< Piektā Mozus 11 >

1 Tad nu tev būs mīlēt To Kungu, savu Dievu, un turēt Viņa baušļus un Viņa likumus un Viņa tiesas un Viņa pavēles visu mūžu.
Ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ sì pa ìfẹ́ rẹ̀, ìlànà rẹ̀, òfin rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ ní ìgbà gbogbo.
2 Un jums būs šodien zināt, ka es nerunāju ar jūsu bērniem, kas to nezin un kas nav redzējuši Tā Kunga, jūsu Dieva, pārmācīšanu, Viņa lielo spēku, Viņa stipro roku un Viņa izstiepto elkoni,
Ẹ rántí lónìí pé, kì í ṣe àwọn ọmọ yín, ni ó rí ìbáwí Olúwa Ọlọ́run yín; títóbi rẹ̀, ọwọ́ agbára rẹ̀, nína ọwọ́ rẹ̀;
3 Un Viņa zīmes un Viņa darbus, ko Viņš darījis Ēģiptē pie Faraona, Ēģiptes ķēniņa, un pie visas viņa zemes,
iṣẹ́ àmì rẹ̀ àti ohun tí ó ṣe ní àárín àwọn ará Ejibiti, sí Farao ọba Ejibiti àti gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ̀.
4 Un ko Viņš darījis pie Ēģiptes kara spēka, pie viņa zirgiem un pie viņa ratiem, ka Viņš ūdenim Niedras jūrā lika pār tiem gāzties, kad tie jums dzinās pakaļ, un Tas Kungs tos izdeldēja līdz šai dienai;
Ohun tí ó ṣe sí àwọn jagunjagun Ejibiti, sí kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin rẹ̀: bí ó ṣe rì wọ́n sínú Òkun Pupa, bí wọ́n ṣe ń lé e yín tí Olúwa fi pa wọ́n run pátápátá títí di òní olónìí yìí.
5 Un ko Viņš jums darījis tuksnesī, tiekams jūs esat nākuši šai vietā;
Kì í ṣe àwọn ọmọ yín ni ó rí ohun tí ó ṣe fún un yín ní aginjù, títí ẹ fi dé ìhín yìí,
6 Un ko Viņš darījis Datanam un Abiramam, Eliaba, Rūbena dēla, dēliem, ka zeme atdarīja savu muti un tos aprija ar viņu padomu, kas tiem piederēja visa Israēla vidū.
ohun tí ó ṣe sí Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ẹ̀yà Reubeni, bí ilẹ̀ ti lanu ní ojú gbogbo ará Israẹli tí ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ìdílé wọn, gbogbo àgọ́ ọ wọn àti gbogbo ohun alààyè tí ó jẹ́ tiwọn.
7 Jo jūsu acis ir redzējušas visu šo lielo darbu, ko Tas Kungs darījis.
Ṣùgbọ́n ojú u yín gan an ni ó rí gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí tí Olúwa ti ṣe.
8 Tad nu turiet visus tos baušļus, ko es tev šodien pavēlu, ka jūs topat stipri un nākat un uzņemat to zemi, ko jūs ejat iemantot,
Nítorí náà, ẹ kíyèsi gbogbo àṣẹ tí mo ń fún yín lónìí, kí ẹ ba à lè lágbára àti lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí ẹ ó la Jordani kọjá lọ.
9 Ka jūs ilgi dzīvojat tai zemē, ko Tas Kungs jūsu tēviem zvērējis, dot viņiem un viņu dzimumam, zemi, kur piens un medus tek.
Kí ẹ ba à lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa ti búra fún àwọn baba ńlá a yín, láti fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn: ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
10 Jo tā zeme, uz kurieni tu ej to iemantot, nav kā Ēģiptes zeme, no kurienes jūs esat izgājuši, ko tu apsēji ar savu sēklu un pats aplaistīji, tā kā kāpostu dārzu, -
Ilẹ̀ tí ẹ̀ ń wọ̀ lọ láti gbà kò rí bí ilẹ̀ Ejibiti, níbi tí ẹ ti wá, níbi tó jẹ́ wí pé ẹsẹ̀ yín ni ẹ fi ń rìn lọ bomirin irúgbìn tí ẹ gbìn bí oko ẹ̀fọ́.
