< Mwet Nununku 6 >
1 Mwet Israel elos sifilpa orekma koluk ye mutun LEUM GOD, na LEUM GOD El eisalosyang nu inpoun mwet Midian ke lusen yac itkosr.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Mwet Midian elos ku liki mwet Israel, ke ma inge mwet Israel elos wikwik in luf ku kutepacna acn elos ku in wikla we fineol uh.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Pacl nukewa ma mwet Israel inge ac yukwi sacn sunalos uh, mwet Midian ac mwet Amalek ac mwet ma muta yen mwesis uh elos ac tuku ac orek lokoalok nu selos.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Mwet inge ac tuku tulokinya lohm nuknuk selos uh in acn elos imai inge, ac kunausla ima ac sacn sunalos uh. Elos ac kunausla acn inge som na nwe eir apkuran nu Gaza. Elos ac oayapa sruok sheep, cow, ac donkey natulos, ac tia filiya kutena ma nu sin mwet Israel.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Ke mwet inge ac tuku wi ma orakrak natulos ac lohm nuknuk selos uh, elos arulana pus oana pusiyen locust uh. Mwet inge, weang camel natulos uh, elos arulana pusla, tia ku in oaoala. Elos ac fahsrot kunausla acn na lulap,
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 ac wangin ma mwet Israel ku in oru nu selos. Na mwet Israel elos wowoyak nu sin LEUM GOD tuh Elan kasrelos.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Ke mwet Israel elos wowoyak nu sin LEUM GOD ke sripen mwet Midian inge,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 na LEUM GOD El ac supwama sie mwet palu nu yurin mwet Israel, ac el ac fahk nu selos, “LEUM GOD El fahk, Nga God lun Israel, su uskowosme liki sruoh lowos in acn Egypt.
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Nga molikowosla liki mwet Egypt, oayapa liki mwet su lain kowos in facl se inge. Nga lusak mwet lokoalok lowos ye motowos ac eisla facl selos ac asot tuh in ma lowos.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Nga tuh fahk nu suwos lah nga LEUM GOD lowos, ac kowos in tia alu nu sin god lun mwet Amor su kowos muta fin acn selos inge. Tuh pa kowos tiana porongeyu.”
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Na sie lipufan lun LEUM GOD El tuku nu Ophrah ac muta ye sak oak soko sunal Joash, sie mwet in ota lal Abiezer. Gideon, wen natul, el wikla muta tuktuk wheat ke nien fut wain, mwet Midian inge in tia liyal.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Na lipufan sac sikyang nu sel ac fahk, “LEUM GOD El wi kom. Kom sie mwet ku ac pulaik!”
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Na Gideon el fahk nu sel, “Oasr sie ma nga kena siyuk sum. LEUM GOD El fin wi kut, efu ku ma inge sikyak ouinge nu sesr— Pia sruhk ma wowo mwet matu lasr meet ah tuh srumun nu sesr mu LEUM GOD El tuh oru wo nu selos ke El tuh usalosme liki acn Egypt ah— Pacl inge LEUM GOD El siskutla ac filikuti ye poun mwet Midian inge.”
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Na LEUM GOD El fahk nu sel Gideon, “Fahsrot ke ku lom kewa, ac molela mwet Israel liki mwet Midian. Nga pa supwekom uh.”
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Ac Gideon el topuk ac fahk, “O LEUM GOD, nga ac molela Israel fuka— Ota luk uh pa munas emeet ke sruf lal Manasseh, ac nga pa pilasr emeet in sou luk uh.”
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 LEUM GOD El fahk nu sel, “Kom ku in oru mweyen nga ac fah kasrekom. Kom ac fah itungya mwet Midian inge arulana fisrasr, oana in mwet sefanna.”
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Ac Gideon el topuk, “Nga fin ohi sum, nga siyuk tuh kom in ase sie mwe akul in akpwayeye lah kom pa LEUM GOD.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Nunak munas, nikmet som nwe ke nga use kutu mwe mongo nu sum.” Na lipufan sac fahk, “Nga ac mutana nwe ke kom foloko.”
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Na Gideon el som nu in lohm sel ah, ac akmolyela nani fusr soko, ac el eis sie bushel in flao ac munanla bread wangin mwe pulol kac. El sang ikwa sac nu in fotoh se ac sup ah nu in tup se, ac use ma inge nu yurin lipufan lun LEUM GOD su muta ye sak oak soko ah, ac el sang nu sel tuh elan mongo.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Ac lipufan sac fahk nu sel, “Filiya ikwa ac bread an fin eot se inge, ac okoaung sup an nu fac.” Gideon el oru oana.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Na lipufan lun LEUM GOD el asroela sak soko oan inpaol ah, ac pusralla ikwa ac bread inge ke mutun sak soko ah. Na e se sikyak ke eot sac twe esukak ikwa ac bread inge. Na lipufan sac wanginla.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Ke ma inge Gideon el akilen lah lipufan lun LEUM GOD pa el liye ah. Na Gideon el sangeng ac fahk, “O LEUM GOD Fulat, nga liye na pwaye lipufan lom — kut angetani sie sin sie!”
