< Ecechiela 11 >

1 Un Gars mani pacēla un mani nesa pie Tā Kunga nama priekšējiem vārtiem, kas pret rītiem stāv; un redzi, pie vārtu durvīm bija divdesmit un pieci vīri, un viņu vidū es redzēju Jazaniju, Asura dēlu, un Platiju, Benajas dēlu, ļaužu virsniekus.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 Un Viņš uz mani sacīja: cilvēka bērns, šie ir tie vīri, kas netaisnību izdomā un dod ļaunu padomu šinī pilsētā.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 Tie saka: laiks vēl nav klāt, namus celt! Šī (pilsēta) ir tas pods un mēs tā gaļa.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Tāpēc sludini pret tiem, sludini, cilvēka bērns!
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 Tad Tā Kunga Gars krita uz mani un uz mani sacīja: runā: tā saka Tas Kungs: jūs, ak Israēla nams, sakāt tā, jo Es zinu, kādas domas jums nāk prātā.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Varen daudz ir to, ko esat nokāvuši šinī pilsētā, un viņas ielas jūs esat pildījuši ar nokautiem.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Tādēļ Tas Kungs Dievs tā saka: jūsu nokautie, ko jūs viņas vidū esat nogāzuši, tie ir tā gaļa, un šī ir tas pods, bet jūs no viņas vidus izvedīs ārā.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 Jūs bīstaties no zobena, un zobenu Es vedīšu pār jums, saka Tas Kungs Dievs.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Es jūs no viņas vidus izvedīšu ārā un jūs nodošu svešiem rokā un nesīšu jums tiesu.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 Jūs kritīsiet caur zobenu, Es jūs sodīšu pie Israēla robežām, un jūs samanīsiet, ka Es esmu Tas Kungs.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 Šī (pilsēta) jums nebūs par podu, un jūs nebūsiet par gaļu viņas vidū; pie Israēla robežām Es jūs gribu sodīt.
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 Un jūs samanīsiet, ka Es esmu Tas Kungs, tāpēc ka neesat staigājuši Manos likumos nedz darījuši Manas tiesas, bet turējušies pēc pagānu tiesām, kas jums visapkārt.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 Un notikās, kad es sludināju, tad Platija, Benajas dēls, nomira. Tad es kritu uz savu vaigu un brēcu ar stipru balsi un sacīju: Ak Kungs Dievs, vai tu pavisam galu darīsi Israēla atlikušiem?
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 Tad Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 Cilvēka bērns, tie ir tavi brāļi, tavi brāļi, tavi radi, un viss Israēla nams visnotaļ ir tie, uz ko Jeruzālemes iedzīvotāji saka: atkāpjaties tālu no Tā Kunga, šī zeme mums ir dota par mantību.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 Tādēļ saki: tā saka Tas Kungs Dievs: jebšu Es tos tālu esmu aizvedis starp tautām un tos izkaisījis pa valstīm: taču Es par mazu brīdi tiem būšu par svētumu tanīs valstīs, kur tie nākuši.
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 Tādēļ saki: tā saka Tas Kungs Dievs: tiešām, Es jūs sapulcināšu no tām tautām un jūs salasīšu no tām valstīm, kur esat izkaisīti, un Es jums došu Israēla zemi.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 Un tie nāks uz turieni un ņems visus viņas gānekļus un visas viņas negantības no tās nost.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 Un Es tiem došu vienādu sirdi un Es jums došu jaunu garu, un atņemšu to akmens sirdi no viņu miesām un tiem došu miesīgu sirdi,
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 Lai tie staigā Manos likumos un sarga Manas tiesas un tās dara, un tie Man būs par ļaudīm, un Es tiem būšu par Dievu.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 Bet tiem, kam sirds pēc savu gānekļu un neganto elku prāta dzenās, tiem Es viņu grēkus metīšu uz viņu galvu, saka Tas Kungs Dievs.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 Tad tie ķerubi pacēla savus spārnus un tie skrituļi bija viņiem sānis, un Israēla Dieva godība bija virsū pār tiem.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 Un Tā Kunga godība cēlās no pilsētas vidus un nostājās uz tā kalna, kas pilsētai pret rītiem.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 Tad Gars mani pacēla un mani aizveda parādīšanā un caur Dieva Garu uz Kaldeju pie tiem aizvestiem, un tā parādīšana, ko es biju redzējis, no manis nozuda.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 Un es tiem aizvestiem runāju visus Tā Kunga vārdus, ko Viņš man bija parādījis.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.

< Ecechiela 11 >