11 Bet tā zeme, ko jūs ejat iemantot, ir zeme ar kalniem un ielejām, tā top slacīta ar ūdeni no debess lietus,
Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí ẹ ó la Jordani kọjá láti gbà, jẹ́ ilẹ̀ olókè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ tí òjò ń rọ̀ sí latọ̀run.
12 Zeme, ko Tas Kungs, tavs Dievs, apgādā, uz ko Tā Kunga, tava Dieva, acis skatās bez mitēšanās no gada iesākuma līdz gada galam.
Ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń mójútó ni, ojú Olúwa Ọlọ́run yín sì ń fi ìgbà gbogbo wà lórí rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún dé òpin ọdún.
13 Un ja jūs labi klausīsiet Maniem baušļiem, ko Es jums šodien pavēlu un mīlēsiet To Kungu, savu Dievu, un Viņam kalposiet no visas savas sirds un no visas savas dvēseles,
Nítorí náà, bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ tí mo fún un yín lónìí tọkàntọkàn: tí ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì sìn ín, pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn yín:
14 Tad Es došu lietu jūsu zemē savā laikā, agri un vēlu, ka tu vari sakrāt savu labību un savu vīnu un savu eļļu.
nígbà náà, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ ẹ yín lákòókò rẹ̀, àti òjò àkọ́rọ̀ àti ti àrọ̀kẹ́yìn, kí ẹ ba à lè kórè oúnjẹ yín wọlé àní wáìnì tuntun àti òróró.
15 Un Es došu zāli tavā laukā taviem lopiem, un tu ēdīsi un būsi paēdis.
Èmi yóò mú kí koríko hù lórí ilẹ̀ yín fún àwọn ohun ọ̀sìn in yín, ẹ ó sì jẹ, ẹ ó sì yó.
16 Sargājaties, ka jūsu sirds netop pārrunāta, atkāpties un kalpot citiem dieviem un tos pielūgt;
Ẹ ṣọ́ra, kí a má ba à tàn yín jẹ láti yípadà kí ẹ sì sin ọlọ́run mìíràn àti láti máa foríbalẹ̀ fún wọn.
17 Tā ka Tā Kunga bardzība neiedegās pret jums un neaizslēdz debesi, ka lietus nenāk un zeme nedod savus augļus, un ka jūs ātri neejat bojā no tās labās zemes, ko Tas Kungs jums dod.
Nígbà náà ni ìbínú Olúwa yóò sì ru sí i yín, Òun yóò ti ìlẹ̀kùn ọ̀run kí òjò má ba à rọ̀, ilẹ̀ kì yóò sì so èso kankan, ẹ ó sì ṣègbé ní ilẹ̀ rere tí Olúwa fi fún un yín.
18 Ieliekat tad šos Manus vārdus savā sirdī un savā dvēselē un sienat tos par zīmi uz savām rokām, un ka tie ir par piemiņas zīmēm starp jūsu acīm,
Ẹ fi gbogbo ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí sí àyà a yín, àti ọkàn an yín, ẹ so wọ́n bí àmì sórí ọwọ́ yín, kí ẹ sì so wọ́n mọ́ iwájú orí yín.
19 Un mācat tos saviem bērniem, ka tu no tiem runā savā namā sēžot un savu ceļu staigājot, ir apguļoties, ir ceļoties;
Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín, ẹ máa sọ̀rọ̀ nípa wọn bí ẹ bá jókòó nínú ilé, àti ní ojú ọ̀nà bí ẹ bá ń rìn lọ, bí ẹ bá sùn àti bí ẹ bá jí.
20 Un raksti tos uz sava nama stenderes un pie saviem vārtiem, -
Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
21 Lai jūsu dienas un jūsu bērnu dienas top vairotas tai zemē, ko Tas Kungs jūsu tēviem zvērējis, tiem to dot, kamēr būs debess un zeme.
Kí ọjọ́ ọ yín àti ti àwọn ọmọ yín lè pọ̀ ní ilẹ̀ tí Olúwa ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá a yín, ní ìwọ̀n ìgbà tí ọ̀run wà lókè tí ayé sì ń bẹ ní ìsàlẹ̀.
