< Job 35 >
1 igitur Heliu haec rursum locutus est
Elihu sì wí pe:
2 numquid aequa tibi videtur tua cogitatio ut diceres iustior Deo sum
“Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé, òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?
3 dixisti enim non tibi placet quod rectum est vel quid tibi proderit si ego peccavero
Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ, tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.
4 itaque ego respondebo sermonibus tuis et amicis tuis tecum
“Èmi ó dá ọ lóhùn àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.
5 suspice caelum et intuere et contemplare aethera quod altior te sit
Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.
6 si peccaveris quid ei nocebis et si multiplicatae fuerint iniquitates tuae quid facies contra eum
Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí? Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?
7 porro si iuste egeris quid donabis ei aut quid de manu tua accipiet
Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un, tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?
8 homini qui similis tui est nocebit impietas tua et filium hominis adiuvabit iustitia tua
Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ; òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.
9 propter multitudinem calumniatorum clamabunt et heiulabunt propter vim brachii tyrannorum
“Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe; wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.
10 et non dixit ubi est Deus qui fecit me qui dedit carmina in nocte
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé, ‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;
11 qui docet nos super iumenta terrae et super volucres caeli erudit nos
tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ, tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’
12 ibi clamabunt et non exaudiet propter superbiam malorum
Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.
13 non ergo frustra audiet Deus et Omnipotens singulorum causas intuebitur
Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán; bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.
14 etiam cum dixeris non considerat iudicare coram eo et expecta eum
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i, ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ, ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.
15 nunc enim non infert furorem suum nec ulciscitur scelus valde
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni, òun kò ni ka ìwà búburú si?
16 ergo Iob frustra aperit os suum et absque scientia verba multiplicat
Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀ lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”