< 2 Kroniku 20 >

1 Hagi ana'ma hutegeno'a, Moapu vahe'ma, Amoni vahe'ma, mago'a Meuni vahe'ma hu'za Jehosafatina hara eme hunte'za hu'naze.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
2 Hagi mago'a vahe'mo'za Jehosafatina amanage hu'za eme asami'naze, Tusi'a vahekrerfamo'za ha' hugante'naku hagerimofo kantu kaziga Edomuti e'za Hazazon-tamari emani'naze hu'za eme asmi'naze. (Hazazon-tamaria mago agi'a Engedi'e).
Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
3 Ananke'ma Jehosafati'a nentahino'a, tusi koro nehuno Ra Anumzamofo avesi'zankura nunamuna huno antahinegeno, mika Juda vahera ke hige'za ne'zana a'o hu'za Ra Anumzamofontega nunamu hu'naze.
Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
4 Hagi mika Juda vahetmimo'za emeri atru hu'za Ra Anumzamo'ma zamaza hanigura antahige'naze. Mika Juda rankumapintira Ra Anumzamofontega nunamu hu'za antahige'naku eme atru hu'naze.
Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
5 Hagi mika Juda vahe'ene Jerusalemi vahetmimofo zamavugane Ra Anumzamofo mono nomofo avuga kasefa kuma'ma tro'ma hunte'nazafi Jehosafati'a oti'neno,
Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
6 amanage huno nunamuna hu'ne, Ra Anumzana Kagra tafahe'i Anumzamoka kagra monafi Anumzana mani'nane. Kagrake'za maka ama mopafi kumatmina kegava hu'nane. Kagri kazampinke maka hihamu hankavea me'neankino, mago vahe'mo'e huno hara hugageteoregahie.
O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
7 Kagra Anumzantimoka, Israeli vaheka'a zamavufi ama mopafima ko'ma mani'naza vahera zmahenatitrenka, kanampaka'a Abrahamu agehemofo ama mopa zamagri mopa mevava hugahie hunka zami'nane.
Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
8 Hagi zamagra ama ana mopafi mani'ne'za mono'ma hugantesaza mono nona kintete'za amanage hu'naze,
Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
9 ha' eme hurante'nazo, hazenke'za fore hanio, ruzahu ruzahu kri fore hanio, agatonto kna fore haniana ama Kagri kagima erisgahu mono nomofo avuga otita Kagritega krafagema hanunkenka, krafagetia antahiraminka knazanpintira tagu'vazigahane hu'none.
‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
10 Hagi tagehemofo Israeli vaheku'ma hanke'za Isipitima ne-eza Moapu vahe'ma, Amoni vahe'ma' Seiri agonafima nemaniza vahera ha'ma huozmante'za zamagatere'za e'naza vahe'mo'za menina ha' hurantenaku neaze.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
11 Hagi e'i anahu avu'ava'ma huzmante'nonte, miza neramiza erisantihareho hunkama tami'nana mopafintira eme tahenatitre'za ama mopa eri'naku neazafi ko?
Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
12 Hagi Anumzantimoka nahanigenka kagra refko hunka keaga ana zantera hunezmantenka hazenkea ozamigahane? Na'ankure tagra ama tusi vahekrerfama neazana knarera osu'nonankita, hara huozmante'gahune. Hagi antahintahi timo'a savari higeta, tazama hanankura kagri kavufinke keteta mani'none.
Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
13 Anage'ma nehigeno'a, mika Juda venenemo'za ne'one mofavrezmine, a'nezamine, mofavre'zmine Ra Anumzamofo avuga oti'za mani'nazageno,
Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
14 ana vahe amu'nompi Zekaraia nemofo Jahazielinte Ra Anumzamofo Avamumo'a e'ne. Hagi Zekaraia'a Benia nemofo'e, Benia'a Jeieli nemofo'e, Jeieli'a Matania nemofo Livae nekino, Asapu ne' mofavreramimpinti ne' mani'ne.
Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
15 Hagi Jahazieli'a amanage hu'ne, Mika Juda vahe'ma, Jerusalemi kumapima nemaniza vahe'motane kini ne' Jehosafetiganena antahiho, Ra Anumzamo'a amanage hie, ha'ma huramante'naku'ma, tusi'a sondia vahekrerfamo'zama aza vahekura tamahirahikura huta korora osiho, na'ankure ama hara tamagri hara omne'neanki, Anumzamofo ha' me'ne.
Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
16 Oki'na uramita hara ome huzmanteho. Zamagra Zizi krahopinti marerigahazankita Jerueli hagege kokamofo zage hanati kaziga ome zamagegahaze.
Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
17 Tamagra ama ana hapina hara osugahazanki, oti hankavetita retrohuta manineta Ra Anumzamo'ma tamagritegama anteno tamagu'ma vaziniana keho. Juda vahe'ene Jerusalemi vahe'mota korora nehuta tamahirahikura osiho. Ra Anumzamo'a tamagrane manigahianki, okina hara ome huzmanteho.
Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
18 Anage'ma higeno'a, Jehosafati'a mopafi renaregeno, Juda vahe'mo'zane, Jerusalemima nemaniza vahe'mo'zanena Ra Anumzamofo avuga zamarena re'za kepri hu'za Ra Anumzamofona monora hunte'naze.
Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
19 Ana hazageno Kohati nagapinti Livae vahe'mo'zane, Kora naga'mo'zanena oti'za Ra Anumzana Israeli vahe'mofo Anumzana ranke hu'za zagamera hu'za agi'a ahentesga hu'naze.
Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
20 Hagi nanterame oti'za hagege kokampi Tekoa vu'naze. Hagi anama nevazageno'a, Jehosafati'a otino amanage hu'ne, Juda vahe'ene Jerusalemima nemaniza vahe'enena kama antahiho, Ra Anumzana tamagri Anumzamofonte tamentintia hinkeno tamagu vazino tamaza nehina, Agri kasnampa vahetmimofo kere tamentinti nehuta, knarera huta manigahaze.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
21 Hagi zamavare atru huno ana nanekema zmasamiteno'a, ruotge'ma hu'nea kukena hu'neza vugote'za nevu'za zagamera hu'za Ra Anumzamofoma agima ahentesgama hanaza vahetami zamazeri oti'ne. Hagi anama hutege'za amanage hu'za ana zagamera hu'naze, Ra Anumzamofona susu huntone, na'ankure avesirante'nea zamo'a mevava huno vugahie.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
22 Anagema hutege'za agafa hu'za zagamera ranke hu'za nehazageno Amoni vahe'ma, Moapu vahe'ma, Seiri agonafima nemaniza vahetaminena Ra Anumzamo'a agafa huno zamazeri savri hige'za, hara zamagra zamagra hu'za ohefri ahefria hu'naze.
Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
23 Amoni vahe'ene Moapu vahe'mo'zanena rukrahe hu'za, Seiri agonafi vahera hara huzmante'za zamahe'naze. Hagi Seiri agonafi vahe'ma zamahe vagamarete'za, ete Moapu vahe'mo'zane Amoni vahe'mo'za oti'za zamagra zamagra ohefri ahefri hu'naze.
Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
24 Hagi hagege kokamofoma uruha'ma nehaza agonare Juda vahe'mo'za emarerite'za, kegamanute'za hagege kokantegama kazana mago'mo'e huno atre'nora ofre'neanki ana maka vahetmimo'za fri'za uvase evase hu'nazage'za ke'naze.
Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
25 Hagi kini ne' Jehosafati'ene vahe'amo'zanema ana vahetmimofo fenoma erinaku'ma e'za eme kazana, ana fri vahetmimofo fenoma, ne'zama, kukenama, zago'amo mareri zantaminena, tusi feno me'nege'za eri vagaregara osu'naze. Ana fenoma eri'nazana tusi'a fenonkino, 3'a zage knafi fenona hantage'naze.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
26 Hagi namba 4kna zupa Beraka agupofi emeri tru hu'za muse nehu'za, Ra Anumzamofo agi'a ahentesga hu'naze. E'ina hu'negu ana agupomofo agia Berake (Berakaema hu'nena asomure hu'ne) hu'za hazageno meno eno menina ama knarera ehanati'ne.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
27 Ana hutazageno Jehosafati'a vugota huzmantege'za maka Juda vahetamine, Jerusalemima nemaniza vahe'mo'zanena Ra Anumzamo'ma ha' vahe'zmima ha'ma huzmagaterea zanku zagame nehu'za tusi muse hume Jerusalemi vu'naze.
Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
28 Hagi Jerusalemi kumapima enefre'za, hapu zavenama, laerie nehaza zavenama nehe'za, ufenena nere'za Ra Anumzamofo nompina musenkase hu'za ufre'naze.
Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
29 Hagi Ra Anumzamo'ma Israeli vahe'ma zamaza huno ha' vahezmima zamaheankema ruga'a kumatmimpi vahe'mo'zama nentahi'za, Anumzamofonkura tusi koro hu'naze.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
30 E'ina higeno Jehosafeti'ma kinima mani'noma vu'nea knafina, agri Anumzamo'a ha'zana eri atrege'za maka kazigatira hara eme huozmantage'za fru hu'za mani'naze.
Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
31 Hagi Jehosafati'a 35'a kafu hu'neno Juda vahe kinia efore huno mani'neankino, 25'a kafufi Jerusalemi kumatera kinia mani'ne. Hagi nerera agia Azubakino, agra Silhi mofa mani'ne.
Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
32 Hagi Jehosafati'a ko'ma nefa Asa'ma fatgo avu'ava'ma hu'neaza huno, Ra Anumzamofo avurera fatgo avu'ava hu'ne.
Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
33 Hianagi havi anumzante'ma mono hunentaza kumatmina eri haviza osu'neanki'za, vahe'mo'za zmafahemofo Anumzantera zamagu'aretira hu'za amagera onte'naze.
Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
34 Hagi Jehosafati'ma agafa huno kinima mani'neretima vuno vagamaretema vu'nea knafima tro'ma hu'nea zantmimofo agenkea, Hanani nemofo Jehu avontafepi krentegeno, Israeli kini vahetmimofo agenkema krentenazafi me'ne.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
35 Hagi henka Juda kini ne' Jehosafati'a havi avu'avazama nehia Israeli kini ne' Ahasia'ene eri hagerafino mani'ne.
Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
36 Hagi ana kini netremokea vente trohuke Tasisi vunaku mago zanarimpa huteke, ana venteramina Ezion-Geba kumate trohu'na'e.
Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
37 Ana'ma nehakeno'a higeno'a Maresa kumateti ne' Dodavahu nemofo Eliezeri'a anage huno Jehosafatina kasnampa kea hunte'ne, Na'ankure kagra Ahasia'ene kea hagerafinankino, tro'ma hana venteramina Ra Anumzamo'a eri haviza hugahie. Higeno ana venteramimo'za haviza hazage'za, Tasisia ovu'naze.
Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.

< 2 Kroniku 20 >