< Ecechiela 44 >

1 Un viņš mani veda atpakaļ pie svētās vietas ārējiem vārtiem, kas ir pret rīta pusi, un tie bija aizslēgti.
Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
2 Un Tas Kungs uz mani sacīja: šie vārti lai stāv aizslēgti, tie nav jāatver, un neviens pa tiem lai neieiet, tāpēc ka Tas Kungs, Israēla Dievs, pa tiem ir iegājis, tāpēc lai tie stāv aizslēgti.
Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
3 Par valdnieku jāsaka: kas valdnieks, tas lai tur sēž, maizi ēst Tā Kunga priekšā; pa vārtu priekšnamu tam būs ieiet un pa to pašu ceļu tam būs iziet.
Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
4 Un viņš mani veda pie ziemeļa vārtiem nama priekšā, un es redzēju, un raugi, Tā Kunga godība piepildīja to namu; tad es kritu uz savu vaigu.
Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
5 Un Tas Kungs sacīja uz mani: cilvēka bērns, ņem vērā un redzi ar savām acīm un klausies ar savām ausīm visu, ko Es ar tevi runāju par visiem Tā Kunga nama likumiem un par visiem viņa baušļiem, un ņem vērā tā nama ieejamo vietu ar visām tām svētās vietas izejamām vietām.
Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
6 Un saki uz tiem pārgalvīgiem, uz Israēla namu; tā saka Tas Kungs Dievs: nu ir gan, Israēla nams, ar visu jūsu negantību.
Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
7 Ja jūs esat ieveduši svešiniekus ar neapgraizītām sirdīm un neapgraizītām miesām, ka tie bija Manā svētā vietā, to sagānīt, Manu namu, kad jūs upurējāt Manu maizi, taukus un asinis, un tie Manu derību lauza pie visām jūsu negantībām.
Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
8 Un jūs neesat izpildījuši savu svēto kalpošanu, bet citus sev esat iecēluši, kalpot Manā svētā vietā.
Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
9 Tā saka Tas Kungs Dievs: nevienam svešiniekam, kam neapgraizīta sirds un neapgraizīta miesa, nebūs ieiet Manā svētā vietā, no visiem tiem svešiniekiem, kas ir starp Israēla bērniem.
Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
10 Bet tie leviti, kas tālu no Manis atkāpušies, kad Israēls maldīdamies no manis nomaldījās saviem elkiem pakaļ, tie gan nesīs savu noziegumu.
“‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Un tiem būs kalpot Manā svētā vietā par sargiem pie nama vārtiem, un tiem būs to namu apkopt, tiem būs kaut dedzināmos un kaujamos upurus priekš tiem ļaudīm, un viņu priekšā stāvēt, viņiem kalpodami.
Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
12 Tāpēc ka tie viņiem ir kalpojuši viņu elku priekšā un Israēla namam bijuši par apgrēcību uz noziedzību, tāpēc Es paceļu Savu roku pret tiem, saka Tas Kungs Dievs, ka tiem būs nest savu noziegumu.
Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
13 Un tiem nebūs Man tuvoties, Man būt par priesteriem nedz pieiet pie visām Manām svētām un tām visu svētākām lietām, bet tiem būs savu kaunu nest un savas negantības, ko tie darījuši.
Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
14 Tāpēc Es tos ieceļu par sargiem, to namu kopt pie viņa darba, un pie visa, kas iekš tā būs jādara.
Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
15 Bet tie priesteri un Levja cilts, Cadoka bērni, kas to kalpošanu izpildījuši Manā svētā vietā, kad Israēla bērni no Manis nomaldījās, tiem Man būs tuvoties, Man kalpot un stāvēt Manā priekšā, Man upurēt taukus un asinis, saka Tas Kungs Dievs.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 Tiem būs ieiet Manā svētā vietā, un tiem būs nostāties pie Mana galda, Man kalpot un Manu kalpošanu izpildīt.
Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
17 Un kad tie nāks pie tā iekšējā pagalma vārtiem, tad tiem būs apvilkt linu drēbes, bet vilnainās tiem nebūs ģērbties, kad tie iekšējā pagalma vārtu iekšpusē kalpo.
“‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
18 Linu autiem būs būt uz viņu galvām un linu ūzām(biksēm) uz viņu gurniem, un tiem nebūs apjozties sviedros.
Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
19 Un kad tie iziet ārējā pagalmā, proti ārējā pagalmā pie tiem ļaudīm, tad tiem būs novilkt savas drēbes, ar ko tie kalpojuši, un tās nolikt svētās vietas kambaros, un tiem būs apvilkt citas drēbes, lai tie tos ļaudis nesvētī ar savām drēbēm.
Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
20 Un tiem savu galvu nebūs pliku nodzīt nedz arī saviem matiem likt gari izaugt, bet tiem savus matus būs apcirpt.
“‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
21 Un nevienam priesterim nebūs vīna dzert, kad tiem jāiet iekšējā pagalmā.
Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
22 Tiem arīdzan nebūs ņemt nedz atraitni nedz atšķirtu par sievu, bet jumpravas no Israēla nama dzimuma; bet atraitni, kas ir priestera atraitne, to viņi var ņemt.
Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
23 Un tiem būs mācīt Maniem ļaudīm izšķirt svētu un nesvētu, un tiem darīt zināmu starpību starp nešķīstu un šķīstu;
Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
24 Un tiem būs stāvēt par tiesas lietām un tiesāt, pēc Manām tiesām tiem būs tiesāt, un tiem būs turēt Manus baušļus un Manus likumus visos Manos svētkos un svētīt Manas svētdienas.
“‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
25 Un nevienam no tiem nebūs iet pie kāda miruša cilvēka, lai netop nešķīsts; bet tēva un mātes dēļ, vai dēla un meitas dēļ, brāļa un māsas dēļ, kas nav bijusi pie vīra, tiem ir brīv tapt nešķīstiem.
“‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
26 Un pēc viņa šķīstīšanās vēl septiņas dienas jāpieskaita.
Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
27 Un tai dienā, kad viņš ieies svētā vietā, iekšējā pagalmā, kalpot svētā vietā, tad tam būs upurēt savu grēku upuri, saka Tas Kungs Dievs.
Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
28 Un tas tiem būs par mantību: Es esmu viņu mantība; tāpēc jums tiem nekādu sevišķu daļu nebūs dot iekš Israēla, - Es esmu viņu daļa.
“‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
29 Ēdamo upuri un grēku upuri un nozieguma upuri, tos tiem būs ēst, un viss, kas iekš Israēla (Dievam) apsolīts, tiem piederēs.
Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
30 Un visu pirmo augļu pirmaji no visa un visi cilājamie upuri no visiem jūsu cilājamiem upuriem lai pieder priesteriem. Arī savas mīklas pirmajus jums būs dot priesterim, lai svētība paliek uz tava nama.
Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
31 Nekādu maitu, nedz saplosītu no putniem un no lopiem priesteriem nebūs ēst.
Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.

< Ecechiela 44 >