< Ezekiel 31 >

1 Ke len se meet in malem aktolu ke yac aksingoul sie in sruoh lasr, LEUM GOD El kaskas nu sik ac fahk,
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 “Kom, mwet sukawil moul la, fahkang nu sin tokosra lun Egypt ac mwet lal nukewa: Fuka lupan ku lom! Mea nga ac ku in lumwe kom nu kac?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Kom oana soko sak cedar in acn Lebanon Ma lesak kac uh kato, ac arulana yohk acn luliya. Soko sak arulana fulat, ac fiya kac sun pukunyeng uh.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Oasr kof in akkapye, Ac infacl soror ye fohk uh in akmongoi. Infacl inge aksroksrokye acn ma sak soko inge kapak we Ac supwala infacl srisrik nu ke sak nukewa insak uh.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Ke sripen wo fahsriyen kof uh nu kac El kapak loes liki sak nukewa saya. Lah kac uh kapak loes ac lahlah.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Kain in won nukewa orala ahng lalos in lesak uh, Ac kosro lemnak uh oswe natu natulos ye lulin sak uh. Mutunfacl nukewa mongla ye lulin sak soko inge.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Fuka oaskuiyen sak soko ah — Kapak arulana fulat, ac loes lah kac. Okah kac uh som nwe ke sun kof ye fohk uh.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Wangin sak cedar in ima lun God ma ku in lumweyuk nu kac. Soenna oasr sak fir ma lahlah oana sak soko ah, Ac lah ke sak saya nukewa tia wo oana lah ke sak soko inge. Wangin pac sak in ima lun God ma kato oana.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Nga pa orala in arulana oasku ac lahlah. Sak nukewa in Eden, ima lun God, ke ouiyalos sak soko inge.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 “Inge, nga, LEUM GOD Fulatlana, ac fahk nu sum ma ac sikyak nu ke sak soko ah, su kapak nwe ke na sun pukunyeng uh. Ke el kapak fulat, nunak lal uh fulatak pac.
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 Ouinge nga sisella ac eisalang nu sin sie leum in siena mutunfacl. El ac fah oru nu sin sak soko ah fal nu ke orekma koluk lal.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 Mwet sulallal in mutunfacl saya elos ac fah pakiya, ac som liki. Lah kac, wi lah srisrik uh, ac fah putati nu fineol nukewa ac infahlfal nukewa in facl sac. Mutunfacl nukewa ma tuh muta ye lulin sak uh elos ac fahsrelik.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 Won yen engyeng uh ac fah sohkma ac tuhwi fin sak ikori soko ah, ac kosro lemnak uh ac fah fahsr fin lesak uh.
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 Ke ma inge, in pacl se ingela, wangin sak ac ku in sifil kapak fulat ac sun pukunyeng uh oana fulatiyen sak soko ah, finne aksroksrokyeyuk wo. Sak nukewa ac fah misa oana mwet uh, ac welulosyang su som tari nu in facl lun mwet misa.”
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Pa inge ma LEUM GOD Fulatlana El fahk: “Ke len se ma sak soko uh ac som nu in facl sin mwet misa, nga fah oru tuh kof ye fohk uh in afunla sak soko ah, in oana sie akul in asor. Nga ac fah sikulya infacl uh, ac tia lela kutena unon srisrik in sororla. Mweyen sak soko inge misa tari, nga ac fah oru lohsr matoltol in luliya fineol in acn Lebanon, ac oru tuh sak nukewa insak uh in uli. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Ke pacl se nga ac supweya sak soko uh nu in facl sin mwet misa uh, ngirla lun ikori lal uh ac fah osrokak mutunfacl uh. Sak nukewa in Eden, ac sak sacnsan nukewa ma aksroksrokyeyuk wo in acn Lebanon ma som tari nu ten ye faclu, ac fah engankin lah ikori. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 Elos ac fah wi sak soko inge som nu in facl sin mwet misa, in tuh weang sak nukewa ma ikori tari. Na mwet nukewa su muta ye lulin sak soko ah, ac fahsrelik nu in facl saya uh. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 “Sak soko inge pa tokosra lun acn Egypt ac mwet nukewa lal. Wangin sak in ima Eden ma fulat ac kato oana sak soko uh. Tusruktu inge el ac oana sak Eden uh, ac som nu in facl sin mwet misa, ac weang mwet su tia etu God, ac elos su anwukla ke mweun. Nga, LEUM GOD Fulatlana, pa fahk ma inge.”
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ezekiel 31 >