< Piektā Mozus 10 >

1 Tanī laikā Tas Kungs sacīja uz mani: izcērt sev divus akmens galdiņus, kā tos pirmos, un uzkāp pie Manis kalnā; pēc tam taisi koka šķirstu.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Gbé wàláà òkúta méjì bí i ti àkọ́kọ́ kí o sì gòkè tọ̀ mí wá. Kí o sì tún fi igi kan àpótí kan.
2 Un Es uzrakstīšu uz tiem galdiņiem tos vārdus, kas bija uz tiem pirmiem galdiņiem, ko tu esi sasitis; tad liec tos tai šķirstā.
Èmi yóò sì kọ ọ̀rọ̀ tí ó wà lára wàláà àkọ́kọ́ tí ìwọ fọ́, sára wàláà wọ̀nyí. Ìwọ yóò sì fi wọ́n sínú àpótí náà.”
3 Tad es taisīju šķirstu no akācijas koka un izcirtu divus akmens galdiņus tā kā tos pirmos, un uzkāpu uz to kalnu, un tie divi galdiņi bija manā rokā.
Mo sì kan àpótí náà pẹ̀lú igi kasia, mo sì gbẹ́ wàláà òkúta méjì náà jáde bí i ti ìṣáájú. Mo sì gòkè lọ pẹ̀lú wàláà méjèèjì lọ́wọ́ mí.
4 Tad Viņš uz tiem galdiņiem uzrakstīja to pirmo rakstu, tos desmit vārdus, ko Tas Kungs kalnā uz jums bija runājis no uguns vidus sapulces dienā, un Tas Kungs man tos iedeva.
Olúwa tún ohun tí ó ti kọ tẹ́lẹ̀ kọ sórí wàláà wọ̀nyí. Àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó ti sọ fún un yín lórí òkè, láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀. Olúwa sì fi wọ́n fún mi.
5 Un es atgriezdamies nokāpu no tā kalna un liku tos galdiņus tai šķirstā, ko es biju taisījis, un tie tur ir, kā Tas Kungs man bija pavēlējis.
Mo sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà, mo sì ki àwọn wàláà òkúta náà sínú àpótí tí mo ti kàn, bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi, wọ́n sì wà níbẹ̀ di ìsinsin yìí.
6 Un Israēla bērni aizgāja no Berot Bnejakana līdz Mozeram; tur Ārons nomira un tapa tur aprakts, un viņa dēls Eleazars palika par priesteri viņa vietā.
(Àwọn ará Israẹli sì gbéra láti kànga àwọn ará Jaakani dé Mosera. Níbí ni Aaroni kú sí, tí a sì sin ín, Eleasari ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ bí i àlùfáà.
7 Un no turienes tie aizgāja līdz Gudgodam un no Gudgoda līdz Jatbatai; tā ir upēm bagāta zeme.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti rìn lọ sí Gudgoda, títí dé Jotbata, ilẹ̀ tí o kún fún odò tí ó ń sàn.
8 Tanī laikā Tas Kungs atšķīra Levja cilti, nest Tā Kunga derības šķirstu un stāvēt Tā Kunga priekšā, Viņam kalpot un svētīt Viņa vārdā līdz šai dienai.
Ní ìgbà yìí ni Olúwa yan àwọn ẹ̀yà Lefi láti máa ru àpótí ẹ̀rí Olúwa, láti máa dúró níwájú Olúwa láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, àti láti fi orúkọ Olúwa súre bí wọ́n ti ń ṣe títí di òní yìí.
9 Tādēļ Levja ciltij nav nekādas daļas nedz mantības ar saviem brāļiem; Tas Kungs ir viņa mantība, kā Tas Kungs tavs Dievs, uz viņu runājis.
Ìdí nìyí tí àwọn ẹ̀yà Lefi kò fi ní ìpín tàbí ogún kan láàrín àwọn arákùnrin wọn. Olúwa ni ogún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti sọ fún un yín.)
10 Un es stāvēju kalnā tā kā papriekš četrdesmit dienas un četrdesmit naktis, un Tas Kungs mani paklausīja arī to brīdi; Tas Kungs negribēja tevi izdeldēt.
