< Jāņa 3. Vēstule 1 >

1 Tas vecākais Gajum, tam mīļotam, ko es patiesībā mīlēju.
Alàgbà, Sì Gaiusi, olùfẹ́, ẹni tí mo fẹ́ nínú òtítọ́.
2 Mīļais, pār visām lietām es vēlēju, lai tev labi klājās, un tu esi vesels, tā kā tavai dvēselei labi klājās.
Olùfẹ́, èmi ń gbàdúrà pé nínú ohun gbogbo kí o lè máa dára fún ọ, kí o sì máa wà ni ìlera, àní bí o tí dára fún ọkàn rẹ.
3 Jo es ļoti esmu priecājies, kad tie brāļi nāca un apliecināja tavu patiesību, tā kā tu iekš patiesības staigā.
Nítorí mo yọ̀ gidigidi, nígbà tí àwọn arákùnrin dé tí wọn sì jẹ́rìí sí ìwà òtítọ́ inú rẹ̀, àní bí ìwọ tí ń rìn nínú òtítọ́.
4 Man lielāka prieka nav, nekā kad dzirdu savus bērnus staigājam iekš patiesības.
Èmi ni ayọ̀ tí ó tayọ, láti máa gbọ́ pé, àwọn ọmọ mi ń rìn nínú òtítọ́.
5 Mīļais, tu dari pēc ticības, ko tu dari pie tiem brāļiem, un vēl tiem no svešuma atnākušiem,
Olùfẹ́, ìwọ ń ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún àwọn tí ń ṣe ará, àti pàápàá fún àwọn tí ń ṣe àlejò.
6 Kas ir devuši liecību par tavu mīlestību draudzes priekšā; un tu labi darīsi, kad tu tos izvadīsi, tā kā pieklājās Dieva priekšā.
Tí wọn ń jẹ́rìí sí ìfẹ́ rẹ̀ níwájú ìjọ, bí ìwọ bá ń pèsè fún wọn ní ọ̀nà àjò wọn gẹ́gẹ́ bí ó tí yẹ nínú Ọlọ́run.
7 Jo tie Viņa vārda dēļ ir izgājuši, neko no pagāniem neņemdami.
Nítorí pé, nítorí iṣẹ́ Kristi ni wọ́n ṣe jáde lọ, láìgba ohunkóhun lọ́wọ́ àwọn aláìkọlà.
8 Tad nu mums pienākas tos tādus uzņemt, ka mēs paliekam par darba biedriem pie patiesības.
Nítorí náà, ó yẹ kí àwa fi inú rere gba irú àwọn wọ̀nyí, kí àwa lè jẹ́ alábáṣiṣẹ́pọ̀ pẹ̀lú òtítọ́.
9 Es tai draudzei esmu rakstījis; bet Diotrefs, kas grib būt starp tiem tas augstākais, mūs nepieņem.
Èmi kọ̀wé sí ìjọ ṣùgbọ́n Diotirefe, ẹni tí ó fẹ́ láti jẹ́ ẹni pàtàkì jùlọ, kò gbà wá.
10 Tādēļ, kad es nākšu, tad es viņa darbus pieminēšu, ko viņš dara, ar ļauniem vārdiem pret mums aprunādams; un ar to nebūdams mierā viņš pats tos brāļus neuzņem un aizliedz arī tiem, kas to grib darīt, un tos izmet no draudzes.
Nítorí náà bí mo bá dé, èmi yóò mú iṣẹ́ rẹ̀ tí ó ṣe wá sì ìrántí rẹ, tí ó ń sọ ọ̀rọ̀ búburú àti ìsọkúsọ sí wa, èyí kò sì tún tẹ́ ẹ lọ́rùn, síbẹ̀ òun fúnra rẹ̀ kọ̀ láti gba àwọn ará, àwọn tí ó sì ń fẹ́ gbà wọ́n, ó ń dá wọn lẹ́kun, ó sì ń lé wọn kúrò nínú ìjọ.
11 Mīļais, nedzenies tam ļaunam pakaļ, bet tam labam; kas labu dara, tas ir no Dieva, bet kas ļaunu dara, tas Dievu nav redzējis.
Olùfẹ́, má ṣe ṣe àfarawé ohun tí í ṣe ibi bí kò ṣe ohun tí ṣe rere. Ẹni tí ó bá ń ṣe rere ti Ọlọ́run ni; ẹni tí ó ba ń ṣe búburú kò rí Ọlọ́run.
12 Demeterim liecība top dota no visiem un no pašas patiesības, un mēs arīdzan liecību dodam, un jūs zināt, ka mūsu liecība ir patiesīga.
Demetriusi ní ẹ̀rí rere lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn àti ní ti òtítọ́ fúnra rẹ̀ pẹ̀lú; nítòótọ́, àwa pẹ̀lú sì gba ẹ̀rí rẹ̀ jẹ́; ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí wa.
13 Man daudz būtu ko rakstīt, bet es negribu tev rakstīt ar tinti un spalvu;
Èmí ní ohun púpọ̀ láti kọ sínú ìwé sí ọ, ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ fi kálàmù àti tawada kọ wọ́n sínú ìwé.
14 Bet es ceru drīz tevi redzēt, tad mēs muti pret muti runāsim. Miers lai ir ar tevi. Tie draugi tevi sveicina. Sveicini tos draugus pa vārdam.
Mo ni ìrètí láti rí ọ láìpẹ́, tí àwa yóò sì sọ̀rọ̀ lójúkojú. Àlàáfíà fún ọ. Àwọn ọ̀rẹ́ wa tó wà níbí kí ọ. Kí àwọn ọ̀rẹ́ wa tó wà lọ́dọ̀ rẹ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.

< Jāņa 3. Vēstule 1 >