< Proverbi 3 >

1 Figliuol mio, non dimenticare il mio insegnamento, e il tuo cuore osservi i miei comandamenti,
Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
2 perché ti procureranno lunghi giorni, anni di vita e di prosperità.
Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
3 Bontà e verità non ti abbandonino; lègatele al collo, scrivile sulla tavola del tuo cuore;
Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
4 troverai così grazia e buon senno agli occhi di Dio e degli uomini.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
5 Confidati nell’Eterno con tutto il cuore, e non t’appoggiare sul tuo discernimento.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
6 Riconoscilo in tutte le tue vie, ed egli appianerà i tuoi sentieri.
Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
7 Non ti stimar savio da te stesso; temi l’Eterno e ritirati dal male;
Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
8 questo sarà la salute del tuo corpo, e un refrigerio alle tue ossa.
Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
9 Onora l’Eterno con i tuoi beni e con le primizie d’ogni tua rendita;
Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
10 i tuoi granai saran ripieni d’abbondanza e i tuoi tini traboccheranno di mosto.
nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
11 Figliuol mio, non disdegnare la correzione dell’Eterno, e non ti ripugni la sua riprensione;
Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12 ché l’Eterno riprende colui ch’egli ama, come un padre il figliuolo che gradisce.
nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
13 Beato l’uomo che ha trovato la sapienza, e l’uomo che ottiene l’intelligenza!
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
14 Poiché il guadagno ch’essa procura è preferibile a quel dell’argento, e il profitto che se ne trae val più dell’oro fino.
nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15 Essa è più pregevole delle perle, e quanto hai di più prezioso non l’equivale.
Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16 Lunghezza di vita è nella sua destra; ricchezza e gloria nella sua sinistra.
Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
17 Le sue vie son vie dilettevoli, e tutti i suoi sentieri sono pace.
Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
18 Essa è un albero di vita per quei che l’afferrano, e quei che la ritengon fermamente sono beati.
Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
19 Con la sapienza l’Eterno fondò la terra, e con l’intelligenza rese stabili i cieli.
Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
20 Per la sua scienza gli abissi furono aperti, e le nubi distillano la rugiada.
nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
21 Figliuol mio, queste cose non si dipartano mai dagli occhi tuoi! Ritieni la saviezza e la riflessione!
Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
22 Esse saranno la vita dell’anima tua e un ornamento al tuo collo.
Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
23 Allora camminerai sicuro per la tua via, e il tuo piede non inciamperà.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
24 Quando ti metterai a giacere non avrai paura; giacerai, e il sonno tuo sarà dolce.
Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
25 Non avrai da temere i sùbiti spaventi, né la ruina degli empi, quando avverrà;
Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
26 perché l’Eterno sarà la tua sicurezza, e preserverà il tuo piede da ogn’insidia.
Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
27 Non rifiutare un benefizio a chi vi ha diritto, quand’è in tuo potere di farlo.
Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28 Non dire al tuo prossimo: “Va’ e torna” e “te lo darò domani”, quand’hai di che dare.
Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29 Non macchinare il male contro il tuo prossimo, mentr’egli abita fiducioso con te.
Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30 Non intentar causa ad alcuno senza motivo, allorché non t’ha fatto alcun torto.
Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
31 Non portare invidia all’uomo violento, e non scegliere alcuna delle sue vie;
Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
32 poiché l’Eterno ha in abominio l’uomo perverso, ma l’amicizia sua è per gli uomini retti.
Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33 La maledizione dell’Eterno è nella casa dell’empio, ma egli benedice la dimora dei giusti.
Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
34 Se schernisce gli schernitori, fa grazia agli umili.
Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
35 I savi erederanno la gloria, ma l’ignominia è la parte degli stolti.
Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.

< Proverbi 3 >