uz Hozeju, Beērus dēlu, Uzijas, Jotama, Ahazs, Hizkijas, Jūda ķēniņu, dienās un Jerobeama, Jehoas dēla, Israēla ķēniņa dienās.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
2 Šis ir tas iesākums, kā Tas Kungs runāja ar Hozeju. Tas Kungs sacīja uz Hozeju: ej, ņem sev maukas sievu un maukas bērnus, jo zeme dzenās tiešām maucībai pakaļ no Tā Kunga nost.
Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
3 Tad viņš nogāja un ņēma Gomeri, Diblaima meitu, un tā tapa grūta un dzemdēja viņam dēlu.
Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
4 Un Tas Kungs uz viņu sacīja: Sauc viņa vārdu Jezreēli (tas Kungs izkaisīs); jo par īsu laiku Es piemeklēšu Jezreēļa asins vainu pie Jeūs nama un darīšu galu Israēla nama valstībai.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
5 Un tai dienā Es salauzīšu Israēla stopu Jezreēļa ielejā.
Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
6 Un viņa tapa atkal grūta un dzemdēja meitu. Un Viņš uz to sacīja: nosauc viņas vārdu LoRukama (neapžēlota), jo Es joprojām vairs neapžēlošos par Israēla namu, ka Es tiem piedotu.
Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
7 Bet par Jūda namu Es apžēlošos un tos atpestīšu caur To Kungu, viņu Dievu; bet Es tos neatpestīšu ne caur stopu, ne caur zobenu, ne caur karu, ne caur zirgiem, ne caur jātniekiem.
Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
8 Kad tā nu to LoRukamu bija atšķīrusi, tad viņa tapa grūta un dzemdēja dēlu.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
9 Un Viņš sacīja: sauc viņa vārdu LoAmmi (ne Mana tauta); jo jūs neesat Mana tauta, un arī Es nebūšu jūsu (Dievs).
Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
10 Bet Israēla bērnu pulks būs kā jūras smiltis, ko nevar ne mērot, ne skaitīt. Un notiks tai vieta, kur uz tiem sacīja: jūs neesat Mani ļaudis, - uz tiem sacīs: Jūs tā dzīvā Dieva bērni!
“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
11 Un Jūda bērni un Israēla bērni sapulcināsies kopā un iecels pār sevi vienu galvu un atnāks no tās zemes jo Jezreēļa diena būs liela.
Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.

< Hozejas 1 >