< Ezekiel 24 >

1 Iti maikasiam a tawen, iti maikasangapulo nga aldaw iti maikasangapulo a bulan, immay manen kaniak ti sao ni Yahweh a kunana,
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Anak ti tao, isuratmo ti petsa ita nga aldaw, daytoy a mismo nga aldaw; ta iti daytoy a mismo nga aldaw, linakuben ti ari ti Babilonia ti Jerusalem.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 Ket ibagam daytoy a proberbio maibusor iti daytoy a nasukir a balay, maysa a pangngarig, ket ibagam kadakuada, ‘Kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Isaangmo ti kaldero a paglutoan! Isaangmo daytoy! Ken kasta met a kargaam daytoy iti danum!
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Ipisukmo ditoy dagiti karne, amin dagiti kasayaatan—ti luppo ken abaga; punoem daytoy kadagiti kasayaatan a tulang!
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Alaem ti kasayaatan iti arban ken ikabilmo dagiti dadduma a tulang iti siruk ti kaldero; pagburekem a nalaing, ken angerem met a nalaing dagiti tulang.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 Isu a kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Asi pay ti siudad ti dara, kasla la kaldero a paglutoan a naglati ken saanto a maikkat dayta a lati iti daytoy! Saggaysaem nga adawen dagiti naikabil ditoy, ngem saanmo a pilien dagiti adawem manipud iti ditoy.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 Ta ti darana ket adda iti katengngaanna! Inkabilna daytoy iti nalammuyot a bato; saanna nga imbuyat daytoy iti daga tapno magaburan daytoy iti tapuk,
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 isu a mangyeg daytoy iti nakaro a pungtot a pakaigapuan ti panangibales! Inkabilko ti darana iti nalammuyot a bato tapno saan daytoy a magaburan!
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 Isu a kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Asi pay ti siudad ti dara! Ilawlawakto pay ti gabsuon ti kayo!
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Sungrodak pay iti adu a kayo! Sindiak ti apuy! Angerek a nalaing ti karne ken rikadoak ti sabaw! Ket bay-ak a makset a nalaing dagiti tulang!
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Kalpasanna, isaangmo ti kaldero a paglutoan nga awan nagianna, tapno pumudot ken agbeggang ti bronsena, tapno ti rugitna ket marunawto, ken mapuoran ti lati daytoy!’
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Kasta unay ti bannogna gapu iti nadagsen unay a trabaho, ngem saan latta a naikkat kenkuana ti latina babaen iti apuy.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 Ti nakababain a kababalinmo ket adda iti kinarugitmo, gapu ta pinadaska a dinalusan, ngem saanka latta a nadalusan. Saanto latta a maikkat ti kinarugitmo agingga nga agbaaw ti nakaro a pungtotko kenka.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 Siak a ni Yahweh, impakaammok a mapasamakto daytoy, ket ipatungpalkonto daytoy! Saanakto a mangaasi wenno agbabawi a mangaramid iti daytoy. Aniaman dagiti wagasyo ken dagiti aramidyo, makedngankayonto babaen kadagitoy! —kastoy ti pakaammo ti Apo a ni Yahweh.”
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Kalpasanna, immay kaniak ti sao ni Yahweh a kunana,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 “Anak ti tao, dumngegka! Kellaatek nga alaen ti tarigagay dagiti matam babaen iti angol, ngem masapul a saanka nga agliday wenno agsangit, ken masapul a saan nga agarubos dagiti luam.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Masapul nga agasugka a siuulimek. Saanmo nga ipakita nga agladladingitka para iti natay. Igalutmo dayta turbantem ken isuotmo ti sandaliasmo, ngem saanmo nga abbongan ti rupam wenno saanmo a kanen ti tinapay dagiti lallaki nga agladladingit gapu ta napukawda dagiti assawada.”
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Isu a kabigatanna, kinasaritak dagiti tattao, ket iti karabianna natay ti asawak. Ket kabigatanna, inaramidko ti naibilin kaniak.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 Sinaludsod kaniak dagiti tattao, “Saanmo kadi nga ibaga kadakami no ania ti kaipapanan dagitoy a banbanag, dagiti banbanag nga ar-aramidem?”
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Isu a kinunak kadakuada, “Immay kaniak ti sao ni Yahweh a kunana,
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 ‘Ibagam iti balay ti Israel a kastoy ti kuna ti Apo a ni Yahweh: Dumngegkayo! Ti panangipanpannakkelyo iti kinapigsayo, ti tarigagay dagiti matayo, ken ti kinagartemyo ket tultulawanna ti santuariok! Isu a dagiti annakyo a lallaki ken babbai nga imbatiyo ket mapasagto babaen iti kampilan.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 Isu nga aramidenyonto met nga apag-isu ti kas iti inaramidko: saanyonto nga abbongan dagiti rupayo, wenno saanyonto a kanen ti tinapay dagiti agladladingit a lallaki!
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 Ngem ketdi, ikabilyonto dagiti turbante kadagiti uloyo, ken nakasandaliaskayonto; saankayonto nga agladingit wenno agsangit, ta mapukawkayonto gapu kadagiti nakaro a kinadakesyo, ket agasugto ti tunggal tao gapu iti kabsatna.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Isu a ni Ezekiel ti agserbinto a ballaag kadakayo, aramidenyonto met ti kas iti amin nga inaramidna inton dumteng daytoy. Ket maammoanyonto a Siak ti Apo a ni Yahweh!”’
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 Ngem sika anak ti tao, iti aldaw nga ikkatek ti temploda, nga isu a ragsakda, nga itangtangsitda, nga kitkitaenda ken tartarigagayenda—ket inton ipanawko dagiti annakda a lallaki ken babbai—
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 iti dayta nga aldaw, addanto makalibas nga umay kenka tapno ibagana kenka ti damag!
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 Iti dayta nga aldaw, maungapto ti ngiwatmo iti dayta a nakalibas ket agsaokanto—saankanton a naulimek. Agserbikanto a ballaag kadakuada, isu a maammoandanto a Siak ni Yahweh!”
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

< Ezekiel 24 >