< Otra Ķēniņu 4 >

1 Un viena sieva no praviešu bērnu sievām piesauca Elišu un sacīja: mans vīrs, tavs kalps, ir nomiris, un tu zini, ka tavs kalps To Kungu bijās. Un nu nāk tas parādu dzinējs, gribēdams manus divus bērnus sev ņemt par kalpiem.
Ìyàwó ọkùnrin kan láti ara ẹgbẹ́ wòlíì sọkún tọ Eliṣa wá, “Ìránṣẹ́ rẹ ọkọ mi ti kú, ó sì mọ̀ wí pé ó bu ọlá fún Olúwa. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, onígbèsè rẹ̀ ti ń bọ̀ láti wá kó ọmọ ọkùnrin mi gẹ́gẹ́ bí ẹrú rẹ̀.”
2 Un Eliša uz to sacīja: ko man tev būs darīt? Stāsti man, kas ir tavā namā? Un viņa sacīja: tavai kalponei nav it nekā namā, kā tikai krūze eļļas.
Eliṣa dá a lóhùn pé, “Báwo ni èmi ṣe lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Sọ fún mi; kí ni ìwọ ní ní ilé rẹ?” Ó wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ kò ní ohunkóhun níbẹ̀ rárá, àyàfi òróró kékeré.”
3 Tad viņš sacīja: ej, aizņemies traukus no citiem, no visiem saviem kaimiņiem lūdz tukšus traukus labu pulku.
Eliṣa wí pé, “Lọ yíká kí o sì béèrè lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò fún ìkòkò òfìfo. Má ṣe béèrè fún kékeré.
4 Tad ej iekšā un aizslēdz durvis aiz sevis un aiz saviem dēliem un lej visos tanīs traukos un, kas pilni, tos liec pie malas.
Nígbà náà, lọ sí inú ilé kí o sì pa lẹ́kun dé ní ẹ̀gbẹ́ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, dà òróró sínú gbogbo ìkòkò, gẹ́gẹ́ bí gbogbo rẹ̀ ti kún, kó o sí apá kan.”
5 Tad tā no viņa aizgāja un aizslēdza durvis aiz sevis un aiz saviem dēliem, tie viņai atnesa tos traukus, un viņa ielēja.
Ó sì fi sílẹ̀ lẹ́yìn náà ó ti ìlẹ̀kùn ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n gbé ìkòkò wá fún un ó sì ń dà á.
6 Un kad tie trauki bija pilni, tad tā sacīja uz savu dēlu: nes man vēl vienu trauku Bet tas uz viņu sacīja: nav vairs trauka Tad tā eļļa nostājās.
Nígbà tí gbogbo ìkòkò náà kún, ó sọ fún ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ gbé òmíràn fún mi wá.” Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Kò sí ìkòkò tí ó kù mọ́.” Nígbà náà ni òróró kò dà mọ́.
7 Un tā gāja un to teica tam Dieva vīram. Un viņš sacīja: ej, pārdod to eļļu un maksā savu parādu, un no atlikuma uzturies pati ar saviem dēliem.
Ó sì lọ ó sì lọ sọ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì wí pé, “Lọ, ta òróró náà kí o sì san gbèsè rẹ. Ìwọ àti ọmọ rẹ kí ẹ máa sinmi lórí èyí tí ó kù.”
8 Un notikās kādu dienu, kad Eliša gāja uz Šunemi, tad tur bija viena bagāta sieva, tā viņu uzlūdza, pie viņas ēst. Un notikās, kad viņš tur cauri staigāja, tad viņš tur iegāja, ēst maizi,
Ní ọjọ́ kan Eliṣa lọ sí Ṣunemu. Obìnrin ọlọ́rọ̀ kan sì wà níbẹ̀, ẹni tí ó rọ̀ ọ́ kí ó dúró jẹun. Bẹ́ẹ̀ ni nígbàkígbà tí ó bá ń kọjá lọ, ó máa ń dúró níbẹ̀ láti jẹun.
