< Exodo 1 >

1 Dagitoy dagiti nagan dagiti annak ti Israel a kimmuyog kenni Jacob a napan idiay Egipto, kadua ti tunggal maysa ti sangkabalayanna:
Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
2 Ruben, Simeon, Levi ken Juda,
Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
3 Isacar, Zabulon ken Benjamin,
Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
4 Dan, Naftali, Gad ken Aser.
Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
5 Pitopulo amin ti bilang dagiti kaputotan ni Jacob. Adda idin ni Jose idiay Egipto.
Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
6 Ket natay ni Jose, dagiti amin a kakabsatna, ken amin dayta a henerasion.
Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7 Nabunga dagiti Israelita, immadu ken pimmigsada iti kasta unay; napunno ti daga kadakuada.
ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8 Ket nagturay ti maysa a baro nga ari iti entero nga Egipto, a saan a mangbigbigbig iti pakasaritaan ni Jose.
Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 Kinunana kadagiti tattaona, “Kitaenyo dagiti Israelita; ad-adu ken napigpigsada ngem datayo.
Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
10 Umaykayo, tratoentayo ida a sisisirib. Ta no saan, ad-adda nga umaduda, ket no adda iti gubat, tumiponndanto kadagiti kabusortayo, a lumaban kadatayo, ket pumanawda iti daga.”
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
11 Isu a nangisaadda kadagiti kapatas a mangparigat kadakuada iti nadagsen a trabaho. Nangipatakder dagiti Israelita iti pagipenpenan a siudad para kenni Faraon: ti Pitom ken Rameses.
Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
12 Ngem kas ad-adda a parparigaten dagiti Egipcio ida, ad-adda met nga umad-adu ken agwar-waras dagiti Israelita. Isu a nangrugi nga agbuteng dagiti Egipcio kadagiti Israelita.
Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
13 Pinagtrabaho dagiti Egipcio dagiti Israelita iti nakaro.
Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
14 Pinagbalinda a nasaem ti panagbiagda babaen iti nadagsen a panagtrabaho iti alketran ken ladrilio, ken iti amin a kita ti trabaho iti talon. Amin a trabaho nga impaaramidda kadakuada ket narigat.
Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
15 Ket nakisarita ti ari iti Egipto kadagiti partera a Hebreo; ti nagan ti maysa ket Zifra ken ti maysa ket Pua.
Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
16 Kinunana, “No tulonganyo dagiti Hebreo a babbai iti paganakan, siputanyo no aganakda. No lalaki ti maladaga, masapul a patayenyo isuna; ngem no babai daytoy, bay-anyo nga agbiag.”
“Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
17 Ngem adda panagbuteng dagiti partera iti Dios ket saanda nga inaramid ti imbilin ti ari iti Egipto kadakuada; ngem ketdi, binay-anda nga agbiag dagiti lallaki a maladaga.
Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
18 Pinaayaban ti ari ti Egipto dagiti partera ket kinunana kadakuada, “Apay a binay-anyo nga agbiag dagiti lallaki a maladaga?”
Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
19 Simmungbat dagiti partera kenni Faraon, “Dagiti babbai a Hebreo ket saan a kasla kadagiti babbai nga Egipcio; napigsada ken nakaanakdan sakbay a sumangpet ti partera kadakuada.”
Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
20 Sinalakniban ti Dios dagitoy a partera. Immadu ti dagiti tattao ken pimmigsada iti kasta unay.
Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
21 Gapu ta managbuteng iti Dios dagiti partera, inikkanna ida iti pamilia.
Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
22 Binilin ni Faraon dagiti amin a tattaona, “Masapul nga ibellengyo iti karayan ti tunggal lalaki a maiyanak, ngem mabalinyo a bay-an nga agbiag ti tunggal babai.”
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”

< Exodo 1 >