< Esdra 2 >
1 OR questi [sono] gli uomini della provincia, che ritornarono dalla cattività, d'infra la moltitudine che Nebucadnesar, re di Babilonia, avea menata in cattività in Babilonia; e ritornarono in Gerusalemme ed in Giudea, ciascuno alla sua città.
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 I quali vennero con Zorobabel, Iesua, Neemia, Seraia, Reelaia, Mardocheo, Bilsan, Mispar, Bigvai, Rehum, [e] Baana. Il numero degli uomini del popolo d'Israele [fu questo: ]
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 I figliuoli di Paros [furono] due mila censettantadue;
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 i figliuoli di Sefatia trecensettantadue;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 i figliuoli di Ara settecensettantacinque;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 i figliuoli di Pahat-Moab, [divisi] ne' figliuoli di Iesua, [e] di Ioab, duemila ottocento-dodici;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 i figliuoli di Elam mille dugentocinquantaquattro;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 i figliuoli di Zattu novecenquarantacinque;
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 i figliuoli di Zaccai settecensessanta;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 i figliuoli di Bani seicenquarantadue;
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 i figliuoli di Bebai seicenventitrè;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 i figliuoli di Azgad mille dugenventidue;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 i figliuoli di Adonicam seicensessantasei;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 i figliuoli di Bigvai duemila cinquantasei;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 i figliuoli di Adin quattrocencinquantaquattro;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 i figliuoli di Ater, per Ezechia, novantotto;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 i figliuoli di Besai trecenventitrè;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 i figliuoli di Iora centododici;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 i figliuoli di Hasum dugenventitrè;
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 i figliuoli di Ghibbar novantacinque;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 i figliuoli di Bet-lehem cenventitrè;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 gli uomini di Netofa cinquantasei;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 gli uomini di Anatot cenventotto;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 gli uomini di Azmavet quarantadue;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 gli uomini di Chiriat-arim, di Chefira, e di Beerot, settecenquarantatrè;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 gli uomini di Rama e di Gheba, seicenventuno;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 gli uomini di Micmas cenventidue;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 gli uomini di Betel e di Ai dugenventitrè;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 i figliuoli di Nebo cinquantadue;
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 i figliuoli di Magbis cencinquantasei;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 i figliuoli d'un altro Elam mille dugencinquantaquattro;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 i figliuoli di Harim trecenventi;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 i figliuoli di Lod, di Hadid, e d'Ono, settecenventicinque;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 i figliuoli di Gerico trecenquarantacinque;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 i figliuoli di Senaa tremila seicentrenta.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 De' sacerdoti: i figliuoli di Iedaia, della famiglia di Iesua, novecensettantatrè;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 i figliuoli d'Immer mille cinquantadue;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 i figliuoli di Pashur mille dugenquarantasette;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 i figliuoli di Harim mille diciassette.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 De' Leviti: i figliuoli di Iesua, e di Cadmiel, d'infra i figliuoli di Hodavia, settantaquattro.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 De' cantori: i figliuoli di Asaf, cenventotto.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 De' figliuoli de' portinai: i figliuoli di Sallum, i figliuoli di Ater, i figliuoli di Talmon, i figliuoli di Accub, i figliuoli di Hatita, i figliuoli di Sobai; in tutto centrentanove.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 De' Netinei: i figliuoli di Siha, i figliuoli di Hasufa, i figliuoli di Tabbaot,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 i figliuoli di Cheros, i figliuoli di Siaha, i figliuoli di Padon.
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 I figliuoli di Lebana, i figliuoli di Hagaba, i figliuoli di Accub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 i figliuoli di Hagab, i figliuoli di Samlai, i figliuoli di Hanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 i figliuoli di Ghiddel, i figliuoli di Gahar, i figliuoli di Reaia,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 i figliuoli di Resin, i figliuoli di Necoda, i figliuoli di Gazam,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 i figliuoli di Uzza, i figliuoli di Pasea, i figliuoli di Besai,
Ussa, Pasea, Besai,
50 i figliuoli di Asna, i figliuoli di Meunim, i figliuoli di Nefusim,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 i figliuoli di Bacbuc, i figliuoli di Hacusa, i figliuoli di Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 i figliuoli di Baslut, i figliuoli di Mehida, i figliuoli di Harsa, i figliuoli di Barcos,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 i figliuoli di Sisera, i figliuoli di Tema,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 i figliuoli di Nesia, i figliuoli di Hatifa.
Nesia àti Hatifa.
55 De' figliuoli de' servi di Salomone: i figliuoli di Sotai, i figliuoli di Soferet, i figliuoli di Peruda, i figliuoli di Iaala,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 i figliuoli di Darcon, i figliuoli di Ghiddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 i figliuoli di Sefatia, i figliuoli di Hattil, i figliuoli di Pocheret-hassebaim, i figliuoli di Ami.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 Tutti i Netinei, e i figliuoli de' servi di Salomone[furono] trecennovantadue.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Or costoro vennero di Telmela, [e di] Telharsa, [cioè: ] Cherub, Addan, [ed] Immer, e non poterono dimostrar la casa loro paterna, nè la lor progenie, se [erano] d'Israele;
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 [come anche] i figliuoli di Delaia, i figliuoli di Tobia, i figliuoli di Necoda, [in numero di] seicencinquantadue.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 E de' figliuoli de' sacerdoti, i figliuoli di Abaia, i figliuoli di Cos, i figliuoli di Barzillai, il quale prese per moglie una delle figliuole di Barzillai Galaadita, e fu nominato del nome loro.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Costoro cercarono i lor nomi fra i rassegnati nelle genealogie; ma non furono trovati; laonde furono appartati dal sacerdozio, come persone non consacrate.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Ed Hattirsata disse loro che non mangiassero delle cose santissime, finchè si presentasse un sacerdote con Urim e Tummim.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Questa raunanza, tutta insieme, [era di] quarantaduemila trecensessanta;
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 oltre a' lor servi e serve, [in numero di] settemila trecentrentasette, fra i quali [v'erano] dugento cantori e cantatrici.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 I lor cavalli [erano] settecentrentasei, i lor muli dugenquarantacinque,
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 i lor cammelli quattrocentrentacinque, gli asini seimila settecenventi.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Ed [alcuni] d'infra i capi delle [famiglie] paterne, quando furono giunti alla Casa del Signore, che [è] in Gerusalemme, fecero una offerta volontaria per la Casa di Dio, per rimetterla in piè.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 [E] diedero nel tesoro della fabbrica, secondo il lor potere, sessantunmila dramme d'oro, e cinquemila mine d'argento, e cento robe da sacerdoti.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 E i sacerdoti e i Leviti, e que' del popolo, e i cantori, e i portinai, e i Netinei, abitarono nelle lor città; tutto Israele eziandio [abitò] nelle sue città.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.