< Ulangan 27 >

1 Kemudian bersama para pemimpin Israel, Musa menyampaikan pesan ini kepada bangsa itu, "Taatilah segala perintah yang saya berikan kepadamu hari ini.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Pa gbogbo àṣẹ tí mo fún ọ lónìí mọ́.
2 Pada hari kamu menyeberangi Sungai Yordan untuk masuk ke negeri yang diberikan TUHAN Allahmu kepadamu, kamu harus menegakkan beberapa batu besar lalu mengapurnya.
Nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani sí inú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, gbé kalẹ̀ lára àwọn òkúta ńlá àti aṣọ ìlekè rẹ pẹ̀lú ẹfun.
3 Tuliskanlah pada batu-batu itu setiap perkataan dari hukum-hukum ini. Apabila kamu sudah masuk ke negeri yang kaya dan subur yang dijanjikan TUHAN, Allah nenek moyangmu kepadamu,
Kí ìwọ kí ó kọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí sára wọn nígbà tí ìwọ bá ti ń rékọjá láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti ṣèlérí fún ọ.
4 dan kamu sudah ada di seberang Sungai Yordan, kamu harus pergi ke Gunung Ebal. Di situ kamu harus menegakkan dan mengapur batu-batu itu seperti yang saya perintahkan kepadamu hari ini.
Àti nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani, kí o gbé òkúta yìí kalẹ̀ sórí i Ebali, bí mo ti pa à láṣẹ fún ọ lónìí, kí o sì wọ̀ wọ́n pẹ̀lú ẹfun.
5 Di tempat itu harus juga kamu dirikan bagi TUHAN Allahmu sebuah mezbah dari batu-batu yang belum pernah dikerjakan dengan alat-alat besi,
Kọ́ pẹpẹ síbẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, pẹpẹ òkúta. Má ṣe lo ohun èlò irin lórí wọn.
6 sebab setiap mezbah yang didirikan untuk TUHAN Allahmu harus dibuat dari batu yang utuh. Di atas mezbah itu kamu harus mempersembahkan kurban-kurban bakaran.
Kí ìwọ kí ó mọ pẹpẹ pẹ̀lú òkúta àìgbẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí ìwọ kí ó sì máa rú ẹbọ sísun ni orí rẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.
7 Persembahkanlah juga kurban perdamaianmu dan makanlah di situ serta bersukacitalah di hadapan TUHAN Allahmu.
Rú ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀ kí o jẹ wọ́n, kí o sì yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
8 Di atas batu-batu yang dikapur itu harus kamu tulis dengan jelas setiap perkataan dari hukum-hukum Allah."
Kí o sì kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí ketekete sórí òkúta tí ó ti gbé kalẹ̀.”
9 Kemudian bersama para imam Lewi, Musa berkata kepada seluruh bangsa Israel, "Saudara-saudara, perhatikanlah dan dengarlah! Hari ini kamu sudah menjadi umat TUHAN Allahmu.
Nígbà náà ni Mose àti àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, sọ fún Israẹli pé, “Ẹ dákẹ́ ẹ̀yin Israẹli, kí ẹ sì fetísílẹ̀! O ti wá di ènìyàn Olúwa Ọlọ́run rẹ báyìí.
10 Sebab itu taatilah TUHAN Allahmu dan lakukanlah semua perintah-Nya yang saya berikan kepadamu hari ini."
Gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì tẹ̀lé àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mo ń fi fún ọ lónìí.”
11 Lalu Musa berkata kepada bangsa Israel,
Ní ọjọ́ kan náà Mose pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé.
12 "Sesudah kamu menyeberangi Sungai Yordan, suku Simeon, Lewi, Yehuda, Isakhar, Yusuf dan Benyamin harus berdiri di atas Gunung Gerizim pada waktu diucapkan berkat atas bangsa ini.
Nígbà tí ìwọ bá ti kọjá a Jordani, àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Gerisimu láti súre fún àwọn ènìyàn: Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Josẹfu àti Benjamini.
13 Pada waktu diucapkan kutuk, suku Ruben, Gad, Asyer, Zebulon, Dan serta Naftali harus berdiri di atas Gunung Ebal.
Àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Ebali láti gé ègún: Reubeni, Gadi, àti Aṣeri, àti Sebuluni, Dani, àti Naftali.
14 Orang-orang Lewi harus mengucapkan kata-kata berikut ini dengan suara nyaring dan orang Israel harus menjawab, 'Amin'.
Àwọn ẹ̀yà Lefi yóò ké sí gbogbo ènìyàn Israẹli ní ohùn òkè:
15 Orang-orang Lewi: 'Terkutuklah orang yang membuat patung dari batu, kayu atau logam, dan menyembahnya dengan sembunyi-sembunyi; TUHAN membenci pemujaan berhala!' Seluruh rakyat: 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó fín ère tàbí gbẹ́ òrìṣà ohun tí ó jẹ́ ìríra níwájú Olúwa, iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà tí ó gbé kalẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
16 'Terkutuklah orang yang tidak menghormati orang tuanya dan membiarkan mereka terlantar.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dójútì baba tàbí ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
17 'Terkutuklah orang yang menggeser batas tanah tetangganya.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí òkúta ààlà aládùúgbò o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
18 'Terkutuklah orang yang menyesatkan orang buta.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣi afọ́jú lọ́nà ní ojú ọ̀nà.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
19 'Terkutuklah orang yang merampas hak orang asing, anak yatim piatu dan janda.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí ìdájọ́ po fún àlejò, aláìní baba tàbí opó.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
20 'Terkutuklah orang yang menghina ayahnya karena bersetubuh dengan salah seorang istri ayahnya.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó baba rẹ̀, nítorí ó ti dójúti ibùsùn baba rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
21 'Terkutuklah orang yang bersetubuh dengan binatang.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹranko.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
22 'Terkutuklah orang yang bersetubuh dengan saudaranya perempuan yang sekandung, atau saudaranya seayah atau seibu.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú arábìnrin rẹ̀, ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
23 'Terkutuklah orang yang bersetubuh dengan ibu mertuanya.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyá ìyàwó o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
24 'Terkutuklah orang yang melakukan pembunuhan dengan sembunyi-sembunyi.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
25 'Terkutuklah orang yang menerima suap untuk membunuh orang yang tidak bersalah.' 'Amin!'
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti pa ènìyàn láìjẹ̀bi.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
26 'Terkutuklah orang yang tidak menepati hukum dan ajaran Allah dengan perbuatan.' 'Amin!'"
“Ègún ni fún ọkùnrin náà tí kò gbé ọ̀rọ̀ òfin yìí ró nípa ṣíṣe wọ́n.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”

< Ulangan 27 >