< Salmi 136 >

1 Celebrate l’Eterno, perché egli è buono, perché la sua benignità dura in eterno.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
2 Celebrate l’Iddio degli dèi, perché la sua benignità dura in eterno.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
3 Celebrate li Signor dei signori, perché la sua benignità dura in eterno.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
4 Colui che solo opera grandi maraviglie, perché la sua benignità dura in eterno.
Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
5 Colui che ha fatto con intendimento i cieli, perché la sua benignità dura in eterno.
Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
6 Colui che ha steso la terra sopra le acque, perché la sua benignità dura in eterno.
Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
7 Colui che ha fatto i grandi luminari, perché la sua benignità dura in eterno:
Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
8 il sole per regnare sul giorno, perché la sua benignità dura in eterno;
Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
9 e la luna e le stelle per regnare sulla notte, perché la sua benignità dura in eterno.
Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
10 Colui che percosse gli Egizi nei loro primogeniti, perché la sua benignità dura in eterno;
Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
11 e trasse fuori Israele dal mezzo di loro, perché la sua benignità dura in eterno;
Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
12 con mano potente e con braccio steso, perché la sua benignità dura in eterno.
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
13 Colui che divise il Mar rosso in due, perché la sua benignità dura in eterno;
Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
14 e fece passare Israele in mezzo ad esso, perché la sua benignità dura in eterno;
Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
15 e travolse Faraone e il suo esercito nel Mar Rosso, perché la sua benignità dura in eterno.
Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
16 Colui che condusse il suo popolo attraverso il deserto, perché la sua benignità dura in eterno.
Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
17 Colui che percosse re grandi, perché la sua benignità dura in eterno;
Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
18 e uccise re potenti, perché la sua benignità dura in eterno:
Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
19 Sihon, re degli Amorei, perché la sua benignità dura in eterno,
Sihoni, ọba àwọn ará Amori
20 e Og, re di Basan, perché la sua benignità dura in eterno;
Àti Ogu, ọba Baṣani;
21 e dette il loro paese in eredità, perché la sua benignità dura in eterno,
Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
22 in eredità ad Israele, suo servitore, perché la sua benignità dura in eterno.
Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
23 Colui che si ricordò di noi del nostro abbassamento, perché la sua benignità dura in eterno;
Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
24 e ci ha liberati dai nostri nemici, perché la sua benignità dura in eterno.
Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
25 Colui che dà il cibo ad ogni carne, perché la sua benignità dura in eterno.
Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
26 Celebrate l’Iddio dei cieli, perché la sua benignità dura in eterno.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;

< Salmi 136 >