Mo tún dúró ní orí òkè náà fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, bí mo ti ṣe ní ìgbà àkọ́kọ́, Olúwa sì gbọ́ tèmi ní àkókò yìí bákan náà. Kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ láti run yín.
11 Bet Tas Kungs uz mani sacīja: celies, ej, dodies ceļā ļaužu priekšā, ka tie nāk un uzņem to zemi, ko Es viņu tēviem esmu zvērējis, viņiem dot.
Olúwa sọ fún mi pé, “Lọ darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọ̀nà wọn, kí wọn bá à lè wọ ilẹ̀ náà, kí wọn sì gba ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba wọn láti fún wọn.”
12 Nu tad, Israēl, ko Tas Kungs tavs Dievs, no tevis prasa, kā vien bīties To Kungu, savu Dievu, staigāt visos Viņa ceļos un Viņu mīlēt un Tam Kungam, savam Dievam, kalpot no visas savas sirds un no visas savas dvēseles,
Nísinsin yìí ìwọ Israẹli, kín ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe kí ìwọ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ àti láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti fẹ́ràn rẹ̀, láti fi gbogbo ọkàn rẹ sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ọkàn àti àyà rẹ,
13 Turēt Tā Kunga baušļus un likumus, ko es tev šodien pavēlu, tev par labu?
àti láti máa kíyèsi àṣẹ àti ìlànà Olúwa tí mo ń fún ọ lónìí, fún ìre ara à rẹ.
14 Redzi, Tam Kungam, tavam Dievam, pieder debesis un debesu debesis, zeme un viss, kas iekš tās.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ni ọ̀run àní àwọn ọ̀run tó ga ju ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
15 Tomēr pie taviem tēviem vien Tam Kungam bijis labs prāts, viņus mīlēt, un Viņš ir izredzējis viņu dzimumu pēc viņiem, jūs pašus, no visiem ļaudīm, tā kā tas šodien ir.
Síbẹ̀ Olúwa sì tún fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn fún àwọn baba ńlá a yín, Ó sì fẹ́ wọn Ó sì yan ẹ̀yin ọmọ wọn láti borí gbogbo orílẹ̀-èdè títí di òní.
16 Apgraiziet tad savas sirds priekšādu un neesat vairs pārgalvīgi.
Ẹ kọ ọkàn yín ní ilà, kí ẹ má sì ṣe jẹ́ olórí kunkun mọ́ láti òní lọ.
17 Jo Tas Kungs, jūsu Dievs, ir tas dievu Dievs un tas kungu Kungs, stiprs Dievs, liels, varens un bīstams, kas vaigu neuzlūko un dāvanas neņem,
Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín, ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn olúwa. Ọlọ́run alágbára, tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, tí kì í ṣe ojúsàájú kì í sì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
18 Un tiesu nes bāriņiem un atraitnēm, un mīļo svešinieku un dod viņam maizi un drēbes.
Ó máa ń gbẹjọ́ aláìní baba àti opó rò, Ó fẹ́ràn àjèjì, Òun fi aṣọ àti oúnjẹ fún wọn.
19 Tāpēc mīļojiet to svešinieku, jo jūs esat bijuši svešinieki Ēģiptes zemē.
Ẹ gbọdọ̀ fẹ́ràn àwọn àjèjì, torí pé ẹ̀yin pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì rí ní Ejibiti.
20 To Kungu, savu Dievu, tev būs bīties, Viņam kalpot un Viņam pieķerties un pie Viņa vārda zvērēt.
Ẹ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ sì máa sìn ín. Ẹ dìímú ṣinṣin, kí ẹ sì búra ní orúkọ rẹ̀.
21 Viņš ir tava slava un Viņš ir tavs Dievs, kas pie tevis darījis šīs lielās un briesmīgās lietas, ko tavas acis redzējušas.
Òun ni ìyìn in yín, Òun sì ni Ọlọ́run yín, tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá àti ohun ẹ̀rù, tí ẹ fojú ara yín rí.
22 Tavi tēvi nogāja uz Ēģiptes zemi, septiņdesmit dvēseles, un nu Tas Kungs, tavs Dievs, vairojis tavu pulku, kā debess zvaigznes.
Àádọ́rin péré ni àwọn baba ńlá a yín tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín ti mú un yín pọ̀ sí i ní iye bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run.

< Piektā Mozus 10 >