< Deuteronomy 17 >

1 “Nimet kisakin nu sin LEUM GOD lowos, kutena cow ku sheep ma oasr kutena ma koluk ke mano. Ma inge mwe srungayuk sel.
Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
2 “Kowos fin lohng lah oasr in sie sin siti suwos, sie mwet — mukul ku mutan — su orekma koluk lain LEUM GOD ac kunausla wuleang lal
Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
3 ke el alu ku orekma nu sin god saya, ku nu ke faht, malem ku itu, ac ma inge lain ma sap lun LEUM GOD.
èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
4 Kowos fin lohng kain in pweng inge, kowos sokak akwoya. Fin pwaye lah ma koluk se inge sikyak in Israel,
tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
5 na usla mwet sac nu likin siti uh, ac tanglal nwe ke el misa.
Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
6 Tusruktu, el ac anwuki fin oasr mwet loh luo ku pus liki, su lainul; el fah tia anwuki fin oasr mwet loh sefanna.
Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
7 Mwet loh inge pa ac tanglal meet uh, toko na mwet ngia fah wi tanglal. Pa inge ma ac oru lumah koluk se inge in wanginla.
Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
8 “Kutu pacl uh, ac upa nu sin mwet nununku in sie siti in orala wotela lalos in konauk ma pwaye ke kain in sripa inge: suwohs ke ma lun mwet ke acn, ku ke musalla lun mano, ku ke misa se lah ma ke ongla ouiya ku akmas akola se. Pacl lumah ouinge sikyak, kowos in som nu ke acn in alu se ma LEUM GOD lowos El sulela kowos in alu we,
Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
9 ac sang sripa lowos nu sin mwet Levi su mwet tol, ac nu sin mwet nununku se su orekma in pacl sac, elos in wotela.
Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
10 Elos ac orala wotela lalos, na kowos fah oru oana ma elos fahk.
Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
11 Kowos in insese nu ke konauk lalos, ac fahsr fal nu ke ma nukewa elos sapkin.
Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
12 Kutena mwet su seakos ma mwet nununku sac ku mwet tol se su orekma ke pacl sacn wotela uh, fah anwuki. In ouiya se inge kowos ac fah sisla ma koluk se inge liki Israel.
Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
13 Mwet nukewa fah lohng kac ac sangengla, na wangin mwet ac sifil pulaik in oru lumah inge.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
14 “Tukun kowos ac eisla facl se LEUM GOD lowos El ac sot nu suwos ac kowos oakwuki tari we, na kowos ac lungse in oasr sie tokosra lowos, in oana mutunfacl nukewa su raunikowosla.
Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
15 Karinganang tuh mwet se kowos ac sulela in tokosra elan mwet se ma LEUM GOD El sulela. El enenu elan siena sin mwet Israel wiowos. Nik kowos oru sie mwetsac in tokosra lowos.
Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
16 Tia enenu in pukanten horse nutin un mwet mweun lal tokosra, ac elan tia supwala mwet nu Egypt in moul horse we, mweyen LEUM GOD El fahk tari mu mwet lal in tia sifil folok nu we.
Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
17 In tia pus mutan kien tokosra, mweyen elos ac ku in kifasulla liki LEUM GOD; ac elan tia sifacna akkasrupyal ke silver ac gold.
Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
18 Pacl se el ac tokosrala, enenu in oasr yorol sie ma simusla ke book in ma sap ac kas in luti lun God, ma simla oana book limlim emeet ah ma karinginyuk sin mwet tol Levi.
Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
19 Book se inge elan karingin in oanna siskal, ac elan riti in moul lal nufon tuh elan lutlut in arulana akfulatye LEUM GOD, ac in oaru in akos ma nukewa ma sapkinyuk loac.
Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
20 Ma inge ac fah oru elan tia nunku mu el wo liki mwet Israel wial, oayapa elan tia seakos ma sap lun LEUM GOD in kutena ouiya. Na el fah leum ke yac puspis, ac fwilin tulik natul ac fah leumi Israel ke fwil puspis tokol.
Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.

< Deuteronomy 17 >