< Izikeli 6 >

1 Ra Anumzamo'a amanage huno nasami'ne,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
2 Vahe'mofo mofavremoka, Israeli agonaramintega kavugosa hunte'nenka amanage hunka kasnampa kea hunto,
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3 Israeli agonaramimoka Ra Anumzamofo nanekea antahio! Ra agonaramine osi agonaramine, tinkrahotamine, aguporaminenkura Ra Anumzamo'a huno, Nagra ha' vahetami huzmanta'nenkeno agonaramimpima havi anumzama mono'ma hunentaza kumara eri haviza hugahaze.
wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
4 Ana nehu'za havi anumzante'ma kresramnama nevaza itaramina, tapagehu netre'za mnanentake zama kre'mnama nevaza itaramina rurakoraku nehu'za, kaza osu havi anumzantmimofo zamavuga vahetmina zamahe vatu hugahaze.
Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
5 Hagi Israeli vahe'ma fri'naza zamavufaga kaza osu havi anumzazmimofo zamavuga eri tru hunente'na, zaferinazmia kresramna vu itaraminte rupanani hu'na atrena kagigahue.
Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
6 Mika nemaniza kumatamine, rankumatmimo'enena havizantfa hinkeno, mono'ma nehaza agona kumatmimo'enena haviza hugahie. Hagi mono'ma nehaza agona kumatmimpima me'nea kresramna vu itaramine, kaza osu havi anumzantamine, mnanentake zama kre mnama nevaza itaraminena taganavaziza eri havizantfa hanageno, tro'ma hunteneta mono'ma nehaza zantmimo'a maka fanane hugahie.
Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
7 Hagi maka kaziga ha' vahe'mo'za vahera zamahe fri vagaresageta, manisaza nagamota negeta Nagrikura Ra Anumza mani'ne huta keta antahita hugahaze.
Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 Hianagi mago'a vahera ozamahe zamatregahue. Na'ankure ha' vahe'mo'za zamavare'za vanage'za ru kumategane mago'a mopafi mago mago hu'za umanigahaze.
“‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
9 Hagi kina huzamante'za zamavare'za vanaza vahetmimofo kumatega umani'neza, Nagri'ma zamagenama hunenamiza havi anumzama kezamanunuma hu'za mono'ma huntazage'nama narimpa knama hu'noa zankura zamagesa antahigahaze. Na'ankure zamagra hi'mnage huno kasri avu'ava hu'naza zanku zamagazegu hugahaze.
Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
10 Ana nehu'za Nagrikura Ra Anumza mani'ne nehu'za, kema hu'nea kemo'a amne zanknara osu'neanki, knaza tamino tazeri haviza hie hu'za ke'za antahi'za hugahaze.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
11 Ra Anumzamo'a huno, Kazana nerunka kagia mopare nemasaginka amanage huo, Avo! Israeli vahe'mo'za kasrino hi'mnage avu'ava'ma hazazamo higeno ha' vahe'mo'zane, agatonto zane, kefo kriramimo'enena zamazeri haviza hie hunka huo.
“‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
12 Hagi afete moparegama mani'nesaza vahetmina kefo krimo zamahe nefrinigeno, tavaonte'ma manisaza vahera ha' vahe'mo'za zamahe nefrisageno, mago'ama manisaza vahe'mo'za zamagaku hu'za frigahaze. E'ina hu'na maka narimpa ahe'zana zamagrite maka rupopo hutre vagaregahue.
Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
13 Hagi ha' vahe'mo'zama zamahesage'za frisaza vahe'mokizmi zamavufagamo'a maka osi agonaramimpine, ranra agonaramimpine, zafa agafafine, anina kuronkuro hu oki zafa agafafine, kaza osu havi anumzazmimofo amu'nompine, mnanentake'zama kremnama nevaza itaramimofo avuganena megagi'nenige'za nege'za Nagrikura Ra Anumza mani'ne hu'za ke'za antahi'za hugahaze.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
14 Ana hute'na mopazmire nazana rutare'na ka'ma mopareti agafa huteno vuno Ribla kumate'ma uhanati'nia mopa eri havizantfa hanuge'za, Nagrikura Ra Anumza mani'ne hu'za ke'za antahi'za hugahaze.
Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Izikeli 6 >