< Piektā Mozus 21 >

1 Kad atrod kādu nokautu tai zemē, ko Tas Kungs, tavs Dievs, tev dos iemantot, un tas guļ uz lauka, un neviens nezin, kas to nokāvis,
Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
2 Tad taviem vecajiem un taviem soģiem būs iziet ārā un mērot līdz tām pilsētām, kas ir ap to nokauto.
àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
3 Kura pilsēta nu tam nokautam tā tuvākā, tās pilsētas vecaji lai ņem no liellopiem teli, ar ko vēl nav strādāts, kas nekādu jūgu vēl nav vilkusi.
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
4 Un tās pilsētas vecajiem būs novest to teli tekošas upes ielejā, kur netop ne strādāts, ne sēts, un tiem tur upes ielejā tai telei būs lauzt kaklu.
kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
5 Tad priesteriem, Levja bērniem, būs pieiet, jo Tas Kungs, tavs Dievs, tos ir izredzējis, Viņam kalpot un svētīt Tā Kunga Vārdā, un lai pēc viņu vārdiem ikviena ķilda un ikviena vaina top izlīdzināta.
Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
6 Un visiem šīs pilsētas vecajiem, kas tam nokautam ir tie tuvākie, būs mazgāt savas rokas pār to teli, kam kakls lauzts upes ielejā.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
7 Un tiem būs dot liecību un sacīt: mūsu rokas nav izlējušas šās asinis un mūsu acis nav redzējušas.
wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
8 Piedod Saviem Israēla ļaudīm, ko Tu, Kungs, esi atpestījis, un nepielīdzini nenoziedzīgas asinis Saviem Israēla ļaudīm - tad tie būs salīdzināti par šīm asinīm.
Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
9 Tā Tu izdeldēsi tās nenoziedzīgās asinis no Sava vidus, darīdams, kas ir tiesa Tā Kunga acīs. -
Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
10 Kad tu iesi karā pret saviem ienaidniekiem, un Tas Kungs viņus nodos tavā rokā, ka tu gūstītus no viņiem pārvedi cietumā,
Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
11 Un tu redzēsi starp tiem gūstītiem skaistu sievu, un tu viņas iegribies un to ņem sev par sievu,
tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
12 Tad tev to būs vest savā namā un lai viņa savu galvu apcērp un savus nagus apgraiza,
Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
13 Un noliek savas cietuma drēbes un sēž tavā namā un apraud savu tēvu un savu māti vienu mēnesi un pēc tam ej pie viņas un esi viņai par vīru, un viņa lai ir tev par sievu.
kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
14 Un ja viņa tev nepatīk, tad atlaid viņu, kur viņa grib, bet par naudu tev to nebūs pārdot, nedz turēt verdzībā, tāpēc ka tu to esi pazemojis.
Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
15 Kad kādam vīram ir divas sievas, viena mīlēta un otra neieredzēta, un tā mīlētā kā tā neieredzētā dzemdē viņam dēlus, un tas pirmdzimtais ir no tās neieredzētās, -
Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
16 Un kad viņš saviem dēliem savu mantu dalīs, tad tās mīlētās dēlu viņš nevar uzņemt par pirmdzimto, tās neieredzētās dēla vietā, kas tas pirmdzimtais.
Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
17 Bet viņam būs atzīt tās neieredzētās dēlu par pirmdzimto, un tam dot divkārtīgu tiesu no visa, kas tam ir; jo tas ir viņa spēka pirmdzimtais, - tam pieder pirmdzimtības tiesa. -
Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
18 Kad kādam vīram ir stūrgalvīgs un neklausīgs dēls, kas neklausa sava tēva un savas mātes balsij, un tie viņu ir pārmācījuši, un viņš tomēr tiem neklausa,
Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
19 Tad viņa tēvam un mātei to būs sagrābt un izvest pie savas pilsētas vecajiem un pie savas pilsētas vārtiem,
baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
20 Un tiem būs sacīt uz savas pilsētas vecajiem: šis mūsu dēls ir stūrgalvīgs un neklausīgs, viņš neklausa mūsu balsij, viņš ir rijējs un dzērājs.
Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
21 Tad visiem viņa pilsētas ļaudīm to būs akmeņiem nomētāt, ka mirst. Tā tev būs izdeldēt to ļaunumu no tava vidus, ka viss Israēls to dzird un bīstas. -
Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
22 Un ja kas darījis kādu grēku, ar ko tas nāvi pelnījis, un top nonāvēts un tu to pakar pie koka,
Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
23 Tad lai viņa miesas nepaliek par nakti pie koka, bet aproc tās tai pašā dienā; jo tas pakārtais ir Dieva lāsts; tā tev šo zemi nebūs apgānīt, ko Tas Kungs, tavs Dievs, tev dod par īpašumu.
o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.

< Piektā Mozus 21 >