< Ecechiela 47 >

1 Un viņš mani veda atpakaļ pie tā nama durvīm, un redzi, tur ūdens iztecēja apakš tā nama sliekšņa pret rītiem, jo tā nama priekšgals bija pret rītiem, un tas ūdens notecēja no apakšas no tā nama labās puses, sānis altārim pret dienvidu.
Ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí àbáwọlé tẹmpili náà, mo sì rí omi tí ó ń tú jáde láti abẹ́ ìloro tẹmpili náà sí apá ìhà ìlà-oòrùn (nítorí tẹmpili náà dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn). Omi náà ń tú jáde sí ìsàlẹ̀ láti abẹ́, ní ìhà gúúsù tẹmpili náà, ní ìhà gúúsù pẹpẹ.
2 Un viņš mani izveda pa Ziemeļa vārtiem, un mani apveda apkārt pa āra ceļu pie ārējiem vārtiem, kas pret rītiem, un redzi, ūdens iztecēja no labās puses.
Ó wá mú mi gba ojú ọ̀nà àríwá jáde, ó sì mú mi yí ìta ojú ọ̀nà ìta tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn, omi náà sì ń sàn láti ìhà gúúsù wá.
3 Kad nu tas vīrs izgāja pret rītiem, tad mēra aukla bija viņa rokā, un viņš mēroja tūkstoš olektis, un lika man brist pār to ūdeni, un tas ūdens man sniedzās līdz krimšļiem.
Bí ọkùnrin náà ti lọ sí apá ìhà ìlà-oòrùn pẹ̀lú okùn wíwọ̀n nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀, ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́, ó sì mú mi gba ibi odò kan tí kò jì jù kókósẹ̀ lọ.
4 Atkal viņš mēroja tūkstoš olektis un lika man brist pār to ūdeni, un tas ūdens man sniedzās līdz ceļiem, un viņš mēroja vēl tūkstoš olektis, un lika man pārbrist, un tas ūdens man sniedzās līdz gurniem.
Ó sì wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba ibi odò tí ó jì ní ìwọ̀n orúnkún. Ó tún wọn ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba odò tí ó dé ìbàdí.
5 Atkal viņš mēroja tūkstoš olektis, tad bija upe, ko es nevarēju izbrist, jo tas ūdens bija dziļš, ūdens, kur bija jāpeld, upe, kur nevarēja iet cauri.
Ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ṣùgbọ́n nísinsin yìí odò tí ń kò lè kọjá rẹ̀ ni, nítorí pé odò tí ó kún, ó sì jì tó èyí tí wọ́n le lúwẹ̀ẹ́ nínú rẹ̀ odò tí ẹnikẹ́ni kò le dá kọjá ni.
6 Un viņš uz mani sacīja: vai tu to esi redzējis, cilvēka bērns? Tad viņš mani veda atkal atpakaļ upes malā.
Ó bi mí léèrè pé, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ o rí èyí?” Lẹ́yìn náà, ó mú mi padà sí etí odò.
7 Kad es nu nācu atpakaļ, redzi, tad upes malā bija ļoti daudz koku, šinī un viņā pusē.
Nígbà tí mo dé ibẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì odò.
8 Un viņš uz mani sacīja; šis ūdens iztek pret rīta pusi un notek klajumā, pēc tas nāk jūrā, un jūrā notecējis tas ūdens taps veselīgs.
Ó sọ fún mi pé, “Odò yìí ń tú jáde sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì wọ inú Òkun lọ, a sì mú omi wọn láradá.
9 Un notiek, ka ikviena dzīva dvaša, kas kustās, kurp šī upe(no diviem avotiem) nāk, dzīvos, un tur būs ļoti daudz zivju, tāpēc ka šis ūdens turp nāks, un būs veseli un viss dzīvos, kur šī upe nāk.
Àwọn ohun alààyè tí ó ń rákò yóò máa gbé ní ibikíbi tí odò ti ń sàn. Ẹja yóò pọ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀, nítorí pé odò ń sàn síbẹ̀, ó sì mú kí omi iyọ̀ tutù nini; nítorí náà níbi tí omi ti ń sàn, gbogbo nǹkan ni yóò wà ni ààyè.
10 Un zvejnieki pie tās stāvēs no Enģediem līdz EnEģlaīm, tur būs vietas, kur tīklus izmetīs. Viņu zivis būs pēc savas kārtas, kā tās lielās zivis jūrā, ļoti daudz.
Àwọn apẹja yóò dúró ní etí bèbè odò; láti En-Gedi títí dé En-Eglaimu ààyè yóò wa láti tẹ́ àwọ̀n wọn sílẹ̀. Oríṣìíríṣìí ẹja ni yóò wà gẹ́gẹ́ bí ẹja omi Òkun ńlá.
11 Bet viņas paltis(dumbrāji) un viņas dīķi netaps veselīgi; tie būs priekš sāls.
Ṣùgbọ́n ẹrẹ̀ àti àbàtà kò ní tòrò; àwa yóò fi wọn sílẹ̀ fún iyọ̀.
12 Un pie tās upes viņas malas abējās pusēs augs visādi augļu koki, kam lapas nesavītīs un augļi nemitēsies, un ikmēnešus tie nesīs jaunus augļus. Jo viņas ūdens iztek no tās svētās vietas, un viņas augļi būs par barību un viņas lapas par dziedināšanu.