9 Un tā sacīja uz savu vīru: redzi, es atzīstu, ka tas ir svēts Dieva vīrs, kas še vienmēr cauri staigā.
Ó sọ fún ọkọ rẹ̀, “Mo mọ̀ pé ọkùnrin tí ó máa ń sábà wá sí ọ̀dọ̀ wa jẹ́ ọkùnrin mímọ́ Ọlọ́run.
10 Taisīsim viņam mazu augšistabiņu ar sienām un liksim viņam tur gultu un galdu un krēslu un lukturi, ka tam pie mums nākot ir, kur ieiet.
Jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí ilé kí a sì gbé ibùsùn àti tábìlì oúnjẹ, àga kan àti fìtílà fún un. Nígbà náà ó lè dúró níbẹ̀ ní ìgbàkúgbà tí ó bá wá sọ́dọ̀ wa.”
11 Un gadījās kādu dienu, kad viņš tur nonāca, tad tas gāja tai augšistabiņā, tur gulēt.
Ní ọjọ́ kan nígbà tí Eliṣa wá, ó lọ sí orí òkè ní yàrá rẹ̀ ó sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
12 Un viņš sacīja uz Gehazi, savu puisi, pasauc šo Šunemieti. Un viņš to sauca un tā ienāca pie viņa.
Ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi pé, “Pe ará Ṣunemu.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é wá, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
13 Un viņš uz to sacīja: saki jel viņai: redzi, mūsu dēļ tev ir bijušas visas šās rūpes, ko man tev būs darīt? Vai tev kas jārunā pie ķēniņa vai pie karu lielkunga? Bet viņa sacīja: es dzīvoju starp saviem ļaudīm.
Eliṣa wí fún un pé, “Wí fún un, ‘Ìwọ ti lọ ṣe gbogbo àníyàn iṣẹ́ ìyìnrere fún wa. Nísinsin yìí kí ni a lè ṣe fún ọ?’” “Ṣé a lè jẹ́ agbẹnusọ fún ọ ní ọ̀dọ̀ ọba tàbí olórí ogun?”
14 Tad viņš sacīja ko tad lai es viņai daru? Un Gehazis sacīja taču gan, viņai nav dēla un viņas vīrs ir vecs.
“Kí ni a lè ṣe fún obìnrin yìí?” Eliṣa béèrè. Gehasi wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, kò ní ọmọ, ọkọ rẹ̀ náà sì tún di arúgbó.”
15 Tad viņš sacīja pasauc viņu. Un tas viņu sauca, un tā ienāca durvīs.
Nígbà náà Eliṣa wí pé, “Pè é,” bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é, ó sì dúró ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
16 Un viņš sacīja: nākošā gadā ap šo laiku tu skūpstīsi dēlu. Bet tā sacīja: ne tā, mans kungs tu Dieva vīrs! Nemelo tu savai kalponei.
Eliṣa sọ wí pé, “Ìwòyí ọdún tí ń bọ̀, ìwọ yóò fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọ.” “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa mi!” n kò fi ara mọ́ ọn. “Jọ̀wọ́, ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, ma ṣe ṣi ìránṣẹ́ rẹ lọ́nà!”
17 Un tā sieva tapa grūta un dzemdēja dēlu otrā gadā ap to pašu laiku, kā Eliša uz viņu bija runājis.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà lóyún ní ọdún kejì ní àkókò náà, ó bí ọmọ ọkùnrin kan, gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti sọ fún un.
18 Kad nu tas bērns paauga, tad tas kādu dienu gāja ārā pie sava tēva pie pļāvējiem.
Ọmọ náà dàgbà, ní ọjọ́ kan, ó jáde lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀, ó wà pẹ̀lú àwọn olùkórè.
