< Deuteronomio 26 >

1 Inton makapankayo iti daga nga it-ited ni Yahweh a Diosyo kadakayo a kas maysa a tawid, ken inton tagikuaen ken pagnaedanyo daytoy,
Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
2 ket nasken a mangalakayo kadagiti amin nga umuna nga apit iti daga nga impanyo iti daga nga it-ited ni Yahweh a Diosyo kadakayo. Nasken nga ikabilyo daytoy iti basket ket mapankayo iti lugar a piliento ni Yahweh a Diosyo a kas santuariona.
mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
3 Nasken a mapankayo iti padi nga agserserbi kadagita nga al-aldaw ket ibagayo kenkuana, 'Ipakaammok ita nga aldaw kenni Yahweh a Diosyo nga immayak iti daga nga inkari ni Yahweh kadagiti kapuonantayo nga ited kadatayo.'
Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
4 Nasken nga alaen ti padi ti basket nga adda iti imayo ket idissona daytoy iti sangoanan ti altar ni Yahweh a Diosyo.
Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
5 Nasken nga ibagayo iti sangoanan ni Yahweh a Diosyo, 'Ti kapuonak ket agalla-ala nga Arameo. Simmalog isuna sadiay Egipto ket nagtalinaed isuna sadiay, ket bassit ti bilang dagiti tattaona. Sadiay, nagbalin isuna a nabileg, mannakabalin, ken natao a nasion.
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
6 Trinatodakami a siraranggas ken pinarigatdakami dagiti Egipcio. Pinagtrabahodakami iti trabaho ti tagabu.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
7 Immasugkami kenni Yahweh, iti Dios dagiti ammami, ket nangngegna ti timekmi ken nakitana iti pakarigatanmi, iti trabahomi, ken pannakaidadanesmi.
Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
8 Inruarnakami ni Yahweh sadiay Egipto babaen iti nabileg nga ima, babaen ti panangiparangna iti pannakabalinna, babaen iti nakabutbuteng, babaen kadagiti pagilasinan, ken babaen kadagiti nakaskasdaaw;
Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
9 ket impannakami iti daytoy a lugar ken intedna kadatayo daytoy a daga, daga nga agay-ayos ti gatas ken diro.
Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
10 Ita adtoy, inyegko ti umuna kadagiti apit iti daga nga intedmo Yahweh kaniak.' Nasken nga idissoyo daytoy iti sangoanan ni Yahweh a Diosyo ken agdaydayawkayo iti sangoananna;
àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
11 ken nasken nga agrag-okayo kadagiti amin a nasayaat nga inaramid ni Yahweh a Diosyo kadakayo, para iti pagtaenganyo—sika, ken ti Levita, ken ti ganggannaet nga adda kadakayo.
Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
12 Inton malpasyo nga it-ited dagiti amin nga apagkapullo dagiti apityo iti maikatallo a tawen, dayta ket ti tawen ti panangited iti apagkapullo, ket nasken nga itedyo daytoy iti Levita, kadagiti ganggannaet, kadagiti ulila, ken iti balo a babai, tapno mabalinda ti mangan kadagiti ruangan ti siudadyo ken mabsogda.
Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
13 Nasken nga ibagay iti sangoanan ni Yahweh a Diosyo, 'Inruarko iti pagtaengak dagiti banbanag a kukua ni Yahweh, ket intedko dagitoy iti Levita, iti ganggannaet, kadagiti ulila, ken iti balo a babai, segun kadagiti amin a bilbilin nga intedmo kaniak. Awan ti aniaman a sinalungasingko kadagiti bilinmo, wenno nalipatak kadagitoy.
Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
14 Saanak a nangan iti aniaman iti daytoy iti panagladingitko, wenno inkabil daytoy iti sadinoman idi narugitak, wenno nangtedak iti aniaman iti daytoy a panangraem iti natay. Dimngegak iti timek ni Yahweh a Diosko; nagtulnogak iti amin a banag nga imbilinmo nga aramidek.
Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
15 Tumannawagka manipud iti nasantoan a lugar a pagnanaedam, manipud langit, ken bendisionam dagiti tattao ti Israel, ken ti daga nga intedmo kadakami, a kas insapatam kadagiti ammami, a daga nga aga-ayus ti gatas ken diro.'
Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
16 Ita nga aldaw bilbilinennakayo ni Yahweh a Diosyo nga agtulnogkayo kadagitoy nga alagaden ken paglintegan; salimetmetanyo ngarud dagitoy ken aramidenyo dagitoy iti isu-amin a pusoyo ken iti isu amin a kararuayo.
Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
17 Binigbigyo ita nga aldaw a ni Yahweh ti Diosyo, ken magnakayonto kadagiti dalanna ken salimetmetanyo dagiti alagadenna, dagiti linlintegna, ken dagiti paglintegenna, ken dumgegkayonto iti timekna.
Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
18 Ita nga aldaw, pinaneknekan ni Yahweh a dakayo dagiti tattaona a bukodna a sanikua, a kas iti inkarina nga aramidenna kadakayo, ket masapul a salimetmetanyo dagiti amin a bilbilinna.
Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
19 Ita nga aldaw, impakaammo ni Yahweh nga aramidennakayo a napatpateg ngem dagiti amin a dadduma a nasion nga inaramidna, maidaydayaw ken maitan-okto ti naganna. Agbalinkayonto a tattao a mailasin a para kenni Yahweh a Diosyo, kas iti imbagana.”
Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.

< Deuteronomio 26 >