< Példabeszédek 30 >

1 Agurnak, a Jáké fiának beszédei, próféczia, melyet mondott a férfiú Itielnek, Itielnek és Ukálnak.
Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
2 Minden embernél tudatlanabb vagyok én, és nincs emberi értelem én bennem.
“Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
3 És nem tanultam a bölcseséget, hogy a Szentnek ismeretét tudnám.
Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
4 Kicsoda ment fel az égbe, hogy onnan leszállott volna? Kicsoda fogta össze a szelet az ő markába? Kicsoda kötötte a vizet az ő köntösébe? Ki állapította meg a földnek minden határit? Kicsoda ennek neve? Avagy kicsoda ennek fiának neve, ha tudod?
Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
5 Az Istennek teljes beszéde igen tiszta, és paizs az ahhoz folyamodóknak.
“Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
6 Ne tégy az ő beszédéhez; hogy meg ne feddjen téged, és hazug ne légy.
Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
7 Kettőt kérek tőled; ne tartsd meg én tőlem, mielőtt meghalnék.
“Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
8 A hiábavalóságot és a hazugságot messze távoztasd tőlem; szegénységet vagy gazdagságot ne adj nékem; táplálj engem hozzám illendő eledellel.
Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
9 Hogy megelégedvén, meg ne tagadjalak, és azt ne mondjam: kicsoda az Úr? Se pedig megszegényedvén, ne lopjak, és gonoszul ne éljek az én Istenem nevével!
Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
10 Ne rágalmazd a szolgát az ő uránál, hogy meg ne átkozzon téged, és bűnhődnöd ne kelljen.
“Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
11 Van oly nemzetség, a ki az ő atyját átkozza, és az ő anyját nem áldja.
“Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
12 Van nemzetség, a ki a maga szemei előtt tiszta, pedig az ő rútságából ki nem tisztíttatott.
Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
13 Van kevély szemű nemzetség, és a kinek szemöldökei igen fellátnak!
àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
14 Van olyan nemzetség, a kinek fogai fegyverek, és a kinek zápfogai kések; hogy a szegényeket kiemészszék e földről, és az emberek közül a szűkölködőket.
Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
15 A nadálynak két leánya van: addsza, addsza! E három nem elégszik meg; négyen nem mondják: elég;
“Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
16 A sír és a meddő asszony, a föld meg nem elégszik a vízzel, és a tűz nem mondja: elég! (Sheol h7585)
Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol h7585)
17 A szemet, mely megcsúfolja atyját, vagy megútálja az anyja iránt való engedelmességet, kivágják a völgynek hollói, vagy megeszik a sasfiak.
“Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
18 E három megfoghatatlan előttem, és e négy dolgot nem tudom:
“Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
19 A keselyűnek útát az égben, a kígyónak útát a kősziklán, a hajónak nyomát a mély tengerben, és a férfiúnak útát a leányzóval.
ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
20 Ilyen a paráználkodó asszonynak úta; eszik, azután megtörli száját és azt mondja: nem cselekedtem semmi gonoszt.
“Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
21 Három dolog alatt indul meg a föld, és négyet nem szenvedhet el.
“Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
22 A szolga alatt, mikor uralkodik, és a bolond alatt, mikor elég kenyere van,
Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
23 A gyűlölt asszony alatt, ha mégis férjhez megy; és a szolgáló alatt, ha örököse lesz az ő asszonyának.
obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
24 E négy apró állata van a földnek, a melyek bölcsek, elmések:
“Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
25 A hangyák erőtlen nép, mégis megkeresik nyárban a magok eledelét;
Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
26 A marmoták nem hatalmas nép, mégis kősziklán csinálják az ő házokat;
Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
27 Királyuk nincs a sáskáknak, mindazáltal mindnyájan szép renddel mennek ki;
àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
28 A pókot kézzel megfoghatod, mégis ott van a királyok palotáiban.
Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
29 Három állat van, a mely szépen jár, sőt négy, a mely jól jár.
“Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
30 Az oroszlán, a hős a vadak között, mely el nem fut senki elől;
Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
31 A harczra felékesített ló, vagy a kecskebak, és a király, a kinek senki nem mer ellene állani.
Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
32 Ha bolond voltál felfuvalkodásodban, vagy ha meggondoltad: kezedet szájadra vessed.
“Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
33 Mert miképen a ki tejet köpül, vajat csinál; és a ki keményen fújja ki az ő orrát, vért hoz ki: úgy a ki a haragot ingerli, háborúságot szerez.
Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”

< Példabeszédek 30 >