22 Jo ja jūs turēsiet visus šos baušļus, ko Es jums pavēlu turēt, mīļodami To Kungu, savu Dievu, un staigādami visos Viņa ceļos un Viņam pieķerdamies,
Bí ẹ bá fi ara balẹ̀ kíyèsi àwọn òfin tí mo ń fún un yín, láti tẹ̀lé, láti fẹ́ Olúwa Ọlọ́run yín, láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti láti dìímú ṣinṣin:
23 Tad Tas Kungs izdzīs visas šīs tautas jūsu priekšā, un jūs uzņemsiet lielākas un stiprākas tautas, nekā jūs esat.
Olúwa yóò sì lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí kúrò níwájú u yín. Ẹ ó sì gba orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì tóbi jù yín lọ.
24 Visas vietas, kurp jūsu kāja staigās, jums piederēs, no tuksneša un Lībanus, no Eifrat upes līdz vakara jūrai būs jūsu robeža.
Gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀ ni yóò jẹ́ tiyín, ilẹ̀ ẹ yín yóò gbilẹ̀ láti aginjù dé Lebanoni, àti láti odò Eufurate dé Òkun Ńlá.
25 Neviens priekš jums nepastāvēs; Tas Kungs, jūsu Dievs, darīs, ka no jums iztrūcināsies un bīsies visa tā zeme, kur jūs staigāsiet, kā Viņš uz jums runājis.
Kò sí ẹni náà tí yóò lè kò yín lójú ìjà, Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi ẹ̀rù àti ìwárìrì i yín sórí gbogbo ilẹ̀ náà bí ó ti ṣèlérí fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá lọ.
26 Redzi, es jums šodien ceļu priekšā svētību un lāstu, -
Ẹ kíyèsi i, mo fi ìbùkún àti ègún lélẹ̀ níwájú u yín lónìí:
27 Svētību, ja jūs klausīsiet Tā Kunga, sava Dieva, baušļiem, ko es šodien jums pavēlu,
ìbùkún ni, bí ẹ bá pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
28 Bet lāstu, ja jūs neklausīsiet Tā Kunga, sava Dieva, baušļiem un atkāpsities no tā ceļa, ko es jums šodien pavēlu, staigājot citiem dieviem pakaļ, ko jūs nepazīstat.
Ègún ni, bí ẹ bá ṣàìgbọ́ràn, sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì yapa kúrò ní ọ̀nà tí mo ti là sílẹ̀ fún yín lónìí, nípa títẹ̀lé ọlọ́run mìíràn, tí ẹ kò tí ì mọ̀.
29 Un kad Tas Kungs, tavs Dievs, tevi ievedīs tai zemē, ko tu ej iemantot, tad tev būs izsaukt to svētību uz Gerizim kalna un to lāstu uz Ebal kalna.
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti mú un yín dé ilẹ̀ náà tí ẹ ń wọ̀ láti gbà, kí ẹ kéde àwọn ìbùkún náà ní orí òkè Gerisimu, kí ẹ sì kéde àwọn ègún ní orí òkè Ebali.
30 Vai tie nav viņpus Jardānes, aiz tā ceļa pret saules noiešanu, Kanaāniešu zemē, kas klajumā dzīvo pret Gilgalu, sānis Mores ozoliem?
Bí ẹ ti mọ̀ pé àwọn òkè wọ̀nyí wà ní ìkọjá a Jordani ní apá ìwọ̀-oòrùn lójú ọ̀nà lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó More, ní ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, tí wọ́n ń gbé ní aginjù, ni agbègbè Gilgali.
31 Jo jūs iesiet pāri pār Jardāni, to zemi iemantot, ko Tas Kungs, jūsu Dievs, jums dod, un jūs to iemantosiet un tur dzīvosiet.
Ẹ ti ṣetán láti la Jordani kọjá láti lè gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín. Nígbà tí ẹ bá gbà á, tí ẹ bá sì ń gbé ibẹ̀,
32 Tad nu turat un darāt visus likumus un visas tiesas, ko es jums šodien lieku priekšā.
ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà àti òfin tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.

< Piektā Mozus 11 >