< Piektā Mozus 31 >
1 Tad Mozus nogāja un runāja šos vārdus uz visu Israēli,
Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
2 Un uz tiem sacīja: šodien es esmu simts un divdesmit gadus vecs; es nevarēšu vairs ne iziet ne ieiet, un Tas Kungs uz mani sacījis: tev nebūs iet pāri pār šo Jardāni.
“Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
3 Tas Kungs, tavs Dievs, Tas ies pats tavā priekšā pāri, Tas izdeldēs šīs tautas tavā priekšā, ka tu tās iemanto; Jozuas, tas ies pāri tavā priekšā, kā Tas Kungs runājis.
Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
4 Un Tas Kungs viņiem darīs, kā Viņš darījis Sihonam un Ogam, Amoriešu ķēniņiem, un viņu zemei, ko Viņš izdeldējis.
Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
5 Kad nu Tas Kungs tos nodos jūsu priekšā, tad jums tiem būs darīt pēc visām pavēlēm, ko es jums esmu pavēlējis.
Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
6 Esat stipri un turat drošu prātu, nebīstaties un nebaiļojaties priekš viņiem, jo Tas Kungs, tavs Dievs, Tas tev iet līdz; Viņš tevi neatstās, nedz tevi pametīs.
Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
7 Un Mozus aicināja Jozua un sacīja uz viņu visa Israēla priekšā: esi stiprs un turi drošu prātu, jo tu ieiesi ar šiem ļaudīm tai zemē, ko Tas Kungs viņu tēviem ir zvērējis, viņiem dot, un tev to būs viņiem izdalīt.
Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
8 Tas Kungs, Tas iet tavā priekšā, Viņš būs ar tevi, Viņš tevi neatstās, nedz tevi pametīs, nebīsties un nebaiļojies.
Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
9 Un Mozus uzrakstīja to bauslību un to deva tiem priesteriem, Levja dēliem, kas nesa Tā Kunga derības šķirstu, un visiem Israēla vecajiem.
Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
10 Un Mozus tiem pavēlēja un sacīja: ik septītā gadā, atlaišanas gada laikā, lieveņu svētkos,
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
11 Kad viss Israēls nāks rādīties Tā Kunga, tava Dieva, priekšā, tai vietā, ko Viņš izredzēs, tad tev šo bauslību būs priekšā lasīt visam Israēlim viņu ausīs.
Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
12 Sapulcini tos ļaudis, vīrus un sievas un bērniņus un savus piedzīvotājus, kas tavos vārtos, lai tie dzird un mācās un bīstas To Kungu, jūsu Dievu, un tur un dara visus šīs bauslības vārdus,
Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
13 Un lai viņu bērni, kas to nezina, dzird un mācās bīties To Kungu, jūsu Dievu, visu to laiku, kamēr jūs dzīvosiet tai zemē, ko iemantot jūs ejat pār Jardāni.
Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
14 Un Tas Kungs sacīja uz Mozu: redzi, tavs laiks ir klāt, ka jāmirst; aicini Jozua, un ejat saiešanas teltī, lai Es viņam pavēlu. Tad Mozus un Jozuas gāja un nostājās saiešanas teltī.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
15 Tad Tas Kungs tai teltī parādījās padebeša stabā, un tas padebeša stabs stāvēja saiešanas telts durvīs.
Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
16 Un Tas Kungs sacīja uz Mozu: redzi, tu dusēsi pie saviem tēviem, un šie ļaudis celsies un maukos pakaļ tās zemes svešiem dieviem, kur tie nāks dzīvot, un atstās Mani un atmetīs Manu derību, ko Es ar tiem esmu derējis,
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
17 Tai dienā Mana bardzība pret tiem iedegsies, un Es tos atstāšu un paslēpšu Savu vaigu no viņiem, ka tie top aprīti, un daudz ļaunuma un daudz bēdu viņiem uzies, ka tie tai dienā sacīs: vai šis ļaunums man nav uzgājis tāpēc, ka mans Dievs nav mūsu vidū?
Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
18 Bet Es paslēpšu Savu vaigu tai dienā visa ļaunuma dēļ, ko tie ir darījuši, nogriezdamies pie citiem dieviem.
Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
19 Un nu uzrakstiet sev šo dziesmu un māci to Israēla bērniem un ieliec to viņu mutē, ka šī dziesma Man ir par liecību pret Israēla bērniem.
“Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
20 Jo Es tos ievedīšu tai zemē, ko esmu zvērējis viņu tēviem, kur piens un medus tek, un kad tie ēdīs un būs paēduši un paliks trekni, tad tie nogriezīsies pie citiem dieviem un tiem kalpos un Mani apkaitinās un atmetīs Manu derību.
Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
21 Un kad daudz ļaunuma un daudz bēdu tiem uzies, tad šī dziesma tiem atbildēs un būs par liecību, jo tā netaps aizmirsta viņu dzimuma mutē. Jo Es zinu viņu domas, kas tiem jau šodien ir, pirms Es tos esmu ievedis tai zemē, ko tiem esmu zvērējis.
Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
22 Tad Mozus uzrakstīja šo dziesmu tai dienā un to mācīja Israēla bērniem.
Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
23 Un Viņš pavēlēja Jozuam, Nuna dēlam, un sacīja: esi stiprs un turi drošu prātu, jo tu ievedīsi Israēla bērnus tai zemē, ko Es viņiem esmu zvērējis, un Es būšu ar tevi.
Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
24 Un kad Mozus bija pabeidzis līdz pat galam sarakstīt šās bauslības vārdus grāmatā,
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
25 Tad Mozus pavēlēja tiem Levitiem, kas Tā Kunga derības šķirstu nesa, sacīdams:
ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
26 Ņemiet šo bauslības grāmatu un noliekat to blakām Tā Kunga, sava Dieva, derības šķirstam, lai viņa tur ir par liecību pret tevi.
“Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
27 Jo es pazīstu tavu nepaklausību un tavu stūrgalvību. Redzi, šodien kamēr es vēl esmu dzīvs jūsu vidū, jūs esat neklausīgi pret To Kungu, - cik vairāk, kad es būšu nomiris!
Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
28 Sapulcējiet pie manis visus savus cilšu vecajus un savus priekšniekus, lai es runāju šos vārdus priekš viņu ausīm un pret tiem piesaucu par lieciniekiem debesis un zemi.
Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
29 Jo es zinu, ka pēc manas nāves jūs visai(pilnīgi) apgrēkosities un atkāpsities no tā ceļa, ko es jums esmu pavēlējis; tad jums tas ļaunums uzies nākamā laikā, kad jūs darīsiet, kas ļauns Tā Kunga acīs, viņu apkaitinādami ar savu rokas darbu.
Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
30 Tad Mozus runāja priekš visas Israēla draudzes ausīm šīs dziesmas vārdus līdz pat galam.
Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli: