< Proverbi 21 >
1 Il cuore del re è un canale d'acqua in mano al Signore: lo dirige dovunque egli vuole.
Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
2 Agli occhi dell'uomo tutte le sue vie sono rette, ma chi pesa i cuori è il Signore.
Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀, ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.
3 Praticare la giustizia e l'equità per il Signore vale più di un sacrificio.
Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.
4 Occhi alteri e cuore superbo, lucerna degli empi, è il peccato.
Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
5 I piani dell'uomo diligente si risolvono in profitto, ma chi è precipitoso va verso l'indigenza.
Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
6 Accumular tesori a forza di menzogne è vanità effimera di chi cerca la morte.
Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
7 La violenza degli empi li travolge, perché rifiutano di praticare la giustizia.
Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
8 La via dell'uomo criminale è tortuosa, ma l'innocente è retto nel suo agire.
Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
9 E' meglio abitare su un angolo del tetto che avere una moglie litigiosa e casa in comune.
Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
10 L'anima del malvagio desidera far il male e ai suoi occhi il prossimo non trova pietà.
Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Quando il beffardo vien punito, l'inesperto diventa saggio e quando il saggio viene istruito, accresce il sapere.
Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
12 Il Giusto osserva la casa dell'empio e precipita gli empi nella sventura.
Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
13 Chi chiude l'orecchio al grido del povero invocherà a sua volta e non otterrà risposta.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
14 Un regalo fatto in segreto calma la collera, un dono di sotto mano placa il furore violento.
Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle.
15 E' una gioia per il giusto che sia fatta giustizia, mentre è un terrore per i malfattori.
Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
16 L'uomo che si scosta dalla via della saggezza, riposerà nell'assemblea delle ombre dei morti.
Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
17 Diventerà indigente chi ama i piaceri e chi ama vino e profumi non arricchirà.
Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà: ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
18 Il malvagio serve da riscatto per il giusto e il perfido per gli uomini retti.
Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo, àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
19 Meglio abitare in un deserto che con una moglie litigiosa e irritabile.
Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
20 Tesori preziosi e profumi sono nella dimora del saggio, ma lo stolto dilapida tutto.
Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n; ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
21 Chi segue la giustizia e la misericordia troverà vita e gloria.
Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè, òdodo, àti ọlá.
22 Il saggio assale una città di guerrieri e abbatte la fortezza in cui essa confidava.
Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára, ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
23 Chi custodisce la bocca e la lingua preserva se stesso dai dispiaceri.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́, ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
24 Il superbo arrogante si chiama beffardo, egli agisce nell'eccesso dell'insolenza.
Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀, àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
25 I desideri del pigro lo portano alla morte, perché le sue mani rifiutano di lavorare.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé; nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26 Tutta la vita l'empio indulge alla cupidigia, mentre il giusto dona senza risparmiare.
Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́: ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
27 Il sacrificio degli empi è un abominio, tanto più se offerto con cattiva intenzione.
Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni: mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
28 Il falso testimone perirà, ma l'uomo che ascolta potrà parlare sempre.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé: ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
29 L'empio assume un'aria sfrontata, l'uomo retto controlla la propria condotta.
Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le: ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
30 Non c'è sapienza, non c'è prudenza, non c'è consiglio di fronte al Signore.
Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye, tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.
31 Il cavallo è pronto per il giorno della battaglia, ma al Signore appartiene la vittoria.
A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun: ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.