< Opinberun Jóhannesar 7 >

1 Eftir þetta sá ég fjóra engla sem stóðu á fjórum skautum jarðarinnar og héldu vindunum fjórum í skefjum, svo að þeir gátu ekki blásið. Lauf trjánna bærðust ekki og hafið varð spegilslétt.
Lẹ́yìn èyí ni mo rí angẹli mẹ́rin dúró ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, wọ́n di afẹ́fẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé mú, kí ó má ṣe fẹ́ sórí ilẹ̀, tàbí sórí Òkun, tàbí sára igikígi.
2 Þá sá ég annan engil, hann kom úr austurátt og hélt á innsigli hins lifandi Guðs. Hann kallaði til englanna fjögurra sem fengið höfðu vald til að granda jörðinni og hafinu, og sagði:
Mo sì rí angẹli mìíràn tí ó ń ti ìhà ìlà-oòrùn gòkè wá, ti òun ti èdìdì Ọlọ́run alààyè lọ́wọ́ rẹ. Ó sì kígbe ní ohùn rara sí àwọn angẹli mẹ́rin náà tí a fi fún un láti pa ayé, àti Òkun, lára,
3 „Bíðið! Skaðið hvorki jörðina, hafið né heldur trén. Gerið ekkert að svo stöddu, ekki fyrr en við höfum sett innsigli Guðs á enni þeirra sem honum þjóna.“
wí pé, “Ẹ má ṣe pa ayé, tàbí Òkun, tàbí igi lára, títí àwa ó fi fi èdìdì sàmì sí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa ní iwájú wọn.”
4 Hve margir fengu þetta innsigli? Það fékk ég að vita, þeir voru 144.000. Hinir innsigluðu voru af öllum tólf ættkvíslum Ísraels eins og hér segir: Júda 12.000, Rúben 12.000, Gað 12.000, Asser 12.000, Naftalí 12.000, Manasse 12.000, Símeon 12.000, Leví 12.000, Íssakar 12.000, Sebúlon 12.000, Jósef 12.000 og Benjamín 12.000.
Mo sì gbọ́ iye àwọn tí a fi èdìdì sàmì si, àwọn tí a sàmì sí jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì láti inú gbogbo ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli wá.
5
Láti inú ẹ̀yà Juda a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Reubeni a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Gadi a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.
6
Láti inú ẹ̀yà Aṣeri a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Naftali a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Manase a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.
7
Láti inú ẹ̀yà Simeoni a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Lefi a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Isakari a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.
8
Láti inú ẹ̀yà Sebuluni, a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Josẹfu a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà. Láti inú ẹ̀yà Benjamini a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.
9 Eftir þetta sá ég mikinn mannfjölda, sem enginn gat talið. Þetta fólk var af öllum þjóðum og tungum og stóð fyrir framan hásætið, frammi fyrir lambinu. Það var í hvítum skikkjum og hélt á pálmagreinum.
Lẹ́yìn náà, mo ri, sì kíyèsi i, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí ẹnikẹ́ni kò lè kà, láti inú orílẹ̀-èdè gbogbo, àti ẹ̀yà, àti ènìyàn, àti láti inú èdè gbogbo wá, wọn dúró níwájú ìtẹ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà, a wọ̀ wọ́n ni aṣọ funfun, imọ̀ ọ̀pẹ si ń bẹ ni ọwọ́ wọn.
10 Og það hrópaði hárri röddu: „Hjálpræðið kemur frá Guði, sem situr í hásætinu, og lambinu!“
Wọ́n sì kígbe ní ohùn rara, wí pé: “Ìgbàlà ni ti Ọlọ́run wá tí o jókòó lórí ìtẹ́, àti ti Ọ̀dọ́-àgùntàn!”
11 Þá söfnuðust allir englarnir umhverfis hásætið, öldungana og verurnar fjórar og féllu fram á ásjónur sínar, frammi fyrir hásætinu og tilbáðu Guð.
Gbogbo àwọn angẹli sì dúró yí ìtẹ́ náà ká, àti yí àwọn àgbà àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ká, wọn wólẹ̀ wọn si dojúbolẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà wọ́n sì sin Ọlọ́run.
12 „Amen!“sögðu þeir. „Lofgjörðin, dýrðin, viskan, þakkargjörðin, heiðurinn, krafturinn og mátturinn sé Guði okkar um alla eilífð. Amen!“ (aiōn g165)
Wí pe: “Àmín! Ìbùkún, àti ògo, àti ọgbọ́n, àti ọpẹ́, àti ọlá, àti agbára àti ipá fún Ọlọ́run wa láé àti láéláé! Àmín!” (aiōn g165)
13 Þá spurði mig einn af öldungunum tuttugu og fjórum: „Veistu hverjir þetta eru, þessir hvítklæddu, og hvaðan þeir koma?“
Ọ̀kan nínú àwọn àgbà náà si dáhùn, ó bi mí pé, “Ta ni àwọn wọ̀nyí tí a wọ ni aṣọ funfun? Níbo ni wọn sì ti wá?”
14 „Nei, herra, “svaraði ég, „segðu mér það.“„Þetta eru þeir sem komnir eru úr þrengingunni miklu, “sagði hann. „Þeir þvoðu skikkjur sínar skjannahvítar í blóði lambsins og
Mo sì wí fún un pé, “Olúwa mi, ìwọ ni o lè mọ̀.” Ó sì wí fún mí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni o jáde láti inú ìpọ́njú ńlá, wọ́n sì fọ aṣọ wọ́n, wọ́n sì sọ wọ́n di funfun nínú ẹ̀jẹ̀ Ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
15 þess vegna eru þeir hér frammi fyrir hásæti Guðs og þjóna honum dag og nótt í musterinu. Sá sem situr í hásætinu mun gæta þeirra.
Nítorí náà ni, “wọn ṣe ń bẹ níwájú ìtẹ́ Ọlọ́run, tí wọn sì ń sìn ín, lọ́sàn àti lóru nínú tẹmpili rẹ̀; ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́ náà yóò si síji bò wọn.
16 Þá mun aldrei framar hungra né heldur þyrsta og sólarhitinn mun ekki brenna þá,
Ebi kì yóò pa wọn mọ́, bẹ́ẹ̀ ni òùngbẹ kì yóò gbẹ́ wọ́n mọ́; bẹ́ẹ̀ ni oòrùn kì yóò pa wọn tàbí oorukóoru kan.
17 því að lambið, sem stendur frammi fyrir hásætinu, mun fæða þá og vera hirðir þeirra. Það mun leiða þá að lind lífsvatnsins og Guð mun þerra tárin af augum þeirra.“
Nítorí ọ̀dọ́-àgùntàn tí ń bẹ ni àárín ìtẹ́ náà ni yóò máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn wọn, ‘tí yóò sì máa ṣe amọ̀nà wọn sí ibi orísun omi ìyè.’ ‘Ọlọ́run yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ni ojú wọn.’”

< Opinberun Jóhannesar 7 >