< Ezekiel 34 >

1 Kalpasanna, dimteng kaniak ti sao ni Yahweh ket kinunana,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ mi wá:
2 “Anak ti tao, agipadtoka a maibusor kadagiti agpaspastor iti Israel! Agipadtoka ket ibagam kadakuada, 'Kastoy ti ibagbaga ti Apo a ni Yahweh kadagiti agpaspastor: Asi pay dagiti agpaspastor iti Israel a mangipaspastor kadagiti bagbagida! Saan kadi a rumbeng a bantayan dagiti agpaspastor ti arban?
“Ọmọ ènìyàn, fi àsọtẹ́lẹ̀ tako Olùṣọ́-àgùntàn Israẹli; sọtẹ́lẹ̀ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn Israẹli tí ó ń tọ́jú ara wọn nìkan! Ṣé ó dára kí olùṣọ́-àgùntàn ṣaláì tọ́jú agbo ẹran?
3 Kankanenyo dagiti nalulukmeg a paset ken agkawkaweskayo iti lupot a naaramid iti buok ti karnero! Parpartienyo dagiti nalulukmeg iti arban! Saankayo a pulos a nagpastor.
Ìwọ jẹ wàrà. O sì wọ aṣọ olówùú sí ara rẹ, o sì ń pa ẹran tí ó wù ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò tọ́jú agbo ẹran.
4 Saanyo a pinapigsa dagiti addaan kadagiti sagubanit, wenno saanyo nga inagasan dagiti masakit. Saanyo a bedbedbedan dagiti nablo, ken saanyo a pinasubli dagiti napapanaw wenno sinapul dagiti napukaw. Ngem ketdi, inturayanyo ida babaen iti bileg ken kinaranggas.
Ìwọ kò ì tí ì mú aláìlágbára lára le tàbí wo aláìsàn sàn tàbí di ọgbẹ́ fún ẹni tí o fi ara pa. Ìwọ kò í tí ì mú aṣáko padà tàbí wá ẹni tí ó nù. Ìwọ ṣe àkóso wọn ní ọ̀nà lílé pẹ̀lú ìwà òǹrorò.
5 Ket nawarawarada nga awan ti mangipastor kadakuada, ket nagbalinda a taraon para kadagiti amin a nabiag a narungsot nga ayup kadagiti away, kalpasan a nawarawarada.
Nítorí náà wọn fọ́n káàkiri nítorí àìsí olùṣọ́-àgùntàn, nígbà tí wọ́n fọ́nká tán wọn di ìjẹ fún gbogbo ẹranko búburú.
6 Naiyaw-awan ti arbanko kadagiti amin a banbantay ken iti tunggal nangangato a turod, ket naiwarawarada iti entero a rabaw ti daga. Ket awan a pulos ti mangbirbirok kadakuada.
Àgùntàn mi n rin ìrìn àrè kiri ní gbogbo àwọn òkè gíga àti òkè kékeré. A fọ́n wọn ká gbogbo orí ilẹ̀ ẹni kankan kò sì wá wọn.
7 Isu a dakayo nga agpaspastor, denggenyo ti pakaammo ni Yahweh:
“‘Nítorí náà, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
8 Iti naganko nga adda iti agnanayon—kastoy ti pakaammo ti Apo a ni Yahweh—gapu ta nagbalin a samsam ti arbanko ken nagbalin a taraon para kadagiti amin a narungsot nga ayup kadagiti away (gapu ta awan ti pastor ken awan kadagiti pastorko ti nangbiruk iti arbanko, ngem binantayan dagiti agpaspastor dagiti bagbagida ket saanda nga impastoran ti arbanko)—
Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ní Olúwa Olódùmarè wí, nítorí pé agbo ẹran mi kò ní olùṣọ́-àgùntàn nítorí tí a kọ̀ wọ́n, tì wọ́n sì di ìjẹ fún ẹranko búburú gbogbo àti pé, nítorí tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn mi kò ṣe àwárí agbo ẹran mi, ṣùgbọ́n wọn ń ṣe ìtọ́jú ara wọn dípò ìtọ́jú agbo ẹran mi,
9 Ngarud, dakayo nga agpaspastor, denggenyo ti pakaammo ni Yahweh:
nítorí náà, ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
10 Kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Kitaem! Maibusorak kadagiti agpaspastor, ket sapulekto manipud kadagiti imada ti arbanko. Ket pasardengekto ida a mangipastor iti arban; wenno saanton nga ipastoran dagiti pastor dagiti bagbagida ta alaekto ti arbanko manipud kadagiti ngiwatda, tapno saanton nga agbalin a taraon ti arbanko para kadakuada.
Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìlòdì sí àwọn Olùṣọ́-àgùntàn, èmi yóò sì béèrè agbo ẹran mi lọ́wọ́ wọn. Èmi yóò sì mú wọn dẹ́kun àti máa darí agbo ẹran mi, tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà kò sì ní lè bọ́ ara wọn mọ́. Èmi yóò gba agbo ẹran mi kúrò ni ẹnu wọn, kì yóò sì jẹ́ oúnjẹ fún wọn mọ́.
