< Mwet Nununku 8 >

1 Na mwet Ephraim elos fahk nu sel Gideon, “Efu ku kom tia pangon kut ke kom som mweuni mwet Midian? Efu kom ku orekut ouinge?” Elos arulana multikin nu sel Gideon.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 Na el fahk nu selos, “Ma nga tuh orala tia apkuran nu ke ma kowos orala. Finne ma na srisrik kowos mwet in sruf lal Ephraim orala an, yohk liki na ma nukewa mwet in ota lal Abiezer elos orala.
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Saya pacna, ke ku lun God kowos tuh uniya leum luo lun mwet Midian ah, Oreb ac Zeeb. Mea nga tuh orala yohk liki ma kowos orala inge?” Ke el fahkla ma inge, elos tila toasr sel.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 In pacl se inge, Gideon ac mwet tolfoko lal ah tuku nu Infacl Jordan ac fahsr alukela. Elos arulana totola, tusruktu elos srakna ukwe mwet lokoalok lalos.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Ke elos sun acn Sukkoth, Gideon el fahk nu sin mwet in acn sac, “Nunak munas, sang kutu bread an nu sin mwet luk inge. Elos arulana totola, ac nga srakna ukwe tokosra luo lun mwet Midian: Zebah ac Zalmunna.”
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Na mwet kol lun acn Sukkoth elos fahk nu sel, “Efu ku kut in sang mongo nu sin mwet mweun lom an? Kom soenna sruokilya Zebah ac Zalmunna.”
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Na Gideon el topuk nu selos, “Fin ouingan, LEUM GOD El fin ase Zebah ac Zalmunna nu inpouk, nga ac fah use kokul ac mah fakfuk yen mwesis uh ac sang sringil kowos.”
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Na Gideon el som nu Penuel ac ngisre mwet we oana ke el tuh ngisre mwet Sukkoth ah, ac mwet we elos topkol oapana mwet Sukkoth ah.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Na Gideon el fahk nu sin mwet Penuel, “Ke nga ac kutangla foloko, nga ac kunausya tower se inge!”
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Zebah ac Zalmunna eltal muta in acn Karkor wi mwet mweun laltal. Siofok longoul tausin mwet mweun lalos misa, ac singoul limekosr na tausin srakna moul.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Gideon el ut sisken yen mwesis kutulap in Nobah ac Jogbehah, ac mweuni mwet lokoalok lalos inge in lukma.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Zebah ac Zalmunna, tokosra luo lun mwet Midian, elos kaing, tusruktu Gideon el ukwaltal ac sruokoltal uh, na mwet mweun nukewa laltal ah fohsak.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Ke Gideon el folok liki mweun ah, el ut ke Innek In Utyak Nu Heres.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 In pacl se inge el sruokya mwet fusr Sukkoth se ac siyuk inen mwet kol lun acn Sukkoth. Na mwet fusr sac simusla inen mwet itngoul itkosr ac sang nu sel Gideon.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Na Gideon el folokla nu yurin mwet Sukkoth ac fahk, “Kowos esam ke kowos tuh srunga kasreyu? Kowos tuh fahk mu kowos ac tia ase mwe mongo nu sin mwet luk inge, ke sripen nga soenna sruokilya Zebah ac Zalmunna. Liye, eltal a inge!”
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Na el eis kokul ac mwe fakfuk in acn mwesis uh sang akkeokye mwet kol lun Sukkoth.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 El oayapa kunausya tower in acn Penuel ac uniya mwet we.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Na Gideon el siyuk sel Zebah ac Zalmunna, “Fuka luman mwet komtal tuh uniya in acn Tabor ah?” Eltal topuk nu sel ac fahk, “Elos oana kom. Elos nukewa oana luman wen nutin tokosra uh.”
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Na Gideon el fahk, “Elos ma wiuk, ma nutin nina kiuk ah. Nga fulahk nu sumtal, komtal funu tia onelosi, nga lukun tia pac uni komtal uh.”
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Na el forang nu sel Jether, wen se omeet natul ah, ac fahk, “Oneltalu!” Tusruktu tulik sac tiana faisak cutlass natul ah, mweyen el srakna fusr, oru el sangeng.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Na Zebah ac Zalmunna fahk nu sel Gideon, “Fahsru sifacna unikuti. Fal sie mukul in orekma in mukul.” Na Gideon el oneltalu, ac eisla mwe naweyuk liki inkwawen camel natultal ah.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Tukun ma inge, mwet Israel elos fahk nu sel Gideon, “Kom in leum facsr — kom ac fwil nutum an — mweyen kom molikutla liki mwet Midian.”
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Ac Gideon el fahk nu selos, “Nga ac fah tia leum fowos, oayapa wen nutik ac fah tia leum fowos. LEUM GOD El fah leum fowos.”
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Na el sifilpa fahk, “Nga ke siyuk ma se suwos. Kais sie suwos in ase nu sik yaring ma kowos eisla sin mwet Midian.” (Mweyen mwet Midian elos oana mwet forfor yen mwesis wialos uh, elos sracsra yaring.)
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Ac elos topuk nu sel, “Kut insewowo in asot ma inge nu sum.” Elos laknelik nuknuk se, ac kais sie selos sang ma oasr sel.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Toasriyen yaring gold ma orekeni inge yohk liki paun angngaul, sayen na mwe naweyuk ac walwal ac nuknuk sroninmutuk lun tokosra luo ah, ku mwe yun ke kwawen camel natultal ah.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Na Gideon el orala sie ma sruloala ke gold ma el eisani inge, ac el filiya in acn sel sifacna, Ophrah. Mwet Israel nukewa elos forla liki God, ac elos som ac alu nu ke ma sruloala se inge, su kwasrip se nu sel Gideon ac sou lal.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Ouinge mwet Israel elos kutangla mwet Midian, ac mwet Midian elos tia sifil orek lokoalok nu selos. Acn Israel muta in misla ke lusen yac angngaul, nwe ke pacl se Gideon el misa.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Gideon el folokla nu in acn sel ac muta we.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Oasr wen itngoul natul, mweyen pus mutan kial.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Oasr pac mutan kulansap se kial in acn Shechem, ac el oswela pac wen se nu sel Gideon, ac Gideon el sang inel Abimelech.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Gideon, wen natul Joash, el misa ke el arulana matu, ac elos piknilya yurin papa tumal in acn Ophrah, acn sin ota lal Abiezer.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Tukun Gideon el misa, mwet Israel elos sifilpa forla liki God ac alu nu sin Baal. Elos eisal Baal-lun-Wuleang tuh elan god lalos.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Elos tia sifil kulansap nu sin LEUM GOD lalos, su tuh molelosla liki mwet lokoalok nukewa lalos su raunelosla.
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 Ac elos tia pac akilen sou lal Gideon ke orekma wo puspis el tuh oru nu selos ah.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Mwet Nununku 8 >