< Zsoltárok 68 >

1 Az éneklőmesternek; Dávid zsoltára, éneke. Felkél az Isten, elszélednek ellenségei; és elfutnak előle az ő gyűlölői.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
2 A mint a füst elszéled, úgy széleszted el őket; a mint elolvad a viasz a tűz előtt, úgy vesznek el a gonoszok Isten elől;
Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
3 Az igazak pedig örvendeznek és vígadnak az Isten előtt, és ujjongnak örömmel.
Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
4 Énekeljetek Istennek, zengedezzetek az ő nevének; csináljatok útat annak, a ki jön a pusztákon át, a kinek Jah a neve, és örüljetek előtte.
Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
5 Árváknak atyja, özvegyeknek bírája az Isten az ő szentséges hajlékában.
Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
6 Isten hozza vissza a száműzötteket, kihozza boldogságra a foglyokat; csak az engedetlenek lakoznak sivatag helyen.
Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7 Oh Isten, mikor kivonultál a te néped előtt, mikor a pusztába beléptél: (Szela)
Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
8 A föld reng vala, az egek is csepegnek vala Isten előtt, ez a Sinai hegy is az Isten előtt, az Izráel Istene előtt.
Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
9 Bő záport hintesz vala, oh Isten, a te örökségedre, s a lankadót megújítod vala.
Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
10 Benne tanyázott a te gyülekezeted: te szerzéd jóvoltodból a szegénynek, oh Isten!
Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
11 Az Úr ad vala szólniok az örömhírt vivő asszonyok nagy csapatának.
Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
12 A seregek királyai futnak, futnak: s a házi asszony zsákmányt osztogat.
“Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13 Ha cserények között hevertek is: olyanok lesztek, mint a galambnak szárnyai, a melyeket ezüst borít, vagy mint vitorla-tollai, a melyek színarany fényűek.
Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
14 Mikor a Mindenható szétszórta benne a királyokat, mintha hó esett volna a Salmonon.
Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
15 Isten hegye a Básán hegye; sok halmú hegy a Básán hegye;
Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
16 Mit kevélykedtek ti sok halmú hegyek? Ezt a hegyet választotta Isten lakóhelyéül; bizony ezen lakozik az Úr mindörökké!
Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17 Az Isten szekere húszezer, ezer meg ezer; az Úr közöttük van, mint a Sinai hegyen az ő szent hajlékában.
Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
18 Felmentél a magasságba, foglyokat vezettél, adományokat fogadtál emberekben: még a pártütők is ide jönnek lakni, oh Uram Isten!
Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
19 Áldott legyen az Úr! Napról-napra gondoskodik rólunk a mi szabadításunk Istene! (Szela)
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
20 Ez a mi Istenünk a szabadításnak Istene, és az Úr Isten az, a ki megszabadít a haláltól.
Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
21 Csak Isten ronthatja meg az ő ellenségeinek fejét, a bűneiben járónak üstökös koponyáját.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22 Azt mondta vala az Úr: Básánból visszahozlak, a tenger mélységéből is kihozlak,
Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
23 Hogy lábadat veresre fessed a vérben, ebeidnek nyelve az ellenségből lakomázzék.
kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
24 Látták a te bevonulásodat, oh Isten! Az én Istenem, királyom bevonulását a szentélybe.
Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
25 Elől mennek vala az éneklők, utánok a húrpengetők, középen a doboló leányok.
Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
26 A gyülekezetekben áldjátok az Istent, az Urat áldjátok, ti Izráel magvából valók!
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
27 Ott a kis Benjámin, a ki uralkodik rajtok, a Júda fejedelmei és az ő gyülekezetök; a Zebulon fejedelmei és a Nafthali fejedelmei.
Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
28 Istened rendelte el a te hatalmadat: erősítsd meg, oh Isten, azt, a mit számunkra készítettél!
Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
29 A te Jeruzsálem felett álló hajlékodból királyok hoznak majd néked ajándékokat.
Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Fenyítsd meg a nádasnak vadját, a bikák csordáját a népek tulkaival egybe, a kik ezüst-rudakkal terpeszkednek; szórd szét a népeket, a kik a háborúban gyönyörködnek.
Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
31 Eljőnek majd a főemberek Égyiptomból; Szerecsenország hamar kinyujtja kezeit Istenhez.
Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
32 E földnek országai mind énekeljetek Istennek: zengjetek dicséretet az Úrnak! (Szela)
Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
33 A ki kezdettől fogva az egek egein ül; ímé, onnét szól nagy kemény szóval.
Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
34 Tegyetek tisztességet Istennek, a kinek dicsősége az Izráelen és az ő hatalma a felhőkben van.
Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
35 Rettenetes vagy, oh Isten, a te szent hajlékodból; az Izráelnek Istene ád erőt és hatalmat a népnek. Áldott legyen az Isten!
Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!

< Zsoltárok 68 >