19 Un tas sacīja uz savu tēvu: vai mana galva, mana galva! Un viņš sacīja puisim: nes to pie viņa mātes.
“Orí mi! Orí mi!” Ó wí fún baba rẹ̀. Baba rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́, “Gbé e lọ sọ́dọ̀ ìyá rẹ̀.”
20 Un tas to ņēma un nesa pie viņa mātes, un tā to ņēma savā klēpī līdz pusdienai, tad tas nomira.
Lẹ́yìn ìgbà tí ìránṣẹ́ náà ti gbé e sókè tí ó sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ, ọmọ ọkùnrin náà jókòó sórí ẹsẹ̀ rẹ̀ títí ó fi di ọ̀sán gangan, nígbà náà ó sì kú.
21 Un tā gāja augšām un to nolika Tā Dieva vīra gultā un to ieslēdza un izgāja,
Ó lọ sí òkè ó sì tẹ́ ọmọ náà lórí ibùsùn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì tìlẹ̀kùn, ó jáde lọ.
22 Un sauca savu vīru un sacīja: sūti man jel vienu no puišiem un vienu ēzeļa māti, es jāšu pie Tā Dieva vīra un atkal pārnākšu.
Ó pe ọkọ rẹ̀ ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ rán ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan kí èmi kí ó lè lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run kíákíá kí n sì padà.”
23 Un viņš sacīja: kāpēc tu šodien iesi pie viņa? Jo nav nedz jauns mēnesis nedz svēta diena. Bet tā sacīja: paliec mierā!
“Kí ni ó dé tí o fi fẹ́ lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ lónìí?” Ó béèrè. “Kì í ṣe oṣù tuntun tàbí ọjọ́ ìsinmi.” Ó wí pé, “Gbogbo rẹ̀ ti dára.”
24 Un viņa apsedloja ēzeļa māti un sacīja uz savu puisi: dzen steigšus, nekavē mani jājot, kā vien, kad es tev saku.
Ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Máa nìṣó; má ṣe dẹ́sẹ̀ dúró dè mí àyàfi tí mo bá sọ fún ọ.”
25 Tā viņa jāja un nāca pie Tā Dieva vīra uz Karmeļa kalnu. Un kad tas Dieva vīrs no tālienes to redzēja, tad viņš sacīja uz savu puisi Gehazi: redzi, tur ir tā Šunemiete.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì jáde wá, ó sì wá sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè Karmeli. Nígbà tí ó sì rí i láti òkèrè, ènìyàn Ọlọ́run sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi, “Wò ó! Ará Ṣunemu nì!
26 Steidzies jel viņai pretī un saki uz to: vai tev labi klājās, un tavam vīram, un tavam dēlam? Un viņa sacīja: labi gan.
Sáré lọ pàdé rẹ̀ kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ‘Ṣé o wà dáradára? Ṣé ọkọ rẹ wà dáradára? Ṣé ọmọ rẹ wà dáradára?’” Ó wí pé, “Gbogbo nǹkan wà dáradára.”
27 Un tā nāca kalnā pie Tā Dieva vīra un apkampa viņa kājas. Bet Gehazis piegāja to atstumt. Bet tas Dieva vīrs sacīja: liec to mierā, jo viņas dvēsele ir noskumusi, un Tas Kungs man to apslēpis un man nav darījis zināmu.
Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè, ó gbá a ní ẹsẹ̀ mú. Gehasi wá láti wá lé e dànù, ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run wí pé, “Fi í sílẹ̀! Ó wà nínú ìpọ́njú kíkorò, ṣùgbọ́n Olúwa fi pamọ́ fún mi kò sì sọ ìdí rẹ̀ fún mi.”
28 Un viņa sacīja: vai es esmu lūgusi dēlu no sava kunga? Vai es nesacīju: nevil mani?
“Ṣé mo béèrè ọmọ lọ́wọ́ rẹ, olúwa mi?” Obìnrin náà wí pé, “Ṣé mi ò sọ fún ọ pé kí o, ‘Má ṣe fa ìrètí mi sókè’?”
