< Dagiti Salmo 2 >
1 Apay nga agrebelde dagiti nasion, ken agtutulag dagiti tattao iti awan serserbina?
Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
2 Agkaykaysa nga agsagana dagiti ari iti daga ken agkaykaysa dagiti mangiturturay nga agtutulag a maibusor kenni Yahweh ken iti Mesiasna, a kunada,
Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
3 “Pugsatentayo dagiti posas nga inkabilda kadatayo ken ibellengtayo dagiti kawarda.”
Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
4 Isuna a nakatugaw kadagiti langit, uyawennanto ida; lalaisen ti Apo ida.
Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
5 Ket agsao isuna kadakuada iti ungetna ken butbutngenna ida iti pungtotna, a kunana,
Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
6 Siak a mismo ti nangpulot iti arik idiay Sion, ti nasantoan a bantayko.”
“Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
7 Ipakaammokto ti bilin ni Yahweh. Kinunana kaniak, “Sika ti anakko! Ita nga aldaw, nagbalinak nga amam.
Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
8 Agkiddawka kaniak, ket itedko kenka dagiti nasion a tawidmo ken dagiti kaadaywan a rehion iti daga a sanikuam.
Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
9 Burakemto ida babaen iti setro a landok; rumekemto ida a kasla banga ti agdamdamili.”
Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
10 Isu nga ita, dakayo nga ari, maballaagankayo; masuroankayo, dakayo a mangiturturay iti daga.
Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
11 Dayawenyo ni Yahweh nga addaan panagbuteng ken agrag-okayo nga addaan panagpigerger.
Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
12 Agkanyo ti anak amangan no makaungetto isuna kadakayo, ket mataykayo iti dalan inton dagus a sumged ti ungetna. Anian a nagasat dagiti amin nga agkamang kenkuana.
Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.