< Ecechiela 22 >

1 Un Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Tad nu, ak cilvēka bērns, vai gribi tiesāt, vai gribi tiesāt to asins pilsētu? Tad rādi viņai visas viņas negantības.
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 Un saki: tā saka Tas Kungs Dievs: ak pilsēta, kas asinis izlej savā vidū, lai viņas laiks nāk, un kas sev taisa elkus un apgānās.
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Caur tām asinīm, ko izlējusi, tu esi noziegusies, un ar saviem elkiem, ko taisījusi, tu esi sagānījusies, un tavām dienām esi likusi tuvu nākt, un esi nākusi savos gados. Tādēļ Es tevi esmu nodevis pagāniem par nievāšanu un visām zemēm par apsmieklu.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Kas tuvu un kas tālu no tevis, tie tevi apsmies, tevi, kam vārds sagānīts un kas nekārtības pilna.
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Redzi, Israēla valdnieki ikviens cik spēdams izlej asinis tavā vidū.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Tēvu un māti tie pie tevis nicina, svešiniekam tie dara varas darbu tavā vidū, bāriņus un atraitnes tie apspiež pie tevis.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Manus svētumus tu nicini, un Manas svētās dienas tu sagāni.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Mēlneši ir pie tevis, kas asinis izlej; tie ēd tavā vidū uz (elku)kalniem, dara bezkaunību tavā vidū.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 Tie atsedz pie tevis tēva kaunumu, un pieguļ pie tevis sārņiem nešķīstas sievas.
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 Cits ar sava tuvāka sievu dara negantību, cits bezkaunīgi apgāna savu vedeklu, atkal cits atzīst savu māsu, sava tēva meitu, tavā vidū.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 Tie ņem pie tevis dāvanas, izliet asinis; tu piedzen augļus un plēs pagaidus, un esi plēsīga pie sava tuvākā ar varasdarbu, bet Mani tu esi aizmirsusi, saka Tas Kungs Dievs.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 Redzi, tad Es sasitu savas rokas par to mantu, ko tu plēsi, un par tām asinīm, kas tavā vidū izlietas.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Vai tava sirds pastāvēs, vai tavas rokas būs stipras tanīs dienās, kad Es ar tevi tiesāšos? Es Tas Kungs to esmu runājis un to darīšu.
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 Un Es tevi izkaisīšu starp tautām un tevi izklīdināšu pa valstīm un darīšu galu tavai nešķīstībai tavā vidū.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 Un tu būsi nesvēta caur sevi pašu priekš pagānu acīm un samanīsi, ka Es esmu Tas Kungs.
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 Un Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 Cilvēka bērns! Israēla nams Man ir palicis par sārņiem, tie visi ir varš un alva un dzelzs un svins ceplī, tie ir palikuši par sudraba sārņiem.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 Tādēļ tā saka Tas Kungs Dievs: Tāpēc ka jūs visi esat palikuši par sārņiem, tad redzi, Es jūs sapulcināšu Jeruzālemes vidū.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Tā kā sudrabu un varu un dzelzi un svinu un alvu kopā liek ceplī, un uguni uzpūš apakšā, lai kausē, tā Es jūs sapulcināšu Savā dusmībā un bardzībā, un jūs ielikšu un kausēšu.
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Tiešām, Es jūs sapulcināšu un uzpūtīšu pret jums Savas dusmības uguni, ka jūs tur iekšā topat kausēti.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Tā kā sudrabs ceplī top kausēts, tāpat jūs tur tapsiet kausēti, un jūs samanīsiet, ka Es, Tas Kungs, Savu bardzību esmu izlējis pār jums.
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 Un Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 Cilvēka bērns, saki uz to: tu esi zeme, kas nav šķīstīta, kur nelīst dusmības dienā.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Viņas pravieši cēluši dumpi viņas vidū; tā kā rūcošs lauva, kad tas laupījumu laupa, tā tie ēd dvēseles, tie plēš naudu un mantu, tie dara daudz atraitņu viņas vidū.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Viņas priesteri neganti pārkāpj manu bauslību un sagāna manus svētumus, tie neizšķir svētu un nesvētu un nemāca izšķirt, kas šķīsts un kas nešķīsts, tie apsedz savas acis priekš manām, svētām dienām, un es viņu starpā topu sagānīts.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Viņas virsnieki ir viņas vidū kā vilki, kas laupa laupījumu, izlej asinis, samaitā dvēseles, mantas kārības dēļ.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 Un viņas pravieši tos apmet ar nelīpamiem kaļķiem un redz aplamas parādīšanas un sludina tiem melus un saka: tā saka Tas Kungs Dievs; un tomēr Tas Kungs nav runājis.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Tie ļaudis tai zemē dara varas darbu un laupīt laupa, un nabagu un bēdīgu tie plēš un svešinieku tie nospaida bez tiesas.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 Tad Es meklēju kādu vīru no tiem, kas atkal sataisītu sētu un stātos plaisumā, manā priekšā aizstāvēt to zemi, ka Es to nemaitātu, bet Es neatradu neviena.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 Tāpēc Es pār tiem esmu izlējis Savu bardzību, ar Savas dusmības uguni Es tiem esmu galu darījis, viņu grēkus Es tiem esmu metis uz viņu galvu, saka Tas Kungs Dievs.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ecechiela 22 >