< Pirmā Ķēniņu 17 >

1 Un Elija no Tizbes, no Gileādas iedzīvotājiem, sacīja uz Ahabu: tik tiešām kā Tas Kungs, Israēla Dievs, dzīvo, kā priekšā es stāvu, šinīs gados nebūs nedz rasas nedz lietus, kā vien, kad es to sacīšu.
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Un Tā Kunga vārds uz to notika tā:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 Ej no šejienes un griezies pret rītiem un paslēpies pie Krites upes, kas tek pret Jardāni.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Un tur tu vari dzert no tās upes, un Es kraukļiem esmu pavēlējis, ka tiem tevi tur būs uzturēt.
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Un viņš nogāja un darīja pēc Tā Kunga vārda, un nogāja un palika pie Krites upes, kas tek pret Jardāni.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Un kraukļi viņam atnesa maizi un gaļu rītos un maizi un gaļu vakaros, un viņš dzēra no tās upes.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Bet pēc kāda laika tā upe izsīka, jo lietus tai zemē nebija.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Tad Tā Kunga vārds uz viņu notika tā:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 Celies un ej uz Sareptu, kas pie Sidones pieder, un paliec turpat; redzi, Es tur esmu pavēlējis vienai atraitnei, tevi uzturēt.
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Tad viņš cēlās un gāja uz Sareptu Un kad viņš nonāca pie pilsētas vārtiem, redzi, tad tur viena atraitne lasīja malku. Un viņš tai sauca un sacīja: atnes man traukā kādu ūdens malciņu, ko dzert.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Un tā gāja to atnest. Un viņš tai sauca un sacīja: atnes man arī kumosu maizes savā rokā.
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Bet tā sacīja: tik tiešām kā Tas Kungs, tavs Dievs, dzīvo, man nekā cepta nav, un tik vien ir sauja miltu tīnē un maķenīt eļļas krūzē, un redzi, es esmu salasījusi kādu pāri malkas gabaliņu, un nu es iešu un sev un savam dēlam ko pataisīšu, ka ēdam un mirstam.
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Un Elija uz to sacīja: nebīsties, ej, pataisi to, kā tu sacījusi, bet man taisi no tiem papriekš mazu rausi un iznes man to ārā, un pēc tu arī varēsi taisīt sev un savam dēlam.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Jo tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: milti tīnē neies galā un krūzē eļļas netrūks līdz tai dienai, kad Tas Kungs dos lietu virs zemes.
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Un tā nogāja un darīja pēc Elijas vārda; tā viņa ēda un viņš un viņas nams labu laiku;
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Milti tīnē negāja galā un krūzē eļļas netrūka pēc Tā Kunga vārda, ko viņš caur Eliju bija runājis.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Un pēc tam notikās, ka šīs sievas, tās nama mātes, dēls palika slims un viņa slimība palika ļoti grūta, kamēr viņam dvašas vairs nebija.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Un tā sacīja uz Eliju: kas man ar tevi, tu Dieva vīrs? Tu pie manis esi atnācis, lai mani grēki top pieminēti un mans dēls mirst.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Un viņš uz to sacīja: dod man šurp savu dēlu. Un viņš to ņēma no viņas klēpja un to uznesa augšistabā, kur viņš mita, un to lika uz savu gultu.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Un viņš piesauca To Kungu un sacīja: Kungs, mans Dievs! Vai tad Tu šai atraitnei, pie kuras es piemājoju, tik ļaunu esi darījis un nonāvējis viņas bērnu?
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Un viņš stiepās pār to bērnu trīs reizes un piesauca To Kungu un sacīja: Kungs, mans Dievs! Lai jel šā bērna dvēsele atkal nāk iekš viņa!
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Un Tas Kungs klausīja Elijas balsi, un tā bērna dvēsele atkal nāca iekš viņa, un tas atdzīvojās.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Un Elija ņēma to bērnu un to nonesa no augšistabas namā un to deva viņa mātei; un Elija uz to sacīja: redzi še, tavs dēls dzīvs.
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Tad tā sieva sacīja uz Eliju: nu es zinu, ka tu esi Dieva vīrs, un Tā Kunga vārds tavā mutē ir patiesība.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”

< Pirmā Ķēniņu 17 >