< Ecechiela 25 >

1 Un Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Cilvēka bērns, griez savu vaigu pret Amona bērniem un sludini pret tiem.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 Un saki uz Amona bērniem: klausiet Tā Kunga Dieva vārdu! Tā saka Tas Kungs Dievs: Tāpēc ka jūs par Manu svēto vietu sakāt: re, re! Tā ir sagānīta! Un par Israēla zemi: tā ir izpostīta! Un par Jūda namu: tie ir cietumā gājuši! -
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 Tādēļ redzi, Es tevi nodošu austruma bērniem par mantību, ka tie tavā vidū uzceļ savas teltis un tavā vidū uztaisa savas māju vietas; tie ēdīs tavus augļus un dzers tavu pienu.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 Un Es Rabu darīšu par kamieļu ganību un Amona bērnus par avju laidaru, un jūs samanīsiet, ka Es esmu Tas Kungs.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Jo tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka tu esi plaukšķinājusi ar rokām un situsi ar kājām un no visas sirds lepni(nievājot) esi priecājusies par Israēla zemi,
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 Tāpēc redzi, Es izstiepšu Savu roku pret tevi un tevi nodošu pagāniem par laupījumu un tevi izdeldēšu no tautām un tevi nomaitāšu no valstīm; Es tevi izdeldēšu, un tu samanīsi, ka Es esmu Tas Kungs.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Tā saka Tas Kungs Dievs: Tāpēc ka Moabs un Seīrs saka: redzi, Jūda nams ir tā kā visi pagāni, -
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 Tādēļ redzi, Es atvēršu Moaba sānus no tām pilsētām, no viņa robežu pilsētām sākot, viņa zemes jaukumu, Betjesivotu, Baāl Meonu un līdz Kiriataīmai,
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 Austruma bērniem klāt pie Amona bērniem Es viņu atdošu par mantību, tā kā Amona bērni starp tautām vairs netaps pieminēti.
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 Un Es turēšu tiesu par Moabu, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka Edoms ar atriebšanu ir atriebies pret Jūda namu, un tie ļoti ir noziegušies, pie tiem atriebdamies,
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 Tādēļ tā saka Tas Kungs Dievs: Es izstiepšu Savu roku pret Edomu un izdeldēšu no viņa cilvēkus un lopus, un Es to darīšu par posta vietu, un tie kritīs caur zobenu no Temana līdz Dedanam.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 Un Es atriebšos pie Edoma caur Savu Israēla ļaužu roku, un tie ar Edomu darīs pēc Manas dusmības un pēc Manas bardzības, tā tie samanīs Manu atriebšanu, saka Tas Kungs Dievs.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Tā saka Tas Kungs Dievs: tādēļ ka Fīlisti atriebušies un no sirds lepni atriebušies uz izdeldēšanu pēc veca ienaida,
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 Tādēļ tā saka Tas Kungs Dievs: redzi, Es izstiepju Savu roku pār Fīlistiem un izdeldēšu Krietus un nomaitāšu tos atlikušos jūrmalā,
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 Un Es pie tiem izdarīšu lielu atriebšanu ar bargām sodībām, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs, kad Es Savu atriebšanu pie tiem būšu izdarījis.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< Ecechiela 25 >