< Salmi 130 >

1 Cantico di Maalot SIGNORE, io grido a te di luoghi profondi.
Orin fún ìgòkè. Láti inú ibú wá ni èmi ń ké pè é ọ́ Olúwa
2 Signore, ascolta il mio grido; Sieno le tue orecchie attente Alla voce delle mie supplicazioni.
Olúwa, gbóhùn mi, jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
3 Signore, se tu poni mente alle iniquità, Chi potrà durare, o Signore?
Olúwa, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀, Olúwa, tá ni ìbá dúró.
4 Ma appo te [vi è] perdono, Acciocchè tu sii temuto.
Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ, kí a lè máa bẹ̀rù rẹ.
5 Io ho aspettato il Signore; l'anima mia [l]'ha aspettato, Ed io ho sperato nella sua parola.
Èmi dúró de Olúwa, ọkàn mi dúró, àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí.
6 L'anima mia riguarda al Signore, Più che le guardie [non riguardano] alla mattina, Stando a guardar [quando verrà] la mattina.
Ọkàn mi dúró de Olúwa, ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ, àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ.
7 Aspetti Israele il Signore; Perciocchè appo il Signore [vi è] benignità, E molta redenzione.
Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti Olúwa: nítorí pé lọ́dọ̀ Olúwa ni àánú wà, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà.
8 Ed egli riscatterà Israele Di tutte le sue iniquità.
Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.

< Salmi 130 >