Àwọn igi eléso ní oríṣìíríṣìí ni yóò máa hù ní bèbè odò ní ìhà ìhín àti ní ìhà ọ̀hún. Ewé wọn kì yóò sì rọ, bẹ́ẹ̀ ní èso wọn kì yóò run, wọn yóò máa ṣe èso tuntun rẹ̀ ní oṣù nítorí pé omi láti ibi mímọ́ ń sàn sí wọn. Èso wọn yóò sì jẹ́ fún jíjẹ àti ewé wọn fún ìwòsàn.”
13 Tā saka Tas Kungs Dievs: šī lai ir robeža, pēc kuras jums to zemi būs ņemt par mantību pēc tām divpadsmit Israēla ciltīm: Jāzepam pienākas divas daļas.
Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ̀nyí ni àwọn ààlà tí ìwọ yóò fi pín ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ogún ìní ní àárín àwọn ẹ̀yà méjìlá Israẹli, pẹ̀lú ìpín méjì fún Josẹfu.
14 Un jums to būs iemantot, vienam kā otram; par to es savu roku esmu pacēlis, to dot jūsu tēviem; un šī zeme jums piekritīs par mantību.
Ìwọ yóò pín ilẹ̀ náà déédé ní àárín wọn. Nítorí pé mo búra nípa nína ọwọ́ sókè láti fi fún àwọn baba ńlá yin, ilẹ̀ yìí yóò di ogún ìní yín.
15 Šī nu ir tās zemes robeža: pret ziemeli no lielās jūras pār Etlonu, kamēr nāk uz Cedadu,
“Èyí yìí ni yóò jẹ́ ààlà ilẹ̀ náà: “Ní ìhà àríwá yóò lọ láti omi Òkun ńlá ní ibi ọ̀nà Hetiloni gbà tí Hamati lọ sí Sedadi,
16 Hamata, Berota, Zibraīma, kas ir starp Damaskus robežu un Hamatas robežu, AcarTikons, kas ir pie Averana robežas.
Berota àti Sibraimu, èyí tí ó wà ní ààlà láàrín Damasku àti Hamati títí dé Hasari Hatikonu, èyí tí ó wà ní agbègbè Haurani.
17 Tā būs tā robeža no jūras līdz AcarEnonam, Damaskus robežai; un tālāk pret ziemeli ir Hamatas robeža, un šī būs tā ziemeļa mala.
Ààlà yóò fẹ̀ láti Òkun lọ sí Hasari Enanu, ní apá ààlà ti Damasku, pẹ̀lú ààlà tí Hamati lọ sí apá àríwá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà ní apá ìhà àríwá.
18 Un tā rītu mala starp Averanu un Damasku un starp Gileādu un Israēla zemi jums būs Jardāne; no tās robežas līdz rītu jūrai jums būs mērot. Un šī ir tā rītu mala.
Ní ìhà ìlà-oòrùn ààlà yóò wá sí àárín Haurani àti Damasku, lọ sí apá Jordani láàrín Gileadi àti ilẹ̀ Israẹli, títí dé Òkun, àti títí dé Tamari. Èyí ní yóò jẹ́ ààlà ìlà-oòrùn.
19 Un tā dienvidu mala pret dienvidiem lai ir no Tamāra līdz Kādeša strīdus ūdenim, un tad gar upi līdz lielai jūrai. Un šī būs tā dienvidu mala pret dienvidiem.
Ní ìhà gúúsù yóò lọ láti Tamari títí dé ibi omi Meriba Kadeṣi, lẹ́yìn náà ni ìhà Wadi tí Ejibiti lọ sí Òkun ńlá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà gúúsù.
20 Un tā vakaru mala lai ir tā lielā jūra no tās robežas, līdz kamēr iet uz Hamatu. Šī būs tā vakaru mala.
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, Òkun ńlá ni yóò jẹ́ ààlà títí dé ibi kan ni òdìkejì lẹ́bàá Hamati. Èyí yìí ni yóò jẹ ààlà ìhà ìwọ̀-oòrùn.
21 Un jums šo zemi savā starpā būs izdalīt pēc Israēla ciltīm.
“Ìwọ ní láti pín ilẹ̀ yìí ní àárín ara yín gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà Israẹli.
22 Un jums to būs izdalīt par mantību sev un arī tiem svešiniekiem, kas jūsu starpā dzīvo un bērnus dzemdinājuši jūsu vidū, un tie lai jums ir kā tas, kas no Israēla bērniem dzimis!
Ìwọ yóò pín gẹ́gẹ́ bí ìní fún ara yín àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé ní àárín yín tí ó sì ní àwọn ọmọ. Ìwọ yóò sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìbílẹ̀ àwọn ará Israẹli; papọ̀ mọ́ yin ni kí ẹ pín ìní fún wọn ní àárín àwọn ẹ̀yà Israẹli.
23 Tiem būs līdz ar jums mantot Israēla cilšu vidū, un tai ciltī, pie kuras tas svešinieks dzīvo, tur jums viņam būs dot daļu, saka Tas Kungs Dievs.
Ní àárín gbogbo ẹ̀yà tí àwọn àlejò ń gbé; wọn gbọdọ̀ fi ìní tirẹ̀ fún un,” ní Olúwa Olódùmarè wí.

< Ecechiela 47 >