< Deuteronomy 3 >

1 “Toko, kut mukuiyak ac som nu epang ke inkanek nu Bashan, ac Tokosra Og el tufokme wi mwet lal nukewa in mweuni kut apkuran nu ke siti Edrei.
Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
2 Tusruktu LEUM GOD El fahk nu sik, ‘Nimet sangeng sel. Nga ac eisalot, mwet lal, ac acn lal nukewa nu inpoum. Oru nu sel oana ke kom oru nu sel Tokosra Sihon lun mwet Amor su leum in Heshbon.’
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
3 “Ouinge LEUM GOD El eisalma Tokosra Og nu inpaosr pac, ac kut onelosla nukewa.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
4 Kut sruokya siti lal nukewa in pacl sac — wangin sie acn lal kut tia eisla. Oasr siti onngoul kut sruokya — acn Argob nufon, su Tokosra Og lun Bashan el leumi.
Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
5 Siti inge nukewa orekla ku ke pot fulat, ac ipinsak na lulap pa sang laki srungul ke mutunpot uh, ac oasr pac siti srisrik ma wangin pot kac.
Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
6 Kut kunausla siti nukewa ac onela mukul, mutan, ac tulik nukewa, oana ke kut tuh oru nu ke siti lal Tokosra Sihon lun Heshbon.
Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
7 Kut usla kosro nukewa ac ma saok nukewa in siti lalos.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
8 “In pacl sac, kut eisla sin tokosra luo lun mwet Amor inge, acn nukewa kutulap in Infacl Jordan, mutawauk Infacl Arnon lac nwe ke Eol Hermon. (
Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
9 Mwet Sidon elos pangon Eol Hermon “Eol Sirion” ac mwet Amor elos pangon “Eol Senir.”)
(Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
10 Kut eisla acn nukewa sel Tokosra Og lun Bashan: siti nukewa yen tupasrpasr uh, wi acn nukewa lun Gilead ac Bashan, som na nwe ke siti Salecah ac Edrei, su oan kutulap.” (
Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
11 Tokosra Og pa safla ke mwet ma pangpang Rephaim. Box in misa lal orekla ke eot, fit onkosr sralap ac apkuran in fit singoul akosr lusa, fal nu ke srikasrak oakwuki in pacl sac. Box sac srakna ku in liyeyuk in siti Rabbah lun mwet Ammon.)
(Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
12 “Ke kut eisla acn inge, nga sang nu sin sruf lal Reuben ac sruf lal Gad acn nukewa epang in siti Aroer apkuran nu Infacl Arnon, ac kutu ipin acn ke fulan eol lun Gilead, wi siti we.
Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
13 Nga sang nu sin tafu sruf lal Manasseh acn lula Gilead ac oayapa acn Bashan nufon, acn ma Tokosra Og el tuh leumi, aok, nufonna acn Argob.” (Eteyuk acn Bashan mu acn sin mwet Rephaim.
Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
14 Jair, sie mwet in sruf lal Manasseh, el eis acn Argob, nufon — acn inge pa Bashan, som na nwe ke masrol lun Geshur ac Maacah. El sang inel sifacna nu ke acn inge, na srakna pangpang acn we “Siti Srisrik lal Jair.”)
Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
15 “Nga sang Gilead nu sin sou lal Machir in sruf lal Manasseh.
Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
16 Ac nu sin sruf lal Reuben ac sruf lal Gad nga sang acn nukewa inmasrlon Gilead lac nu Infacl Arnon. Infulwen infacl soko ah pa masrol lalos nu layen eir, ac masrol layen nu epang pa Infacl Jabbok, su sie ip kac pa masrol lun mwet Ammon.
ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
17 Ke layen nu roto, acn selos fahla na nwe Infacl Jordan, layen epang mutawauk meoa Galilee ac putati nwe Meoa Misa nu eir, na fahla nu pe eol Pisgah layen kutulap.
Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
18 “In pacl sac pacna, nga sapkin nu selos mu, ‘LEUM GOD lasr El sot facl kutulap in Infacl Jordan tuh in ma lowos. Inge sang kufwen mwe mweun nu sin mwet mweun lowos, ac supwalosla in fahsr sasla Infacl Jordan meet liki sruf lun Israel ngia, in kasrelos eis facl sac lalos.
Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
19 Mutan kiowos, tulik nutuwos, ac kosro nutuwos fah tia wi som, a elos in mutana ke siti ma nga sot nu suwos. Nga etu lah pukanten kosro nutuwos.
Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
20 Kasru mwet Israel wiowos nwe ke elos eis acn selos ma LEUM GOD El ac sang lalos ke layen roto in Infacl Jordan, nwe ke LEUM GOD El oakelosi in muta in misla, oana ke El oru tari nu suwos inge. Na toko, kowos fah ku in foloko nu yenu, nu ke acn ma nga sot lowos.’
títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
21 “Na nga fahkang nu sel Joshua: ‘Kom liye tari ma nukewa ma LEUM GOD lom El oru nu sel Tokosra Sihon ac Tokosra Og, ac El ac fah oru oapana nu sin tokosra nukewa ke acn ma kom ac mweuni uh.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
22 Nimet sangeng selos, tuh LEUM GOD lom El ac fah mweun keim.’
Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
23 “In pacl sac, nga kwafeang in pre ac fahk,
Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
24 ‘O LEUM GOD Fulatlana, nga etu lah kom tufahna mutawauk in akkalemye nu sik lupan ku lom ac fulat lom. Wangin sie god inkusrao ku fin faclu su ku in oru orekma kulana oana ma kom orala!
“Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
25 LEUM GOD, lela nu sik in fahsr alukela Infacl Jordan, ac liye facl wo se layeno ingo, oayapa fulan eol kato we ac fineol lun acn Lebanon.’
Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
26 “Tusruktu ke sripowos, LEUM GOD El mulat sik ac tia lungse porongeyu. A El fahk, ‘Tari! Nimet sifilpa fahk!
Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
27 Fanyak nu fin mangon Eol Pisgah ac ngetla nu epang ac nu eir, nu kutulap ac nu roto. Liye akwoya, mweyen kom ac koflana alukela Infacl Jordan.
Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
28 Sang kas in kasru nu sel Joshua ac akkeye nunak lal, mweyen el pa ac kol mwet uh in alukela Infacl Jordan ac oakwuki in acn ma kom ngetot liye ingo.’
Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
29 “Ouinge kut mutana infahlfal se tulanang siti Bethpeor.”
Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.

< Deuteronomy 3 >