< Ecechiela 38 >

1 Un Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Cilvēka bērns, griez savu vaigu pret Gogu Magoga zemē, Roša, Mešeha un Tūbala valdnieku, un sludini pret viņu
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
3 Un saki: tā saka Tas Kungs Dievs: redzi, Es celšos pret tevi, Gog, tu Roša, Mešeha un Tūbala valdnieks.
kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
4 Un Es tevi vedīšu un likšu makšķeri tavos žokļos, un tevi izvedīšu ar visu tavu karaspēku, zirgiem un jātniekiem, kas visi labi ģērbti, lielu pulku, ar krūšu bruņām un priekšturamām bruņām, kas visi nes zobenus;
Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
5 Persieši, Moru ļaudis un Libieši viņiem līdz, tie visi ar priekšturamām bruņām un dzelzs cepurēm.
Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
6 Gomers un visi viņa karavīri, Togarmas nams, kas pašā ziemeļu galā, ar visiem saviem karogiem; daudz tautu līdz ar tevi.
Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
7 Esi gatavs un taisies, tu un viss tavs pulks, kas pie tevis sapulcēts, un esi tiem par vadoni. Pēc daudz dienām tu tapsi piemeklēts,
“‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
8 Un pēdīgā laikā tu nāksi uz to zemi, kas ir atkal atvesta no zobena un sapulcēta no daudz tautām, uz Israēla kalniem, kas bez mitēšanās tapa postīti, un tā ir izvesta no tautām, un tie visnotaļ dzīvos droši.
Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
9 Tad tu celsies, nāksi kā vētra, būsi kā padebesis, kas zemi apklāj, līdz ar visiem taviem karogiem, un daudz tautu tev līdz.
Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
10 Tā saka Tas Kungs Dievs: tai dienā celsies tavā sirdī padomi, un tu domāsi niknas domas,
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
11 Un sacīsi: es celšos pret to neapstiprināto zemi, es nākšu pret tiem, kas dzīvo mierīgi un droši, kas dzīvo visi bez mūriem, un kam nav nedz aizšaujamo, nedz vārtu,
Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
12 Laupīt laupīdams un postīt postīdams, savu roku griezdams pret tām posta vietām, kur atkal dzīvo, un pret tiem ļaudīm, kas no pagāniem ir sapulcēti, kas lopus un mantu krājās un dzīvo zemes vidū.
Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
13 Zaba un Dedans un Taršiša tirgotāji un visi viņu varenie uz tevi sacīs: vai tu nāci laupīdams laupīt? Vai tu savu pulku esi sapulcinājis postīdams postīt, sudrabu un zeltu projām vest, lopus un mantu atņemt, lielu laupījumu laupīt?
Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
14 Tādēļ sludini, cilvēka bērns, un saki uz Gogu: tā saka Tas Kungs Dievs, vai tu tai dienā, kad Mani Israēla ļaudis dzīvos droši, to nemanīsi?
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
15 Tad tu nāksi no savas vietas no ziemeļa gala, tu un daudz tautas tev līdz, visi, zirgu jājēji, liels pulks un varens spēks.
Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
16 Un tu celsies pret Maniem Israēla ļaudīm kā padebesis, zemi apklāj. Tas notiks pēdīgā laikā, ka Es tevi vedīšu pret Savu zemi, lai tās tautas Mani pazīst, kad Es pie tevis, Gog, svēts parādīšos priekš viņu acīm.
Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
17 Tā saka Tas Kungs Dievs: tu tas esi, par ko Es pagājušos laikos esmu runājis caur Saviem kalpiem, Israēla praviešiem, kas tanīs dienās, caur daudz gadiem, sludināja, ka Es tevi vedīšu pret tiem.
“‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
18 Bet notiks tai dienā, kad Gogs nāks pret Israēla zemi, saka Tas Kungs Dievs, tad Mana bargā dusmība iedegsies.
Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
19 Un Es Savā karstumā esmu runājis un Savas dusmības ugunī, ka tai dienā liela drebēšana būs Israēla zemē,
Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
20 Tā ka Manā priekšā trīcēs zivis jūrā, un putni apakš debess un zvēri laukā un visi tārpi, kas virs zemes lien, un visi cilvēki, kas zemes virsū, un kalni gāzīsies, un kalnu gali kritīs, un visi mūri grūs pie zemes.
Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
21 Un Es aicināšu zobenu pret viņu uz visiem Maniem kalniem, saka Tas Kungs Dievs, brāļa zobens būs pret brāli.
Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
22 Un Es ar tiem tiesāšos caur mēri un caur asinīm un likšu stipram lietum līt ar lielu krusu, uguni un sēru uz viņu un uz viņa karogiem un uz visām tām tautām, kas viņam līdz.
Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
23 Tā Es parādīšos liels un svēts un Sevi darīšu zināmu daudz tautu acīs, un tās atzīs, ka Es esmu Tas Kungs.
Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’

< Ecechiela 38 >