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 A LEUM GOD El fahk nu sel, “Misla nu sum, ac nikmet sangeng. Kom ac fah tia misa.”
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Ac Gideon el etoak sie loang nu sin LEUM GOD in acn sac, ac el pangon loang sac “LEUM GOD El Misla.” (Loang se inge srakna oan Ophrah nwe misenge. Acn sac ma lun ota lal Abiezer.)
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 In fong sacna LEUM GOD El fahk nu sel Gideon, “Eis cow mukul nutin papa tomom an, ac soko pac ma yac itkosr matwa, ac kunausya loang lun Baal su papa tomom el orala, ac pakpakiya ma sruloala kacl god Asherah, su ma oanna siska an.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Etoak sie loang na wowo an nu sin LEUM GOD lom fin tohktok se inge. Ac eis cow soko aklukwa ma yac itkosr an, ac oru sie kisa firir an kac, ac etongkin kutkut in sak ma kom pakpakiya ke ma sruloala kacl Asherah.”
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Na Gideon el eis mwet singoul sin mwet kulansap lal ac oru oana ma LEUM GOD El fahk nu sel. El arulana sangeng sin sou lal ah, ac sin mwet in siti uh, pwanang el kofla oru ma inge ke len, a el oru ke fong.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Ke mwet in siti uh toang tukakek in lotu tok ah, elos liye tuh loang lal Baal ac ma sruloala kacl Asherah ah musalsalu, ac cow soko aklukwa ah kisakinyuk tari fin loang se su musaiyukyak.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Mwet uh asiyuki sie sin sie ac fahk, “Su oru ma se inge?” Elos suk nwe konauk tuh na Gideon, wen natul Joash, pa oru ma sac.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Na elos fahk nu sel Joash, “Use wen nutum nu inge tuh kut in unilya! El kunausla loang lal Baal ac pakpakiya ma sruloala lal Asherah su oan siska.”
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Ac Joash el fahk nu selos su tuku in lainul, “Ya kowos ac welul Baal lac— Ya kowos ac eis acn sel— Kutena mwet fin welul, el ac fah anwuki meet liki lututang. Baal el fin sie god, lela elan sifacna molella. Ma lal pa loang se ma kunausyukla ah.”
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Tukun pacl se inge, pangpang Gideon “Jerubbaal,” ke sripen Joash el fahk mu, “Lela Baal elan sifacna molella. Ma lal pa loang se ma kunausyukla ah.”
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Na mwet Midian, mwet Amalek, ac mwet yen mwesis uh elos toeni, ac fahsr sasla Infacl Jordan ac tulokunak lohm nuknuk selos ke Infahlfal Jezreel.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Ngunin LEUM GOD tuku nu facl Gideon, ac el ukya mwe ukuk uh in pangon mwet in ota lal Abiezer tuh elos in fahsr tokol.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 El supwala mwet utuk kas in fahsr sasla acn lun mwet Manasseh Roto ac mwet Manasseh Kutulap kewa elos in tuku fahsr tokol. El supwala pac mwet utuk kas nu sin sruf lal Asher ac Zebulun ac Naphtali, na elos tuku pac welul.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Na Gideon el fahk nu sin LEUM GOD, “Kom fahk mu kom suleyula tuh kom in orekmakinyu in molela mwet Israel.
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Liye, nga ac filiya kutu unen sheep fin fohk uh in nien kulkul wheat uh. Lututang nga fah liye, fin oasr aunfong ke unen sheep uh a wangin fin fohk uh, na nga fah etu lah pwaye kom ac orekmakinyu in molela mwet Israel.”
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Na sikyak oana ma el siyuk ah. Ke Gideon el toang tukakek in lotu tok ah, el fulala unac sac na kof kac ah nwakla pol se.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Na Gideon el fahk nu sin God, “Nikmet mulat sik, mweyen nga ke fahkak pac sie ma. Nunak munas, lela nu sik tuh nga in srike siyuk sie pac ma ke unen sheep uh. Ke pacl se inge, oru tuh unen sheep uh in pao, ac fin fohk uh in sroksrok.”
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Ke fong sac God El oru oana. Ke lututang ah unen sheep sac pao na, a fin fohk uh sroksrok ke aunfong.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.