< Otra Mozus 6 >

1 Tad Tas Kungs sacīja uz Mozu: nu tev būs redzēt, ko Es Faraonam darīšu, jo caur stipru roku viņam tos būs atlaist, un caur stipru roku viņam tos būs izdzīt no savas zemes.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
2 Un Dievs runāja ar Mozu un uz to sacīja: Es esmu Tas Kungs.
Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
3 Un Es esmu parādījies Ābrahāmam, Īzakam un Jēkabam, kā tas visuvarenais Dievs, bet Mans vārds “Kungs” viņiem nav bijis zināms.
Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
4 Es arī esmu uzcēlis Savu derību ar tiem, tiem dot Kanaāna zemi, to zemi, kur viņi piemituši, kur tie bijuši svešinieki.
Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
5 Es arī esmu dzirdējis Israēla bērnu nopūtas, ko ēģiptieši kalpina, un esmu pieminējis Savu derību.
Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
6 Tāpēc saki Israēla bērniem: Es esmu Tas Kungs un jūs izvedīšu no Ēģiptes nastām un jūs izraušu no viņu kalpošanas un jūs atpestīšu ar izstieptu roku un ar lielām sodībām.
“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
7 Un Es jūs pieņemšu par Saviem ļaudīm un jums būšu par Dievu, un jūs atzīsiet, ka Es esmu Tas Kungs, jūsu Dievs, kas jūs izvedis no Ēģiptes nastām.
Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
8 Un Es jūs ievedīšu tai zemē, par ko Es Savu roku esmu uzcēlis, to dot Ābrahāmam, Īzakam un Jēkabam, un došu jums to par īpašumu, Es, Tas Kungs.
Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
9 Un Mozus runāja tā uz Israēla bērniem; bet tie Mozum neklausīja aiz sirdēstiem un grūtiem darbiem.
Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
10 Un Tas Kungs runāja uz Mozu sacīdams:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
11 Ej, runā uz Faraonu, Ēģiptes ķēniņu, ka tam Israēla bērnus būs izlaist no savas zemes.
“Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
12 Un Mozus runāja Tā Kunga priekšā un sacīja: redzi, Israēla bērni man neklausa, kā tad Faraons man klausītu? Un man ir arī neapgraizītas lūpas.
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
13 Un Tas Kungs runāja uz Mozu un Āronu, un tos sūtīja ar pavēli pie Israēla bērniem un pie Faraona, Ēģiptes ķēniņa, Israēla bērnus izvest no Ēģiptes zemes.
Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
14 Šie ir viņu tēvu namu galvinieki: Rūbena, Israēla pirmdzimtā, bērni: Hanoks un Pallus, Hecrons un Karmus; šie ir Rūbena dzimumi.
Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
15 Un Sīmeana bērni: Jemuels un Jamins un Oāds un Jakins un Coārs un Sauls, vienas Kanaānietes dēls, šie ir Sīmeana dzimumi.
Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
16 Un šie ir Levja bērnu vārdi pēc viņu radiem: Geršons un Kehāts un Merarus. Un Levja dzīvības laiks bija simts trīsdesmit un septiņi gadi.
Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
17 Geršona bērni: Libnus un Šimejus pēc viņu dzimumiem.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
18 Un Kehāta bērni: Amrams un Jecears un Hebrons un Uzijels. Un Kehāta dzīvības laiks bija simts trīsdesmit un trīs gadi.
Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
19 Merarus bērni: Maēlus un Muzus; šie ir Levja dzimumi pēc viņu radiem.
Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
20 Un Amrams ņēma par sievu Joķebedu, sava tēva māsu, un tā viņam dzemdēja Āronu un Mozu. Un Amrama dzīvības laiks bija simts trīsdesmit un septiņi gadi.
Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
21 Un Jeceara bērni: Korahs un Nevegs un Sihrus.
Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
22 Un Uzijeļa bērni: Mišaēls un Elcavans un Zitrus.
Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
23 Un Ārons ņēma sev par sievu Elizebu, Aminadaba meitu, Naāsana māsu, un tā viņam dzemdēja Nadabu un Abiju un Eleazaru un Ītamaru.
Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
24 Un Koraha bērni: Asirs un Elkanus un AbiAsafs; šie ir Koriešu dzimumi.
Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
25 Un Eleazars, Ārona dēls, ņēma sev sievu no Putijeļa meitām; un tā viņam dzemdēja Pinehasu. Šie ir Levitu tēvu namu galvinieki pēc viņu dzimumiem.
Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
26 Šis ir tas Ārons un Mozus, kam Tas Kungs sacīja: izvediet Israēla bērnus no Ēģiptes zemes ar viņu pulkiem.
Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
27 Šie ir, kas uz Faraonu, Ēģiptes ķēniņu, runāja, izvest Israēla bērnus no Ēģiptes zemes, proti Mozus un Ārons.
Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
28 Un tai dienā, kad Tas Kungs runāja uz Mozu Ēģiptes zemē,
Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
29 Tad Viņš runāja uz Mozu un sacīja: Es esmu Tas Kungs, - runā uz Faraonu, Ēģiptes ķēniņu, visu, ko Es uz tevi runāju.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
30 Tad Mozus sacīja Tā Kunga priekšā: redzi, man ir neapgraizītas lūpas, kā tad Faraons mani klausīs?
Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

< Otra Mozus 6 >