< Pirmā Mozus 31 >
1 Un viņš dzirdēja, ka Lābana bērni sacīja: Jēkabs visu paņēmis, kas mūsu tēvam pieder, un no tā, kas mūsu tēvam piederēja, viņš visu šo mantu ir krājis.
Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
2 Un Jēkabs redzēja Lābana vaigu, un redzi, tas nebija vairs, kā vakar un aizvakar.
Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
3 Un Tas Kungs sacīja uz Jēkabu: griezies atpakaļ uz savu tēva zemi un pie saviem radiem, un Es būšu ar tevi.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Tad Jēkabs sūtīja un aicināja Rahēli un Leū uz lauku pie savām avīm,
Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
5 Un sacīja uz tām: es redzu jūsu tēva vaigu, ka tas nav pret mani kā vakar un aizvakar, bet mana tēva Dievs ir bijis ar mani.
Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
6 Un jūs zināt, ka ar visu savu spēku jūsu tēvam esmu kalpojis.
Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
7 Bet jūsu tēvs mani pievīlis un manu algu desmitkārt pārgrozījis; tomēr Dievs tam nav vaļas devis, man ļaunu darīt.
síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
8 Kad viņš tā sacīja: tām lāsainām būs tev būt par algu, tad visas avis vedās lāsainas; un kad viņš tā sacīja: tām strīpainām būs tev būt par algu, tad visas avis vedās strīpainas.
Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
9 Tā Dievs jūsu tēvam tos lopus ir atņēmis un man devis.
Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
10 Un notikās tanī laikā, kad avis apgājās, ka es savas acis pacēlu un redzēju sapnī, un redzi, tie āži, kas apgājās, bija strīpaini, raibi un lāsaini.
“Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
11 Tad tas Dieva eņģelis uz mani sacīja sapnī: Jēkab; un es sacīju: še es esmu.
Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
12 Un tas sacīja: pacel jel savas acis un skaties, - visi tekuļi, kas apietās ar tām avīm, ir strīpaini, lāsaini un raibi; jo Es visu to esmu redzējis, ko tev Lābans dara.
Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
13 Es esmu Bēteles Dievs, kur tu esi svaidījis piemiņas akmeni, kur tu man solīdamies esi solījies; celies nu un izej no šās zemes un griezies atpakaļ uz savu dzimteni.
Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
14 Tad Rahēle un Lea atbildēja un uz to sacīja: vai mums vēl ir kāda daļa un mantība mūsu tēva namā?
Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
15 Vai mēs no viņa neesam turētas kā svešas? Jo viņš mūs ir pārdevis un arī mūsu maksu rīdams aprijis.
Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
16 Jo visa bagātība, ko Dievs mūsu tēvam ir atņēmis, pieder mums un mūsu bērniem; un nu dari visu to, ko Dievs tev ir sacījis.
Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
17 Un Jēkabs cēlās un lika savus bērnus un savas sievas uz kamieļiem;
Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
18 Un aizveda visus savus lopus un visu savu mantu, ko Mezopotamijā bija pelnījis, ka ietu pie Īzaka, sava tēva, uz Kanaāna zemi.
Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
19 Un Lābans bija aizgājis savas avis cirpt, un Rahēle nozaga tos elka dievus, kas bija viņas tēvam.
Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
20 Un Jēkabs pievīla Lābanu, to Sīrieti, nesacīdams, ka bēgšot.
Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
21 Un viņš bēga ar visu, kas tam bija, un cēlās un pārcēlās pār to lielo upi un grieza savu vaigu uz Gileād kalniem.
Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
22 Un trešā dienā Lābanam tapa sacīts, Jēkabu esam aizbēgušu.
Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
23 Tad tas ņēma savus brāļus un dzinās tam pakaļ septiņu dienu gājumu un to panāca uz Gileād kalniem.
Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
24 Bet Dievs nāca pie Lābana, tā Sīrieša, sapnī un tam sacīja: sargies, ka tu ar Jēkabu nerunā no laba uz ļaunu.
Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
25 Un Lābans panāca Jēkabu; un Jēkabs savu telti bija uzcēlis kalnā, un Lābans ar saviem brāļiem to uzcēla Gileād kalnos.
Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
26 Tad Lābans sacīja uz Jēkabu: ko tu esi darījis, ka tu mani esi pievīlis un manas meitas aizvedis, tā kā ar zobenu saņemtas?
Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
27 Kam tu paslepen esi aizbēdzis un no manis nozadzies, un man to neesi sacījis, ka es tev būtu pavadījis ar līksmību un dziesmām, ar bungām un koklēm?
Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
28 Un tu man neesi ļāvis skūpstīt savus dēlus un savas meitas. Tu neprātīgi esi darījis.
Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
29 Spēka gan būtu manā rokā jums ļaunu darīt, bet jūsu tēva Dievs vakar uz mani runājis sacīdams: sargies, ka tu ar Jēkabu nerunā no laba uz ļaunu.
Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
30 Un nu, tu esi ātri aizgājis, jo tu esi ilgodamies ilgojies pēc sava tēva nama; - kāpēc tu esi nozadzis manus dievus?
Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
31 Tad Jēkabs atbildēja un sacīja uz Lābanu: man bija bail un es domāju, ka tu man savas meitas ar varu atņemsi.
Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
32 Bet pie kura tu savus dievus atradīsi, tas lai nepaliek dzīvs mūsu brāļu priekšā. Izmeklē, kas man ir, un ņem tos. Bet Jēkabs nezināja, ka Rahēle tos bija nozagusi.
Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
33 Un Lābans gāja Jēkaba teltī un Leas teltī un to abu kalpoņu teltī un neatrada nenieka; un izgāja no Leas telts un iegāja Rahēles teltī.
Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
34 Bet Rahēle tos elka dievus bija ņēmusi un nolikusi apakš kamieļa sedliem un uzsēdusies tiem virsū. Un Lābans apgrābstīja visu to telti un tos neatrada.
Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
35 Un tā sacīja uz savu tēvu: neapskaisties, mans kungs, ka es priekš tevis nevaru celties, jo man klājās, kā sievām mēdz būt. Un viņš pārmeklēdams neatrada tos elka dievus.
Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
36 Tad Jēkabs apskaitās un bārās un sacīja uz Lābanu: kas ir mans noziegums, kas ir mani grēki, ka tu tik karsti man esi dzinies pakaļ?
Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
37 Ka tu visus manus rīkus esi aptaustījis; ko tu esi atradis no visiem tava nama rīkiem? Liec to priekšā maniem un taviem brāļiem, ka tie starp mums abiem tiesā.
Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
38 Šos divdesmit gadus es pie tevis esmu bijis, tavas avis un tavas kazas nav izmetušās, un tos aunus no tavām avīm es neesmu ēdis.
“Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
39 To saplosīto es tev neesmu pārnesis, tas man bija jāmaksā; no manas rokas tu to esi prasījis, vai tas bija zagts dienā, vai tas bija zagts naktī.
Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
40 Es esmu tāds bijis, ka mani dienā karstums nomāca un naktī aukstums, un miegs nenāca manās acīs.
Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
41 Divdesmit gadus esmu bijis tavā namā, četrpadsmit gadus tev esmu kalpojis par tavām divām meitām un sešus gadus par tavām avīm, un tu manu algu desmitkārt esi pārgrozījis.
Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
42 Ja mana tēva Dievs, tas Ābrahāma Dievs un Tas, ko Īzaks bijās, pie manis nebūtu bijis, tu nu mani tukšu būtu aizsūtījis. Dievs manas bēdas un manu roku darbu ir uzlūkojis un tevi izgājušā naktī apsaucis.
Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
43 Tad Lābans atbildēja un sacīja uz Jēkabu: tās meitas ir manas meitas, un tie bērni ir mani bērni, un tās avis ir manas avis, un viss, ko tu redzi, tas ir mans; un ko es šodien darīšu šīm manām meitām vai viņu bērniem, ko tās ir dzemdējušas?
Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
44 Un nu nāc, darīsim derību, es un tu, ka tā ir par liecību starp mani un tevi.
Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
45 Un Jēkabs ņēma akmeni un to uzcēla par zīmi.
Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
46 Un Jēkabs sacīja uz saviem brāļiem: salasiet akmeņus; un tie ņēma akmeņus un salika tos vienā kopā, un ēda tur virs tās kopas.
Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
47 Un Lābans to nosauca Jegar-Sahāduta (āramiski: liecības kopa), bet Jēkabs to nosauca Galed (ebrejiski: liecības kopa).
Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
48 Un Lābans sacīja: šī kopa lai šodien liecību dod starp mani un tevi; tāpēc viņas vārdu nosauca Galedu
Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
49 Un Micpu, tāpēc ka viņš sacīja: Tas Kungs lai skatās uz mani un uz tevi, kad mēs viens otru neredzēsim.
Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
50 Ja tu apbēdināsi manas meitas un ņemsi citas sievas pie manām meitām klāt, - neviens nav pie mums, redzi, Dievs būs liecinieks starp mani un tevi.
Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
51 Tad Lābans sacīja uz Jēkabu: redz, šī kopa, un redz, šī piemiņas zīme, ko es esmu uzcēlis starp mani un tevi.
Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
52 Šī kopa lai dod liecību un šī zīme lai dod liecību, ka es gar šo kopu nenoiešu pie tevis, ļauna darīt, un ka tev gar šo kopu un šo zīmi nebūs pie manis nākt, ļauna darīt.
yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
53 Ābrahāma Dievs un Nahora Dievs un viņu tēvu Dievs lai tiesā starp mums.
Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
54 Un Jēkabs zvērēja pie tā, ko viņa tēvs Īzaks bijās, un upurēja upuri kalnā un aicināja savus brāļus maizi ēst. Un tie ēda maizi un palika par nakti uz tā kalna.
Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
55 Un Lābans cēlās rītā agri un skūpstīja savus bērnus un savas meitas un tos svētīja. Un Lābans aizgāja un griezās atpakaļ uz savu vietu.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.