11 Ta kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Kitaem! Siakto a mismo ti mangsapul iti arbanko ket aywanakto dagitoy,
“‘Nítorí èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi fúnra mi yóò wá àgùntàn mi kiri, èmi yóò sì ṣe àwárí wọn.
12 kas iti panangsapul ti agpaspastor iti arbanna iti aldaw nga adda isuna iti tengnga ti nawarawara nga arbanna. Kastanto ti panangbirokko iti arbanko, ken ispalekto ida manipud kadagiti amin a lugar a nakaiwaraanda iti aldaw a naulep ken nasipnget.
Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe fojú tó agbo ẹran rẹ̀ tí ó fọ́nká nígbà tí ó wà pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe fojú tó àgùntàn mi. Èmi yóò gbá wọn kúrò ni gbogbo ibi tí wọ́n fọ́nká sí ni ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn.
13 Ket irruarkonto ida manipud kadagiti tattao; urnongekto ida manipud kadagiti daga ket iyegkonto ida iti dagayo. Ikabilkonto ida kadagiti pagpasturan kadagiti sikigan dagiti bantay iti Israel, iti abay dagiti karayan, ken iti tunggal pagnaedan iti daga.
Èmi yóò mú wọn jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì kó wọn jọ láti inú àwọn ìlú, èmi yóò sì mú wọn wá sí ilẹ̀ ara wọn. Èmi yóò mú wọn jẹ ni orí àwọn òkè gíga Israẹli, ni àárín àwọn òkè àti ní gbogbo ibùdó ilẹ̀ náà.
14 Ikabilkonto ida iti nasayaat a pagpasturan; dagitinto nangangato a bantay ti Israel dagiti lugar a pagarabanda. Agiddadanto kadagiti nasasayaat a lugar a pagaraban, iti nawadwad a pagpasturan, ken agarabdanto kadagiti bantay ti Israel.
Èmi yóò ṣe ìtọ́jú wọn ní pápá oko tútù dáradára, àní orí àwọn òkè gíga ti Israẹli ni yóò jẹ́ ilẹ̀ ìjẹ koríko wọ́n. Níbẹ̀ wọn yóò dùbúlẹ̀ ní ilẹ̀ ìjẹ koríko dídára, níbẹ̀ wọn yóò jẹun ní pápá oko tútù tí ó dara ní orí òkè ti Israẹli.
15 Siakto a mismo ti mangipastor iti arbanko, ken siakto a mismo ti mangpaidda kadakuada—kastoy ti pakaammo ti Apo a ni Yahweh—
Èmi fúnra mi yóò darí àgùntàn mi, èmi yóò mú wọn dùbúlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 birukekto ti napukaw ken isublikto ti napagtalaw; bedbedakto ti nablo a karnero ken agasakto ti masakit a karnero. Ket pukawekto dagiti napalukmeg ken napigsa! Agpastorakto a nainkalintegan!
Èmi yóò ṣe àwárí àwọn tí ó nú, èmi yóò mú àwọn tí ó ń rin ìrìn àrè kiri padà. Èmi yóò di ọgbẹ́ àwọn tí ó fi ara pa, èmi yóò sì fún àwọn aláìlágbára ni okun, ṣùgbọ́n àwọn tí ó sanra tí ó sì ni agbára ní èmi yóò parun. Èmi yóò ṣe olùṣọ́ àwọn agbo ẹran náà pẹ̀lú òdodo.
17 Ket sika nga arbanko—kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh— kitaem! Siakto ti agbalin nga ukom kadagiti karnero, kadagiti kalakian a karnero ken kadagiti kalding!
“‘Ní tìrẹ, agbo ẹran mi, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn, àti láàrín àgbò àti ewúrẹ́.
18 Bassit kadi a banag a maipastorkayo iti nasayaat a pagpasturan, isu a tarigagayanyo a baddekan ti natda iti pagpasturan? Wenno bassit kadi a banag nga imminumkayo kadagiti nalitnaw a danum, a rumbeng a libegenyo dagiti karayan babaen kadagiti sakayo?
Ṣé oúnjẹ jíjẹ ní pápá oko tútù dídára kò tó yín! Ṣé ó jẹ́ dandan fún ọ láti fi ẹsẹ̀ tẹ pápá oko tútù rẹ tí ó kù? Ṣé omi tí ó tòrò kò tó fún yín ní mímu? Ṣe dandan ni kí ó fi ẹrẹ̀ yí ẹsẹ̀ yín?
19 Ngem ti karnerok ket maipaspastoren iti binaddebaddekan dagiti sakayo; in-inumendan dagiti danum a linibegyo babaen kadagiti sakayo!
Ṣé dandan ni kí agbo ẹran mi jẹ́ koríko tí ẹ ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, kí wọn sì mú omi tí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ wọn sọ di ẹrẹ̀?
