< Ecechiela 2 >

1 Un Viņš sacīja uz mani: Cilvēka bērns, stājies kājās, tad Es ar tevi runāšu.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
2 Un kad Viņš uz mani runāja, tad nāca gars iekš manis un cēla mani kājās, un es dzirdēju To, kas uz mani runāja.
Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
3 Un Viņš sacīja uz mani: Cilvēka bērns, Es tevi sūtu pie Israēla bērniem, pie tiem stūrgalvīgiem ļaudīm, kas sacēlušies pret Mani; viņi un viņu tēvi no Manis atkāpušies līdz šai pašai dienai.
Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
4 Un tie bērni ir stūrgalvji un cietām sirdīm: Es tevi sūtu pie tiem, un tev būs uz tiem sacīt: tā saka Tas Kungs Dievs.
Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
5 Un vai tie klausa, vai neklausa - jo tie ir pārgalvju suga - taču tiem būs zināt, ka pravietis ir viņu vidū.
Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
6 Bet tu, cilvēka bērns, nebīsties no tiem un nebīsties no viņu vārdiem: jebšu dadži un ērkšķi ap tevi, un tu dzīvo pie skorpioniem, tomēr nebīsties no viņu vārdiem un neiztrūksties no viņu vaiga; jo tie ir atkāpēju suga.
Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
7 Un tev būs Manus vārdus uz tiem runāt, vai tie klausa, vai neklausa; jo tie ir stūrgalvji.
Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
8 Bet tu, cilvēka bērns, klausi, ko es tev saku: neesi neklausīgs, tā kā tā nepaklausīgā tauta. Atver savu muti un ēd, ko es tev dodu.
Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
9 Tad es redzēju, un raugi, roka pret mani bija izstiepta, un redzi, iekš tās bija satīta grāmata.
Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
10 Un viņš to attaisīja manā priekšā, un tā bija aprakstīta iekšpusē un ārpusē, un tur bija uzrakstītas raudu dziesmas, nopūtas un vaimanas.
ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.

< Ecechiela 2 >