< Zsoltárok 73 >
1 Aszáf zsoltára. Bizony jó Izráelhez az Isten, azokhoz, a kik tiszta szívűek.
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
2 De én?! Már-már meghanyatlottak lábaim; és kis híjja, hogy lépteim el nem iszamodtak.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
3 Mert irígykedtem a kevélyekre, látván a gonoszok jó szerencséjét.
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
4 Mert halálukig nincsenek kínjaik, és az ő erejök állandó.
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
5 A halandók nyomorúságában nincs részök, és az emberekkel nem ostoroztatnak.
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
6 Ezért nyakuknak ékessége kevélység, ruha gyanánt erőszak borítja őket.
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
7 A kövérség miatt kinn ülnek az ő szemeik, elméjök gondolatjai csaponganak.
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
8 Gúnyolódnak és gonoszságot szólnak; elnyomásról beszélnek fennhéjázással.
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
9 Az égre tátogatják szájokat, és nyelvök eljárja a földet.
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
10 Azért fordul az ő népe ide, hogy tele pohár vizet szürcsölnek;
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
11 És mondják: Mint tudhatná ezt az Isten, s van-é a Magasságosban értelem?
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
12 Ímé, ezek gonoszok, és örök biztonságban vagyont gyűjtenek!
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
13 Bizony hiába tartottam én tisztán szívemet, és mostam ártatlanságban kezeimet;
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
14 Mert nyomorgattatom minden napon, és ostoroztatom minden reggel!
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
15 Ha azt mondom: Ilyen módon szólok: Ímé, a te fiaid nemzedékét árulom el.
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
16 Gondolkodom, hogy ezt megérthessem; de nehéz dolog ez szemeimben.
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
17 Mígnem bemenék az Isten szent helyébe: megértém azoknak sorsát.
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
18 Bizony síkos földön helyezted el őket; pusztaságokra vetetted ki őket.
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
19 Mind elpusztulnak egy szempillantásban! Elvesznek, elenyésznek a rettegéstől.
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
20 Mint álmot, ha felserkenünk: te Uram, ha felserkensz, úgy veted meg képöket.
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
21 Hogyha keseregne szívem, és háborognának veséim:
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
22 Akkor balgatag és tudatlan volnék én, oktalan állat volnék te irántad.
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
23 De én mindenkor veled vagyok, te fogod az én jobb kezemet.
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
24 Tanácsoddal igazgatsz engem, és azután dicsőségbe fogadsz be engem.
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
25 Kicsodám van az egekben? Náladnál egyébben nem gyönyörködöm e földön!
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
26 Ha elfogyatkozik is testem és szívem: szívemnek kősziklája és az én örökségem te vagy, oh Isten, mindörökké!
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
27 Mert ímé, a kik eltávoznak tőled, elvesznek; mind kiirtod azokat, a kik elhajolnak tőled.
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
28 De én? Isten közelsége oly igen jó nékem. Az Úr Istenben vetem reménységemet, hogy hirdessem minden te cselekedetedet.
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.