< Pirmā Samuela 30 >

1 Un notikās, kad Dāvids ar saviem vīriem trešā dienā nāca uz Ciklagu, tad Amalekieši pret dienvidiem un Ciklagā bija ielauzušies un Ciklagu kāvuši un ar uguni sadedzinājuši.
Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
2 Un tās sievas no turienes bija aizveduši, un mazus un lielus, bet nevienu nebija nokāvuši, bet aizveduši un gājuši savu ceļu.
Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
3 Un Dāvids ar saviem vīriem nāca pie tās pilsētas, un redzi, tā bija sadedzināta ar uguni, un viņu sievas un viņu dēli un viņu meitas bija aizvesti.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
4 Tad Dāvids ar tiem vīriem, kas pie viņa bija, pacēla savu balsi un raudāja, kamēr tiem vairs spēka nebija raudāt.
Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
5 Arī Dāvida abas sievas, Aķinoama, tā Jezreēliete, un Abigaīle, Nābala sieva, tā Karmeliete, bija aizvestas.
A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
6 Un Dāvidam bija ļoti bail, jo tie ļaudis to gribēja akmeņiem nomētāt, jo visiem ļaudīm sirds ēdās, ikvienam par saviem dēliem un par savām meitām. Bet Dāvids stiprinājās iekš Tā Kunga, sava Dieva.
Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
7 Un Dāvids sacīja uz priesteri Abjataru, Aķimeleka dēlu: dod jel to efodu šurp! Un Abjatars nesa to efodu pie Dāvida.
Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
8 Tad Dāvids vaicāja To Kungu sacīdams: vai man būs tam pulkam pakaļ dzīties, vai es tos panākšu? Un Viņš tam sacīja: dzenies, tu tos panāksi un patiesi atpestīsi.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
9 Tad Dāvids nogāja ar tiem sešsimt vīriem, kas pie viņa bija, un kad tie nāca pie Bezoras upes, tad tur citi apstājās.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
10 Un Dāvids tiem dzinās pakaļ ar četrsimt vīriem, bet divsimt vīri tur palika stāvot, kas bija piekusuši, ka nevarēja iet pār Bezoras upi.
Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
11 Un tie atrada vienu Ēģiptieti laukā, to tie atveda pie Dāvida, un deva tam maizes, un viņš ēda, un deva tam ūdeni dzert,
Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
12 Un deva tam vienu šķēli vīģu raušu un divus rozīņu raušus. Un viņš ēda, un viņa gars atkal atgriezās pie viņa, jo viņš nebija maizes ēdis, nedz ūdens dzēris trīs dienas un trīs naktis.
Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
13 Tad Dāvids uz to sacīja: kas tu esi un no kurienes tu esi? Tad tas sacīja: esmu ēģiptiešu puisis, viena Amalekieša kalps, un mans kungs mani atstājis, tāpēc ka es priekš trim dienām esmu slims palicis.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
14 Mēs bijām ielauzušies pret dienasvidu pie Krietiem un uz Jūdu un pret dienasvidu pie Kāleba, un Ciklagu ar uguni esam sadedzinājuši.
Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
15 Tad Dāvids uz to sacīja: vai tu gribi mani novest pie šā pulka? Un tas sacīja: zvērē man pie Dieva, ka tu mani negribi nokaut nedz nodot mana kunga rokā, tad es tevi pie šā pulka novedīšu.
Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
16 Un viņš to noveda. Un redzi, tie gulēja izklīduši pa visu klajumu, ēda un dzēra un dejoja par visu to lielo laupījumu, ko tie bija paņēmuši no Fīlistu un Jūdu zemes.
Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
17 Un Dāvids tos kāva no rīta gaismas līdz vakaram otrai dienai sākot, un neviens no tiem neizspruka, kā vien četrsimt jauni vīri, kas uz kamieļiem jāšus aizbēga.
Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
18 Tā Dāvids izglāba visu, ko Amalekieši bija paņēmuši, un Dāvids arī izglāba savas abas sievas.
Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
19 Un no tiem netrūka neviena, ne maza ne liela, ne dēla ne meitas, ne no tā laupījuma, ne no visa, ko tie tiem bija paņēmuši, - visu Dāvids veda atpakaļ.
Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
20 Un Dāvids ņēma visas avis un vēršus, un tie šos lopus dzina Dāvida priekšā un sacīja: šis ir Dāvida laupījums.
Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
21 Kad nu Dāvids pie tiem divsimt vīriem nāca, kas bija piekusuši, ka Dāvidam nevarēja iet pakaļ, un tāpēc pie Bezoras upes bija pamesti, tad tie Dāvidam un tiem ļaudīm, kas pie viņa bija, izgāja pretī. Un Dāvids piestājās pie tiem ļaudīm un vaicāja pēc viņu labklāšanās.
Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
22 Tad visi netiklie un negantie ļaudis to vīru starpā, kas ar Dāvidu bija gājuši, atbildēja un sacīja: tāpēc ka tie mums nav nākuši līdz, tad mēs tiem arī nekā nedosim no tā laupījuma, ko esam glābuši, kā vien ikkatram savu sievu un savas bērnus; tos lai tie ņem un iet.
Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
23 Bet Dāvids sacīja: tā jums, mani brāļi, nebūs darīt ar to, ko Tas Kungs mums ir devis, jo Viņš mūs ir pasargājis, un to pulku, kas pret mums nācis, ir devis mūsu rokā.
Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
24 Kas jūs šinī lietā varētu klausīt? Jo kāda daļa ir tiem, kas gājuši kauties, tāda pat daļa būs arī šiem, kas pie rīkiem palikuši, tiem kopā būs dalīties.
Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
25 Un tas no tās dienas nu joprojām tā ir palicis, jo viņš to par likumu un tiesu ir iecēlis iekš Israēla līdz šai dienai.
Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
26 Kad nu Dāvids uz Ciklagu nāca, tad viņš no tā laupījuma Jūda vecajiem, saviem draugiem, sūtīja un sacīja: redz, še jums ir dāvanas no Tā Kunga ienaidnieku laupījuma.
Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
27 (Proti) tiem Bētelē un tiem Rāmatā pret dienasvidu un tiem Jatirā
Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
28 Un tiem Aroērā un tiem Sipmotā un Estemoā
Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
29 Un tiem Rakalā un tiem, kas bija Jerameēliešu pilsētās, un tiem, kas Keniešu pilsētās dzīvoja,
Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
30 Un tiem Ormā un tiem KorAzanā un tiem Atakā,
àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
31 Tiem Hebronē, un visām vietām, kur Dāvids bija apkārt gājis, viņš un viņa vīri.
Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.

< Pirmā Samuela 30 >