< Ezras 10 >

1 Kad nu Ezra tā lūdza un tā sūdzēja raudādams un nomezdamies Dieva nama priekšā, tad no Israēla pie viņa sapulcējās ļoti liela draudze vīru un sievu un bērnu; jo tie ļaudis raudāja lielā raudāšanā.
Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
2 Tad Šehanija, Jeīeļa dēls no Elama bērniem, atbildēja un sacīja uz Ezru: mēs esam grēkojuši pret savu Dievu, ka esam apņēmuši svešas sievas no tās zemes ļaudīm, bet taču vēl būs cerības priekš Israēla.
Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
3 Derēsim tad nu derību ar savu Dievu, ka izdzenam visas sievas, un kas no tām ir dzimuši, pēc Tā Kunga padoma un pēc to ļaužu padoma, kas mūsu Dieva baušļus bīstas, un lai tad darām pēc bauslības.
Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
4 Celies, jo šī lieta tev piekrīt, un mēs būsim ar tevi; esi stiprs un izdari (to).
Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
5 Tad Ezra cēlās un lika priesteru un levitu un visa Israēla virsniekiem zvērēt, darīt pēc šī vārda. Un tie zvērēja.
Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
6 Un Ezra cēlās Dieva nama priekšā un iegāja Jehohanana, Elijadziba dēla, kambarī, un tur nācis viņš neēda maizes un nedzēra ūdens, jo viņš nobēdājās to aizvesto ļaužu pārkāpšanas dēļ.
Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
7 Un tie lika izsaukt pa Jūdu un Jeruzālemi pie visiem no cietuma pārnākušiem, sapulcēties Jeruzālemē.
Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
8 Un kas triju dienu starpā nenāktu pēc virsnieku un vecaju nosacīšanas, tā manta tapšot izdeldēta un pats izstumts no pārnākušo draudzes.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
9 Tad visi Jūda un Benjamina vīri triju dienu starpā sapulcējās Jeruzālemē, - tā bija tā divdesmitā diena devītā mēnesī, - un visi ļaudis sēdēja uz ielas priekš Dieva nama trīcēdami šās lietas dēļ un no stipra lietus.
Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
10 Tad priesteris Ezra cēlās un uz tiem sacīja: jūs esat apgrēkojušies, svešas sievas apņemdami, ka jūs vairotu Israēla noziegumu.
Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
11 Tad nu izsūdziet to Tam Kungam, savu tēvu Dievam, un dariet pēc viņa prāta, un šķiraties no tās zemes ļaudīm un no tām svešām sievām.
Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
12 Tad visa draudze atbildēja un sacīja ar stipru balsi: pēc taviem vārdiem mums tā jādara.
Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
13 Bet to ļaužu ir daudz un ir lietus laiks, ka nevar ārā stāvēt; tas arī nav vienas jeb divēju dienu darbs, jo mēs šinī lietā esam pārlieku grēkojuši.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
14 Lai mēs savus virsniekus ieceļam pār visu draudzi, ka visi, kas ir mūsu pilsētās, kas svešas sievas apņēmuši, lai nāk nospriestos laikos un ar tiem ikkatras pilsētas vecaji un viņas soģi, kamēr mēs no sevis novēršam sava Dieva bardzību šīs lietas dēļ.
Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
15 Tad Jonatāns, Azaēļa dēls, un Jeazija, Tikvus dēls, tam cēlās pretī, un leviti, Mešulams un Šabetajus, tiem palīdzēja.
Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
16 Bet tie pārnākušie tā darīja: Tie izraudzīja priesteri Ezru un vīrus, proti savu tēvu namu virsniekus pēc saviem tēvu namiem, visus ar vārdu noteiktus. Un tie turēja sapulci desmitā mēneša pirmā dienā, šo lietu izmeklēt.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
17 Un tie to izdarīja pie visiem vīriem, kas svešas sievas bija apņēmuši, līdz pirmā mēneša pirmajai dienai.
ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
18 Un no priesteru dēliem tapa atrasti, kas svešas sievas bija apņēmuši, no Ješuūs, Jocadaka dēla, dēliem un viņa brāļiem: Maāseja, Eliēcers, Jaribs un Ģedalija.
Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
19 Un tie deva savu roku, ka savas sievas izdzīšot, un noziedzīgi būdami tie deva aunu priekš sava nozieguma.
Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
20 Un no Imera bērniem: Hananus un Zebadija.
Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
21 Un no Harima bērniem: Maāseja un Elija un Šemaja un Jeīels un Uzija.
Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
22 Un no Pazura bērniem: Elioēnajus, Maāseja, Ismaēls, Netaneēls, Jozabads un Eleaza.
Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
23 Un no levitiem: Jozabads un Šimejus un Ķelaja, (šis ir Kelita), Petahja, Jūda un Eliēcers.
Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
24 Un no dziedātājiem: Elijašibs. Un no vārtu sargiem: Šalums un Telems un Urus.
Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
25 Un no Israēla, no Pareus bērniem: Ramija un Jezija un Malhija un Mejamins un Eleazars un Malhija un Benaja.
Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
26 Un no Elama bērniem: Metanija, Zaharija, Jeīels un Abdus un Jerimots un Elija.
Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
27 Un no Zatus bērniem: Elioēnajus, Elijadzibs, Matanija un Jerimots un Zabats un Aziza.
Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
28 Un no Bebajus bērniem: Jehohanans, Ananija, Zebajus, Atlajus.
Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
29 Un no Banus bērniem: Mešulams, Malaks un Adaja, Jazubs un Zeals, Jeramots.
Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
30 Un no PaātMoaba bērniem: Adna un Ķelals, Benaja, Maāseja, Matanija Becaleēls un Benujus un Manasus.
Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
31 Un no Harima bērniem: Eliēsers, Jezija, Malhija Šemaja, Sīmeans,
Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
32 Benjamins, Maluks un Zemarija.
Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
33 No Azama bērniem: Matnajus, Matata, Zabads, Elivalets, Jeremajus, Manasus, Šimejus.
Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
34 No Banus bērniem: Maēdajus, Amrams un Uēls,
Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
35 Benaja, Bedija, Ķelujus,
Benaiah, Bediah, Keluhi
36 Un Naja, Meremots, Elijašibs,
Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
37 Mantanija, Matnaja un Jaēzus,
Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
38 Un Banus un Benujus un Šimejus,
Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
39 Un Šelemija un Nātans un Adaja,
Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
40 Maknadbajus, Zazajus, Zarajus,
Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
41 Azareēls un Šelemija, Samarija,
Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
42 Šalums, Amarija, Jāzeps.
Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
43 No Nebus bērniem: Jeīels, Matitija, Zabads, Zebina, Jadajus un Joēls, Benaja.
Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
44 Visi šie bija svešas sievas apņēmuši, un no tām sievām kādas bija bērnus dzemdējušas.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

< Ezras 10 >