< Amos 3 >

1 Dakayo a tattao ti Israel, denggenyo daytoy a sao nga imbalikas ni Yahweh maibusor kadakayo, maibusor iti sibubukel a pamilia nga inruarko iti daga ti Egipto,
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 dakayo laeng ti pinilik manipud kadagiti amin a pamilia iti daga. Isu a dusaenkayonto gapu iti amin a nagbasolanyo.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Agkuyog kadi a magna ti dua a tao no saanda a nagtulag?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Agngernger kadi ti leon idiay kabakiran no awan biktimana? Agngernger kadi ti urbon a leon idiay rukibna no awan nakemmegna?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Matiliw kadi ti billit iti palab-og nga adda iti daga no awan iti appan a naikabil para iti daytoy? Agpangato kadi ti silo manipud iti daga no awan nasiloanna?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 No aguni ti trumpeta iti maysa a siudad, saan kadi nga agtigerger dagiti tattao? Umay kadi ti didigra iti maysa a siudad no saan nga inyeg ni Yahweh daytoy?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 Awan duadua a saan nga agtignay ni Yahweh nga Apo no saanna pay nga impakaammo ti panggepna kadagiti adipenna a profeta.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Nagngernger ti leon; siasino ti saan nga agbuteng? Nagsao ni Yahweh nga Apo; siasino ti saan a mangipadto?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Iwaragawagyo daytoy kadagiti sarikedked idiay Asdod, ken kadagiti sarikedked idiay daga ti Egipto; ibagayo: “Aguummongkayo kadagiti banbantay ti Samaria ket kitaenyo ti dakkel a riribok nga adda kenkuana ken ti pannakaidadanes nga adda kenkuana.
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 Gapu ta saanda nga ammo ti agaramid iti nalinteg”—daytoy ti imbaga ni Yahweh—”Agur-urnongda iti kinaranggas ken pannakadadael kadagiti sarikedkedda.”
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Isu a kastoy ti ibagbaga ni Yahweh nga Apo: “Palawlawanto ti kabusor ti daga. Rebbaenanto dagiti sarikedkedmo ken samsamannanto dagiti sarikedkedmo.”
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Kastoy ti kuna ni Yahweh: “Kas iti panangispal ti agpaspastor iti dua laeng a saka wenno maysa a lapayag manipud iti ngiwat iti leon kastanto met iti pannakaispal dagiti Israelita nga agnanaed iti Samaria, ket ti suli laeng iti sofa wenno maysa laeng a pidaso ti ap-ap ti kama ti maisalbarda.”
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Dumngegkayo ken agsaksikayo maibusor iti balay ni Jacob —kastoy ti impakaammo ti Apo a Yahweh, ti Dios a mannakabalin amin.
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 “Ta iti aldaw a dusaek ti basbasol ti Israel, dusaekto met dagiti altar ti Betel. Maputedto dagiti sara ti altar ket matnagto dagitoy iti daga.
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 Dadaelekto ti balay a pagtataenganda iti panawen iti lam-ek ken ti balayda iti kalgaw. Madadaelto dagiti balay a marfil, ken mapukawto dagiti dadakkel a babbalay,” —daytoy ti imbaga ni Yahweh.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< Amos 3 >