< 1 Samue 4 >

1 Hagi Samuelima miko ke'ma Israeli vahe'ma zmasamige'za antahite'za hatera vu'naze. Hagi ana knafina Israeli vahe'mo'za Filistia vahe ha' huzmante'naku Ebenesa kumate seli no ome ki'za mani'nage'za, Filistia vahe'mo'za Afeki kumate seli nona eme ki'za mani'naze.
Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
2 Hagi Filistia vahe'mo'za rama'a sondia vahe zamazeri retrotra hute'za, avazuhumpi hu'za nevu'za, Israeli vahera tusi'a ha' ome huzamante'za 4 tauseni'a sondia vahe ana zupa zamahe fri'naze.
Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
3 Hagi Israeli sondia vahe'mo'zama ha'tetima azage'za kva vahe'mo'za hu'za, na'a higeno Ra Anumzamo'a tatregeno Filistia vahe'mo'za hara hutagateraze? Hagi tagra Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisia Sailo kumatetira omerineta hatera nevanunkeno, ha' vahetimo'za tahe'zankura ana zamo tagu'vazigahie.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
4 Anagema hute'za sondia vahe huzmantage'za Sailo kumatetira Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisima tarega kazigama Serobimi ankerontrema mani'nakeno Anumzamo'ma amu'nompima nemania vogisia ome eri'naze. Hagi Elina tare mofavrearare Hofani'ene Finiasikea ana hugagerafi huvempage bogisine e'na'e.
Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
5 Hagi seli nonkuma'ma ome ante'za mani'nafima ana huhagerafi huvempage vogisima eri'za ehanatizage'za, Israeli vahe'mo'za kezanke hu'za rankema hu'naza agasasamo'a mopa azeri tore hu'ne.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
6 Hagi ana agasankema Filistia vahe'mo'zama nentahi'za, Hibru vahe seli nonkumapina naza fore nehie, hu'za hu'nazanagi henkama antahi'zana Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisi Hibru vahe'mo'za eri'za e'nazanke antahi'naze.
Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
7 Hagi Filistia vahe'mo'za tusi koro nehu'za amanage hu'naze, Israeli vahe'mokizmi mago anumzazamimo seli nonkuma zamifina e'ne, hu'za nehu'za e'inahukna zana kora nonkonaza forehie.
àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
8 Tagra tusi'a hazenkefi manigahu'ne, iza taza huno hankavenentake anumzazmimofo azampintira tavretregahie? E'i ruzahu ruzahu knazanteti ka'ma kopima Isipi vahe'ma zamazeri haviza hu'nea anumzane.
Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
9 Hagi Filistia vahe'mota ru Hibru vahe'mo'zama tagri kazokzo eri'zama eri'nazankna huta, tagra zamagri kazokzo eri'za erisunki, vene'ne mani'nonanki oti hanaveti'neta hara huzmantesune.
Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
10 Hagi ana zupa Filistia vahe'mo'za hanavetiza hara hu'za Israeli vahera zamarotago hu'za rama'a vahe 30 tauseni'a zamahe fri'zageno manizama'amo'za atre'za fre'za seli nonkuma zamirega vu'naze.
Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
11 Hagi ana zupage huhagerafi huvempage vogisia Filistia vahe'mo'za zamahe'za nehanre'za, Elina tare ne' mofavre'ararena Hopnine Finiasinena zanahe fri'naze.
Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
12 Hagi ana zupage Benzameni nagapinti mago ne'mo ha'ma nehazafinti atreno agareno Sailo kumate vuno kukena'a ome tagoto tagatu nehuno, kugusopa kateno anumpi netreno, asunkura hu'ne.
Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
13 Hagi Eli'a nemania tra'a erino eme anteno kante mani'neno negeno, Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisigura tusi agesa nentahino asunku nehigeno, ana ne'mo'a kumapina ufreno ana nanekea zamasamige'za ana rankumapi vahe'mo'za tusi zavi krafa hu'naze.
Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
14 Hagi ana kumapinti'ma zavi krafagema hazanke'ma Eli'ma nentahino, nazafore nehie? Huno nehigeno ana ne'mo'a ame huno eno ana nanekea eme asami'ne.
Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
15 Hagi ana knarera Eli'a 98'a kafu higeno, avumo'a asu hu'negeno keso'e osu'ne.
Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
16 Hagi ana ne'mo'a Elina asamino, Nagra ha'pintira meni ama e'noe, higeno Eli'a huno, mofavrenimoka inankna ha'mo'a nehifi nasamio?
Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
17 Higeno ana kema erino e'nea ne'mo'a Elina asamino, Israeli vahe'mo'za kore atre'za frageno, Filistia sondia vahe'mo'za tusia vahe zamahazageno, anampina tare ne' mofavreka'ararena Hopnike Finiasikea frikeno, hago huhagerafi huvempage vogisia Filistia vahe'mo'za eri'naze.
Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
18 Hagi Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisima eri'naze ke'ma Eli'a nentahino'a amagenaregati traka huno umasegeno, rankumamofo kafante aheno ananke rehantagigeno fri'ne. Na'ankure agra ranafaregeno avufamo'a kna hu'ne. Hagi Eli'a 40'a kafufi Israeli vahe kva mani'ne.
Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
19 Hagi Finiasi nenaro'a amu'ene hu'neno mofavre ante'za nehia knafi anazana fore higeno, ana a'mo'ma antahiama Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisi'a ha' vahe'mo'za erizageno, nenofero ne'ma frigeno, neve'ma fria kema nentahino'a ame huno ata negrigeno renareno mofavrea kasente'ne.
Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
20 Hagi mofavrema kasenenteno fri'zama nehigeno'a, mofavrema azahuno antenemia a'mo'a asamino, ne' mofavre kasentananki korora osuo, huno asamianagi, ana kenona'a osu'ne.
Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
21 Ana higeno ana mofavremofo agi'a Ikabotie huno antemineankino, ana agimofo agafa'a Israeli vahe'mota Anumzamofo hanavemo'a hago tatre'ne hu'ne. Na'ankure Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisia erizageno, nenanofero nera hago fri'geno neve'enena fri'negeno'e.
Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
22 Hagi ana amo'a huno, Anumzamofo hanavemo'a hago Israeli vahera tatre'ne. Na'ankure Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisia hago ha' vahe'mo'za eri'naze.
Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”

< 1 Samue 4 >