< Nahum 2 >

1 Umayen ti tao a mangrebbek kenka. Bantayam dagiti pader ti siudad, guardiaam dagiti dalan, papigsaem ta bagim, ummongem dagiti armadam.
Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
2 Ta isubsubli ni Yahweh ti kinatan-ok ni Jacob, kas iti kinatan-ok ti Israel, uray dinadael ida dagiti mangsamsamsam ken dinadaelda dagiti sanga ti ubasda.
Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
3 Nalabbaga dagiti kalasag dagiti maingel a tattaona, ken nakakawes iti nalabbaga dagiti natutured a lallaki; agraniag dagiti landok ti karwahe iti aldaw a panagsaganada, ken naiwaradiwad iti tangatang dagiti sipres a gayang.
Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
4 Napegges ti panagtaray dagiti karwahe kadagiti kalsada; agdardarasda nga agsubli-subli kadagiti nalawa a kalkalsada. Kasdala dagiti pagsilawan ken agtatarayda a kasla kimat.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
5 Ay-ayaban ti tao a mangrebbek kenka dagiti opisyalna; maitublakda iti tunggal maysa iti pannagnada; agdardarasda a mangraut iti pader ti siudad. Naisaganan ti dakkel a kalasag a mangsalaknib kadagitoy a mangraraut.
Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
6 Napilit a nailukat dagiti ruangan kadagiti karayan, ket nadadael ti palasio.
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
7 Naussoban ti pagan-anay ti reyna ken naitalaw; agas-asug dagiti adipenna a babbai a kasla dagiti kalapati, dandanugenda dagiti barukongda.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
8 Ti Ninive ket kasla naisawang a danum, a kasla napegges a danum nga agliblibas dagiti tattaona. Ipukpukkaw dagiti dadduma, “Agsardengkayo, agsardengkayo,” ngem awan ti tumalyaw.
Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
9 Alaenyo ti nasamsam a pirak, alaenyo ti nasamsam a balitok, gapu ta awan patingga daytoy, ti dayag dagiti amin a napipintas a banbanag ti Nineve.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Langalang ken nadadael ti Nineve. Marunaw ti puso iti tunggal maysa, agtitim-og dagiti tumtumeng ti tunggal maysa, ken adda ladingit iti tunggal maysa; pimmusyaw amin dagiti rupada.
Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
11 Sadino ngay itan ti rukib ti leon, ti lugar a pangpanganan dagiti urbon a leon, ti lugar a pagpagnaan ti leon ken ti kabaian a leon, agraman dagiti urbon a leon, no sadino ket awan ti pagbutbutnganda?
Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
12 Rinangrangkay ti leon ti natiliwna para kadagiti annakna; Binekkelna dagiti natiliwna a maipaay iti kabaian a leon, ken pinunnona ti rukibna kadagiti natiliwna, ken ti rukibna kadagiti narangrangkay a natay a bagi ti ayup.
Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
13 “Kitaem, bimmusorak kenka”—kastoy ti pakaammo ni Yahweh a Mannakabalin-amin. “Uramekto dagiti karwahem iti asuk, ken alun-onento ti kampilan dagiti urbon a leonmo. Pukawekto ti sinamsammo manipud iti dagam, ken saanton a mangngegan pay dagiti timek dagiti mensaherom.”
“Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

< Nahum 2 >