< Példabeszédek 3 >

1 Fiam! az én tanításomról el ne felejtkezzél, és az én parancsolatimat megőrizze a te elméd;
Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
2 Mert napoknak hosszú voltát, és sok esztendős életet, és békességet hoznak néked bőven.
Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
3 Az irgalmasság és igazság ne hagyjanak el téged: kösd azokat a te nyakadra, írd be azokat a te szívednek táblájára;
Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
4 Így nyersz kedvességet és jó értelmet Istennek és embernek szemei előtt.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
5 Bizodalmad legyen az Úrban teljes elmédből; a magad értelmére pedig ne támaszkodjál.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
6 Minden te útaidban megismered őt; akkor ő igazgatja a te útaidat.
Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
7 Ne légy bölcs a te magad ítélete szerint; féld az Urat, és távozzál el a gonosztól.
Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
8 Egészség lesz ez a te testednek, és megújulás a te csontaidnak.
Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
9 Tiszteld az Urat a te marhádból, a te egész jövedelmed zsengéjéből.
Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
10 Eképen megtelnek a te csűreid elégséggel, és musttal áradnak el sajtód válúi.
nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
11 Az Úrnak fenyítését fiam, ne útáld meg, se meg ne únd az ő dorgálását.
Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12 Mert a kit szeret az Úr, megdorgálja, és pedig mint az atya az ő fiát, a kit kedvel.
nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
13 Boldog ember, a ki megnyerte a bölcseséget, és az ember, a ki értelmet szerez.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
14 Mert jobb ennek megszerzése az ezüstnek megszerzésénél, és a kiásott aranynál ennek jövedelme.
nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15 Drágább a fényes kárbunkulusoknál, és minden te gyönyörűségeid nem hasonlíthatók hozzá.
Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16 Napoknak hosszúsága van jobbjában, baljában gazdagság és tisztesség.
Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
17 Az ő útai gyönyörűséges útak, és minden ösvényei: békesség.
Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
18 Életnek fája ez azoknak, a kik megragadják, és a kik megtartják boldogok!
Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
19 Az Úr bölcseséggel fundálta a földet, erősítette az eget értelemmel.
Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
20 Az ő tudománya által fakadtak ki a mélységből a vizek, és a felhők csepegnek harmatot,
nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
21 Fiam, ne távozzanak el a te szemeidtől, őrizd meg az igaz bölcseséget, és a meggondolást!
Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
22 És lesznek ezek élet a te lelkednek, és kedvesség a te nyakadnak.
Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
23 Akkor bátorsággal járod a te útadat, és a te lábadat meg nem ütöd.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
24 Mikor lefekszel, nem rettegsz; hanem lefekszel és gyönyörűséges lesz a te álmod.
Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
25 Ne félj a hirtelen való félelemtől, és a gonoszok pusztításától, ha eljő;
Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
26 Mert az Úr lesz a te bizodalmad és megőrzi a te lábadat a fogságtól.
Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
27 Ne fogd meg a jótéteményt azoktól, a kiket illet, ha hatalmadban van annak megcselekedése.
Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28 Ne mondd a te felebarátodnak: menj el, azután térj meg, és holnap adok; holott nálad van, a mit kér.
Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29 Ne forralj a te felebarátod ellen gonoszt, holott ő együtt ül bátorságosan te veled.
Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30 Ne háborogj egy emberrel is ok nélkül, ha nem illetett gonoszszal téged.
Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
31 Ne irígykedjél az erőszakos emberre, és néki semmi útát ne válaszd.
Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
32 Mert útálja az Úr az engedetlent; és az igazakkal van az ő titka.
Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33 Az Úrnak átka van a gonosznak házán; de az igazaknak lakhelyét megáldja.
Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
34 Ha kik csúfolók, ő megcsúfolja azokat; a szelídeknek pedig ád kedvességet.
Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
35 A bölcsek tisztességet örökölnek; a bolondok pedig gyalázatot aratnak.
Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.

< Példabeszédek 3 >