29 Tad viņš sacīja uz Gehazi: apjoz savus gurnus un ņem manu zizli savā rokā un ej. Ja tevi kas sastop, tad nesveicini to, un ja kas tevi sveicina, tad neatbildi tam, un liec manu zizli uz tā bērna vaigu.
Eliṣa wí fún Gehasi pé, “Ká agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè, mú ọ̀pá mi sí ọwọ́ rẹ kí o sì sáré. Tí o bá pàdé ẹnikẹ́ni má ṣe kí i, tí ẹnikẹ́ni bá kí ọ, má ṣe dá a lóhùn, fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ ọkùnrin náà.”
30 Bet tā bērna māte sacīja: tik tiešām kā Tas Kungs dzīvs un tava dvēsele dzīva, es tevi neatstāšu. Tad viņš cēlās un tai gāja līdz.
Ṣùgbọ́n ìyá ọmọ náà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ó ti wà láààyè, èmi kò ní í fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dìde ó sì tẹ̀lé e.
31 Gehazis viņu priekšā bija nogājis un licis to zizli uz tā bērna vaigu, bet tur nebija ne balss nedz samaņas. Tad viņš griezās atpakaļ tam pretī un teica un sacīja: tas bērns nav uzmodies.
Gehasi sì ń lọ síbẹ̀ ó sì fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, ṣùgbọ́n kò sí ohùn tàbí ìdáhùn. Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi padà lọ láti lọ bá Eliṣa láti sọ fún un pé, “Ọmọ ọkùnrin náà kò tí ì dìde.”
32 Kad nu Eliša ienāca namā, redzi, tad tas bērns gulēja nomiris viņa gultā.
Nígbà tí Eliṣa dé inú ilé, níbẹ̀ ni òkú ọmọ ọkùnrin náà dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn.
33 Un viņš gāja iekšā un aizslēdza durvis aiz abiem un pielūdza To Kungu.
Ó sì wọ ilé, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ àwọn méjèèjì ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
34 Un viņš uzkāpa un nolikās uz to bērnu un lika savu muti un savas acis uz viņa acīm un savas rokas uz viņa rokām, un nogūlās tā pār tā bērna miesām, kamēr tās sasila.
Nígbà náà ó dé orí ibùsùn, ó sùn sórí ọmọ ọkùnrin náà, ẹnu sí ẹnu, ojú sí ojú, ọwọ́ sí ọwọ́. Gẹ́gẹ́ bí ó ti nà ara rẹ̀ lórí rẹ̀, ara ọmọ náà sì gbóná.
35 Un viņš atkal cēlās un gāja istabā reiz šurp un reiz turp un uzkāpa atkal un nogūlās pār to. Tad tas bērns šķaudīja septiņas reizes, pēc tas atdarīja savas acis.
Eliṣa yípadà lọ, ó sì rìn padà ó sì jáde wá sínú ilé nígbà náà ó sì padà sí orí ibùsùn ó sì tún nà lé e ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọmọ ọkùnrin náà sì sín ní ìgbà méje ó sì ṣí ojú rẹ̀.
36 Un viņš sauca Gehazi un sacīja: pasauc to Šunemieti. Un viņš to sauca un tā nāca; tad viņš sacīja: ņem savu bērnu.
Eliṣa sì pe Gehasi ó sì wí pé, “Pe ará Ṣunemu.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀. Nígbà tí ó dé, ó wí pé, “Gba ọmọ rẹ.”
37 Tad tā nāca un metās viņam pie kājām un nometās zemē un ņēma savu dēlu un izgāja ārā.
Ó sì wọlé, ó sì kúnlẹ̀ síwájú ẹsẹ̀ rẹ̀ ó sì tẹ̀ orí sílẹ̀. Nígbà náà ó sì mú ọmọ rẹ̀ ó sì jáde lọ.
