< Pirmā Ķēniņu 21 >

1 Un pēc tam notikās, ka Nābatam, tam Jezreēlietim, bija vīna dārzs Jezreēlē, sānis Ahaba, Samarijas ķēniņa, pilij.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
2 Un Ahabs runāja ar Nābatu sacīdams: dod man savu vīna dārzu, man par sakņu dārzu, jo tas ir tuvu pie mana nama, un es tev viņa vietā došu labāku vīna dārzu, nekā tas ir; vai ja tev patīk, es tev to aizmaksāšu ar naudu.
Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
3 Bet Nābats sacīja uz Ahabu: lai Tas Kungs mani pasargā, ka es tev atdotu savu tēvu mantojumu.
Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
4 Tad Ahabs saīdzis un dusmīgs nāca mājās tā vārda dēļ, ko Nābats, tas Jezreēlietis, uz viņu bija runājis sacīdams: es tev nedošu savu tēvu mantojumu. Un viņš metās gultā, apgriezās uz otru pusi un neēda maizes.
Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
5 Tad Izebele, viņa sieva, pie tā nāca un ar to runāja: par ko tavs prāts tāds saīdzis un tu maizes neēdi?
Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
6 Un viņš uz to sacīja: es runāju ar Nābatu, to Jezreēlieti, un uz to sacīju: dod man savu vīna dārzu par naudu, vai ja tu gribi, es tev došu citu vīna dārzu tai vietā. Bet tas sacīja: es tev nedošu savu vīna dārzu.
Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
7 Tad Izebele, viņa sieva, uz to sacīja: “Tu, vai tāda tava valdīšana pār Israēli? Celies, ēd maizi, un lai tava sirds ir mierā! Es tev dabūšu Nābata, tā Jezreēlieša, vīna dārzu.”
Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
8 Un tā rakstīja grāmatas Ahaba vārdā un tās aizzieģelēja ar viņa gredzenu, un sūtīja tās grāmatas pie tiem vecajiem un pie tiem cienīgiem viņa pilsētā, kas pie Nābata dzīvoja.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
9 Un tā rakstīja tais grāmatās šos vārdus: izsauciet gavēni un sēdinājiet Nābatu augstā vietā ļaužu priekšā.
Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
10 Un stādiet tam pretim divus netiklus vīrus, kas pret viņu dod liecību un saka: tu Dievu un ķēniņu esi zaimojis, un izvediet to un nomētājiet to akmeņiem, ka tas mirst.
Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
11 Un viņa pilsētas vīri, tie vecaji un cienīgie, kas viņa pilsētā dzīvoja, darīja, kā Izebele tiem bija sacījusi, kā tanīs grāmatās bija rakstīts, ko viņa tiem bija sūtījusi.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
12 Un tie izsauca gavēni un sēdināja Nābatu ļaužu priekšā.
Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
13 Tad divi netikli vīri nāca un stājās viņa priekšā, un tie netiklie vīri deva liecību pret Nābatu ļaužu priekšā un sacīja: “Nābats Dievu un ķēniņu zaimojis.” Un tie to izveda no pilsētas ārā un to nomētāja akmeņiem, ka tas mira.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
14 Tad tie sūtīja pie Izebeles un lika sacīt: Nābats akmeņiem nomētāts un miris.
Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
15 Kad nu Izebele dzirdēja, ka Nābats akmeņiem bija nomētāts un miris, tad Izebele sacīja uz Ahabu: “Celies, ņem Nābata, tā Jezreēlieša, vīna dārzu, ko viņš tev liedzies dot par naudu, jo Nābats nav vairs dzīvs, bet miris.”
Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
16 Kad nu Ahabs dzirdēja, ka Nābats bija miris, tad Ahabs cēlās, noiet uz Nābata, tā Jezreēlieša, vīna dārzu, to paņemt.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
17 Tad Tā Kunga vārds notika uz Eliju no Tizbes tā:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
18 “Celies, ej Ahabam, Israēla ķēniņam, pretī, kas ir Samarijā, redzi, viņš ir Nābata vīna dārzā, turp viņš ir nogājis, to paņemt.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
19 Un runā uz viņu un saki: tā saka Tas Kungs: vai tu neesi nokāvis un arī paņēmis? Tad tev uz viņu tā būs runāt un sacīt: tā saka Tas Kungs: tai vietā, kur suņi laizījuši Nābata asinis, tur suņi arī laizīs tavas asinis, tiešām tavas.”
Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
20 Tad Ahabs sacīja uz Eliju: “Vai tu, mans ienaidnieks, mani esi atradis? Un tas sacīja: “Es tevi esmu atradis, tāpēc ka tu sevi esi pārdevies, ļaunu darīt priekš Tā Kunga acīm.
Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
21 Redzi, Es vedīšu nelaimi pār tevi un atmetīšu tavus pēcnākamos un izdeldēšu no Ahaba ikvienu, kas pie sienas mīž, to mazo un to lielo iekš Israēla.
‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
22 Un Es darīšu tavu namu tāpat kā Jerobeama, Nebata dēla, namu, un kā Baešas, Ahijas dēla, namu, tās kaitināšanas dēļ, ar ko tu Mani esi kaitinājis un ka tu Israēli esi pavedis uz grēkiem.
Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
23 Un par Izebeli Tas Kungs arī runāja un sacīja: “Suņiem Izebeli būs ēst pie Jezreēles mūriem.”
“Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
24 Kas no Ahaba mirst pilsētā, to ēdīs suņi, un kas mirst laukā, to ēdīs putni apakš debess.”
“Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
25 (Tāds kā Ahabs neviens nav bijis, kas sevi bija pārdevies, ļaunu darīt Tā Kunga acīs, jo viņa sieva viņu tā paveda.
(Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
26 Un viņš darīja daudz negantības, staigādams pakaļ elkadieviem, tā kā bija darījuši Amorieši, ko Tas Kungs bija izdzinis Israēla bērnu priekšā.)
Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
27 Kad nu Ahabs šos vārdus dzirdēja, tad viņš saplēsa savas drēbes un uzvilka maisus uz savu miesu un gavēja un gulēja maisā un staigāja apkārt klusu.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
28 Un Tā Kunga vārds notika uz Eliju no Tizbes un sacīja:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
29 “Vai tu neesi redzējis, kā Ahabs Manā priekšā pazemojies? Tāpēc nu, ka tas Manā priekšā pazemojies, tad Es to nelaimi nevedīšu pār to viņa dienās; viņa dēla dienās Es vedīšu to nelaimi pār viņa namu.”
“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”

< Pirmā Ķēniņu 21 >