< Otra Ķēniņu 10 >

1 Un Ahabam bija septiņdesmit dēli Samarijā, un Jeūs rakstīja grāmatas un tās sūtīja uz Samariju pie Jezreēles virsniekiem, pie tiem vecajiem un Ahaba bērnu uzraugiem ar šiem vārdiem:
Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
2 Kad šī grāmata pie jums nonāk, un jūsu kunga dēli ir pie jums, un rati un zirgi, stipra pilsēta un bruņas,
“Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 Tad izredziet to labāko un taisnāko no sava kunga dēliem, un ieceļat to viņa tēva goda krēslā, un karojiet par sava kunga namu.
yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Bet tie bijās varen ļoti un sacīja: redzi, divi ķēniņi viņa priekšā nav pastāvējuši, kā tad mēs pastāvēsim?
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
5 Un kas par to namu un pilsētu bija iecelts, un tie vecaji un uzraugi sūtīja pie Jeūs un sacīja: mēs esam tavi kalpi un darīsim visu, ko tu mums sacīsi, mēs nevienu necelsim par ķēniņu; dari tu, kas tev patīk.
Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
6 Tad viņš tiem rakstīja citu grāmatu ar šiem vārdiem: ja jūs esat manā pusē un gribat klausīt manai balsij, tad ņemiet sava kunga dēlu galvas un nāciet pie manis rīt ap šo laiku uz Jezreēli. (Un to ķēniņa dēlu bija septiņdesmit vīri pie pilsētas lielkungiem, kas tos audzināja.)
Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
7 Kad nu šī grāmata pie tiem atnāca, tad tie ņēma tos ķēniņa dēlus un nokāva visus septiņdesmit un lika viņu galvas kurvjos un tās sūtīja uz Jezreēli.
Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
8 Un kad tas vēstnesis atnāca un viņam to stāstīja sacīdams: tie ir atnesuši ķēniņa dēlu galvas, tad viņš sacīja: lieciet tās divējās kopās pie vārtu durvīm līdz rītam.
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
9 Un no rīta, kad viņš izgāja, tad viņš tur nostājās un sacīja uz visiem ļaudīm: jūs esat taisni, redzi, es esmu cēlis dumpi pret savu kungu un viņu nokāvis; kas tad šos visus ir kāvis?
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
10 Tāpēc atzīstiet, ka no Tā Kunga vārda nekas nav kritis zemē, ko Tas Kungs runājis pret Ahaba namu; jo Tas Kungs ir darījis, ko Viņš runājis caur savu kalpu Eliju.
Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
11 Tad Jeūs arī visus apkāva, kas no Ahaba nama bija atlikušies Jezreēlē, arī visus viņa augstniekus un viņa pazīstamos un viņa svētītājus, kamēr tam neviena vairs neatlika.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
12 Un viņš cēlās un gāja un nonāca Samarijā un bija ceļā vienā namā, kur gani dzīvoja.
Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
13 Tad Jeūs atrada Ahazijas, Jūda ķēniņa, brāļus un uz tiem sacīja: kas jūs esat? Un tie sacīja: mēs esam Ahazijas brāļi un esam nākuši apmeklēt ķēniņa un ķēniņienes bērnus.
Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
14 Tad viņš sacīja: grābiet tos dzīvus. Un tie tos sagrāba dzīvus un tos apkāva pie ganu nama akas, četrdesmit un divus vīrus, un neatlicināja no tiem neviena.
“Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
15 Un no turienes aizgājis viņš atrada Jonadabu, Rekaba dēlu, pretī nākam, un to apsveicināja un uz to sacīja: vai tava sirds taisna, kā mana sirds ar tavu sirdi? Un Jonadabs sacīja: ir gan. (Jeūs sacīja: ) Ja tā ir, tad dod man savu roku. Un viņš tam deva roku. Un viņš tam lika pie sevis kāpt ratos.
Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
16 Un viņš sacīja: nāc man līdz un skaties manu karstumu priekš Tā Kunga. Un viņš tam lika braukt savos ratos.
Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
17 Tad viņš nonāca Samarijā un apkāva visus, kas Ahabam bija atlikuši Samarijā, tiekams viņš tos izdeldēja, pēc Tā Kunga vārda, ko tas caur Eliju bija runājis.
Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
18 Un Jeūs sapulcināja visus ļaudis un uz tiem sacīja: Ahabs Baālam maz ir kalpojis, Jeūs viņam daudz vairāk kalpos.
Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
19 Tāpēc aicinājiet visus Baāla praviešus, visus viņa kalpus un visus viņa svētītājus pie manis, ka neviens neatraujās, jo man Baālam jaupurē liels upuris. Nevienam, kas atraujās, nebūs palikt dzīvam. Bet Jeūs to darīja ar viltību, ka viņš nomaitātu visus Baāla kalpus.
Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
20 Un Jeūs sacīja: svētījiet Baālam svētkus, un tie tos izsauca.
Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
21 Tad Jeūs sūtīja arī pa visu Israēli, un visi Baāla kalpi atnāca, un neviens neatrāvās, kas nebūtu nācis, un tie nāca Baāla namā, ka Baāla nams līdz galu galam bija pilns.
Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Tad viņš sacīja uz tiem, kas bija iecelti pār to drēbju namu: atnesiet visiem Baāla kalpiem drēbes, un tie viņiem atnesa drēbes.
Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
23 Tad Jeūs ar Jonadabu, Rekaba dēlu, gāja Baāla namā, un viņš sacīja uz Baāla kalpiem: meklējiet un pieraugāt, ka jūsu starpā nav neviena no Tā Kunga kalpiem, bet Baāla kalpi vien.
Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
24 Kad tie nu nāca upurēt kaujamos un dedzināmos upurus, tad Jeūs ārā nolika astoņdesmit vīrus un sacīja: ja kāds no tiem vīriem, ko es jums dodu rokā, izbēgs, tad jūsu dvēsele būs viņa dvēseles vietā.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
25 Kad nu dedzināmais upuris bija pabeigts, tad Jeūs sacīja uz pils karavīriem un uz virsniekiem: ejat un kaujiet tos, ka neviens neizbēg. Un tie tos apkāva ar zobena asmeni, un tie pils karavīri un virsnieki tos nometa pie malas un gāja Baāla nama pilī.
Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
26 Un tie iznesa Baāla nama uzceltos stabus un tos sadedzināja,
Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
27 Un sadragāja Baāla uzcelto tēlu un salauzīja Baāla namu un to darīja par gānekļu vietu līdz šodienai.
Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
28 Tā Jeūs Baālu izdeldēja no Israēla.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
29 Bet no Jerobeama, Nebata dēla, grēkiem, kas Israēli bija pavedis uz grēkiem, Jeūs neatstājās, proti no tiem zelta teļiem Bētelē un Danā.
Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
30 Un Tas Kungs sacīja uz Jeū: “Tāpēc ka tev labs prāts bijis darīt, kas Man patīk un Ahaba namam visu esi darījis, kas bija Manā sirdī, tad tavi dēli tev sēdēs Israēla krēslā līdz ceturtam augumam.”
Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
31 Bet Jeūs nedzinās staigāt Tā Kunga, Israēla Dieva, bauslībā ar visu savu sirdi; viņš neatstājās no Jerobeama grēkiem, kas Israēli bija pavedis uz grēkiem.
Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
32 Tanī laikā Tas Kungs Israēli iesāka mazināt, jo Azaēls tos kāva visās Israēla robežās,
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
33 No Jardānes puses pret rītiem visu Gileādas zemi, Gadiešus un Rūbeniešus un Manasiešus, no Aroēra pie Arnonas upes un Gileādu un Basanu.
Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Un kas vēl par Jeū stāstāms, un viss, ko viņš darījis, un viss viņa spēks, tas ir rakstīts Israēla ķēniņu laiku grāmatā.
Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
35 Un Jeūs aizmiga saviem tēviem pakaļ un viņu apraka Samarijā, un viņa dēls Joakas palika par ķēniņu viņa vietā.
Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
36 Un tas laiks, kamēr Jeūs pār Israēli valdījis Samarijā, ir divdesmit un astoņi gadi.
Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.

< Otra Ķēniņu 10 >