38 Un Eliša gāja atkal uz Gilgalu; un zemē bija bads, un praviešu bērni sēdēja viņa priekšā, un viņš sacīja uz savu puisi: liec to lielo podu pie uguns un vāri ēdienu praviešu bērniem.
Eliṣa padà sí Gilgali ìyàn sì wà ní ilẹ̀ náà. Nígbà tí àwọn ọmọ wòlíì ṣe ìpàdé pẹ̀lú rẹ̀, ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Gbé ìkòkò ńlá ka iná kí o sì se ọbẹ̀ aláta díẹ̀ fún àwọn ọkùnrin yìí.”
39 Tad viens izgāja laukā, zāles lasīt un atrada meža gurķu stīgas un no tām salasīja pilnu klēpi meža gurķu un nāca un tos iegrieza tai ēdiena podā, jo tie tos nepazina.
Ọ̀kan lára wọn jáde lọ sí orí pápá láti kó ewébẹ̀ jọ àti láti wá àjàrà igbó. Ó sì kó díẹ̀ nínú ẹ̀fọ́ gbọ̀rọ̀ rẹ̀ jọ, ó sì ka a kún aṣọ agbádá rẹ̀. Nígbà tí ó padà dé, ó sì gé wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí wọ́n ń jẹ.
40 Un tie ielēja tiem vīriem ēst, un kad tie no tā ēdiena ēda, tad tie brēca un sacīja: nāve podā, tu Dieva vīrs! Un nevarēja to ēst.
Wọ́n da ọbẹ̀ náà jáde fun àwọn ọkùnrin náà, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ oúnjẹ náà, wọ́n sọkún jáde, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run ikú ń bẹ nínú ìkòkò yìí!” Wọn kò sì le jẹ ẹ́.
41 Bet viņš sacīja: atnesiet miltus. Un viņš tos iemeta tai podā un sacīja: lej tiem ļaudīm, lai tie ēd. Tad tur vairs nekā nelaba nebija podā.
Eliṣa sì wí pé, “Mú ìyẹ̀fun díẹ̀ wá,” Ó sì fi sínú ìkòkò ó sì wí pé, “Kí ó sì fi fún àwọn ènìyàn láti jẹ.” Kò sì sí ohun tí ó léwu nínú ìkòkò náà.
42 Un viens vīrs nāca no BaālBalizas un atnesa tam Dieva vīram jaunu maizi, divdesmit miežu maizes un taukšētas vārpas savā kulē. Un viņš sacīja: dodi tiem ļaudīm, lai ēd.
Ọkùnrin kan wá láti Baali-Ṣaliṣa, ó sì mú àkàrà àkọ́so èso, ogún ìṣù àkàrà barle, tí wọ́n dín láti ara àkọ́so èso àgbàdo, àti pẹ̀lú síírí ọkà tuntun nínú àpò rẹ̀ wá fún ènìyàn Ọlọ́run náà. Òun sì wí pé, “Fún àwọn ènìyàn láti jẹ.”
43 Bet viņa sulainis sacīja: ko es došu simts vīriem? Un viņš sacīja: dod tiem ļaudīm, lai ēd; jo tā saka Tas Kungs: tie ēdīs un vēl atliks.
“Báwo ni èmi yóò ṣe gbé èyí ka iwájú àwọn ọgọ́rùn-ún ènìyàn?” ìránṣẹ́ rẹ̀ béèrè. Ṣùgbọ́n Eliṣa dá a lóhùn pé, “Gbé e fún àwọn ènìyàn láti jẹ, nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Wọn yóò jẹ yóò sì tún ṣẹ́kù.’”
44 Tad viņš tiem lika priekšā, ka tie ēda, un tur vēl atlika pēc Tā Kunga vārda.
Nígbà náà ó gbé e ka iwájú wọn, wọ́n sì jẹ ẹ́, wọ́n sì ní èyí tó ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.

< Otra Ķēniņu 4 >