20 Kastoy ngarud ti kuna ti Apo a ni Yahweh kadakuada: Kitaem! Siakto a mismo ti mangukom kadagiti nalukmeg ken kadagiti nakuttong a karnero,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún wọn: Wò ó, èmi fúnra mi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn tí ó sanra àti èyí tí ó rù.
21 ta induronyo ida babaen kadagiti bakrang ken abagayo, ken sinangduyo dagiti amin nga agkakapuy agingga nga inwarayo ida iti adayu manipud iti daga!
Nítorí ti ìwọ sún síwájú pẹ̀lú ìhà àti èjìká, tí ìwọ sì kan aláìlágbára àgùntàn pẹ̀lú ìwo rẹ títí ìwọ fi lé wọn lọ,
22 Isu nga isalakankonto ti arbanko; saandanton a pulos nga agbalin a samsam. Ket ukomekto dagiti karnero!
Èmi yóò gba agbo ẹran mi là, a kì yóò sì kò wọ́n tì mọ́. Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn.
23 Mangisaadakto iti maysa nga agpastor kadakuada, ket ipastornanto ida—ti adipenko a ni David! Ipastornanto ida; agbalinto isuna a pastorda!
Èmi yóò fi Olùṣọ́-àgùntàn kan ṣe olórí wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi, òun yóò sì tọ́jú wọn; òun yóò bọ́ wọn yóò sì jẹ́ Olùṣọ́-àgùntàn wọn.
24 Ta siak, a ni Yahweh, ti agbalinto a Diosda, ket ti adipenko a ni David ti agbalinto a panguloda—siak, a ni Yahweh ti nangipakaammo iti daytoy!
Èmi Olúwa yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi yóò jẹ́ ọmọ-aládé láàrín wọn. Èmi Olúwa ní o sọ̀rọ̀.
25 Ket mangaramidakto iti katulagan a pakikapia kadakuada ken ikkatekto dagiti dakes nga atap nga ayup manipud iti daga, isu nga agbiagto a sitatalged dagiti karnerok iti let-ang ken maturogdanto kadagiti kabakiran.
“‘Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, èmi yóò sì gba ilẹ̀ náà kúrò lọ́wọ́ ẹranko búburú, kí wọn kí o lè gbé ní aṣálẹ̀, kí àgùntàn sì gbé ní inú igbó ní àìléwu.
26 Bendisionakto pay ida ken dagiti naglikmut a turodko, ta mangiyegakto iti arbis iti naikeddeng a tiempo. Dagitoyto ket arbis iti bendision!
Èmi yóò bùkún wọn àti ibi agbègbè ti ó yí òkè mi ká. Èmi yóò rán ọ̀wààrà òjò ni àkókò; òjò ìbùkún yóò sì wà.
27 Ket agbunganto dagiti kayo iti talon, ken mangipaayto ti daga iti bunga. Natalgedto dagiti karnerok iti dagada; ket maammoandanto a siak ni Yahweh, inton tukkolek dagiti balunet ti sangolda, ken inton ispalek ida manipud iti ima dagiti nangtagabu kadakuada.
Àwọn igi igbó yóò mú èso wọn jáde, ilẹ̀ yóò sì mu irúgbìn jáde; A yóò sì dá ààbò bo àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ náà. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá já àwọn ohun tí ó ṣe okùnfà àjàgà, tí mo sì gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó fi wọ́n ṣe ẹrú.
28 Saandanton a pulos nga agbalin a samsam kadagiti nasion, ket saanto ida a pulos a kanen dagiti atap nga ayup! Ta agbiagdanto a sitatalged ket saandanto nga agbuteng.
Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò lè kó wọn ní ẹrú mọ́, àwọn ẹranko búburú kì yóò lè pa wọn mọ́. Wọn yóò gbé ni àìléwu, kò sì ṣí ẹni kankan tí yóò le dẹ́rùbà wọ́n.
29 Ta mangaramidakto iti natalna a lugar a pagmulaan para kadakuada tapno saandanton a pulos a matay iti bisin iti daga, ket saanto ida a laisen dagiti nasion.
Èmi yóò pèsè ilẹ̀ ti o ní oríyìn fún èso rẹ̀ fún wọn, wọn kì yóò sì jìyà nípasẹ̀ ìyàn mọ́ ni ilẹ̀ náà tàbí ru ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè.
30 Ket maammoandanto a siak, a ni Yahweh a Diosda ket addaak kadakuada. Isuda dagiti tattaok, ti balay ti Israel— kastoy ti pakaammo ti Apo a ni Yahweh.
Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi wà pẹ̀lú wọn àti pé, àwọn ilé Israẹli jẹ́ ènìyàn mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
31 Ta dakayo dagiti karnerok, ti arban iti pagpasturak, ken dagiti tattaok! Siakto ti Diosyo— kastoy ti pakaammo ti Apo a ni Yahweh.'”
Ìwọ àgùntàn mi, àgùntàn pápá mi; ni ènìyàn, èmi sì ni Ọlọ́run rẹ; ni Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ezekiel 34 >